< Jeremiah 50 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
Detta är det ord som HERREN talade om Babel, om kaldéernas land, genom profeten Jeremia.
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Förkunnen detta bland folken och kungören det, och resen upp ett baner; kungören det, döljen det icke. Sägen: Babel är intaget, Bel har kommit på skam, Merodak är krossad, ja, dess avgudar hava kommit på skam, dess eländiga avgudar äro krossade.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Ty ett folk drager upp mot det norrifrån, som skall göra dess land till en ödemark, så att ingen kan bo däri; både människor och djur skola fly bort.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
I de dagarna och på den tiden, säger HERREN, skola Israels barn komma vandrande tillsammans med Juda barn; under gråt skola de gå åstad och söka HERREN, sin Gud.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
De skola fråga efter Sion; hitåt skola deras ansikten vara vända: "Kommen! Må man nu hålla fast vid HERREN i ett evigt förbund, som aldrig varder förgätet."
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
En vilsekommen hjord var mitt folk. Deras herdar hade fört dem vilse och läto dem irra omkring på bergen. Så strövade de från berg till höjd och glömde sin rätta lägerplats.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
Alla som träffade på dem åto upp dem, och deras ovänner sade: "Vi ådraga oss ingen skuld därmed." Så skedde, därför att de hade syndat mot HERREN, rättfärdighetens boning, mot HERREN, deras fäders hopp.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Flyn ut ur Babel, dragen bort ifrån kaldéernas land, och bliven lika bockar som hasta framför hjorden.
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Ty se, jag skall uppväcka från nordlandet en hop av stora folk och föra dem upp mot Babel, och de skola rusta sig till strid mot det; från det hållet skall det bliva intaget. Deras pilar skola vara såsom en lyckosam hjältes, som icke vänder tillbaka utan seger.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
Och Kaldeen skall lämnas till plundring; dess plundrare skola alla få nog, säger HERREN.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
Ja, om I än glädjens och fröjden eder, I som skövlen min arvedel, om I än hoppen såsom kvigor på tröskplatsen och frusten såsom hingstar,
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
eder moder skall dock komma storligen på skam; hon som har fött eder skall få blygas. Se, bland folken skall hon bliva den yttersta -- en öken, ett torrt land och en hedmark!
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
För HERRENS förtörnelses skull måste det ligga obebott och alltigenom vara en ödemark. Alla som gå fram vid Babel skola häpna och vissla vid tanken på alla dess plågor.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Rusten eder till strid mot Babel från alla sidor, I som spännen båge; skjuten på henne, sparen icke på pilarna; ty mot HERREN har hon syndat.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Höjen segerrop över henne på alla sidor: "Hon har måst giva sig; fallna äro hennes stödjepelare, nedrivna hennes murar!" Detta är ju HERRENS hämnd, så hämnens då på henne. Såsom hon har gjort, så mån I göra mot henne.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Utroten ur Babel både dem som så och dem som i skördens tid föra lien. Undan det härjande svärdet må envar nu vända om till sitt folk och envar fly hem till sitt land.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
Israel var ett vilsekommet får som jagades av lejon. Först åts det upp av konungen i Assyrien, och sist har Nebukadressar, konungen i Babel, gnagt dess ben.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
Därför säger HERREN Sebaot, Israels Gud, så: Se, jag skall hemsöka konungen i Babel och hans land, likasom jag har hemsökt konungen i Assyrien.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
Och jag skall föra Israel tillbaka till hans betesmarker, och han skall få gå bet på Karmel och i Basan; och på Efraims berg och i Gilead skall han få äta sig mätt.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
I de dagarna och på den tider säger HERREN, skall man söka efter Israels missgärning, och den skall icke mer vara till, och efter Juda synder, och de skola icke mer bliva funna; ty jag skall förlåta dem som jag låter leva kvar.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
Drag ut mot Merataims land och mot inbyggarna i Pekod. Förfölj dem och döda dem och giv dem till spillo, säger HERREN, och gör i alla stycken såsom jag har befallt dig.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Krigsrop höras i landet, och stort brak.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Huru sönderbruten och krossad är den icke, den hammare som slog hela jorden! Huru har icke Babel blivit till häpnad bland folken!
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
Jag lade ut en snara för dig, och så blev du fångad, Babel, förrän du visste därav; du blev ertappad och gripen, ty det var med HERREN som du hade givit dig i strid.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
HERREN öppnade sin rustkammare och tog fram sin vredes vapen. Ty ett verk hade Herren, HERREN Sebaot, att utföra i kaldéernas land.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Ja, kommen över det från alla sidor, öppnen dess förrådskammare, kasten i en hög vad där finnes, såsom man gör med säd, och given det till spillo; låten intet därav bliva kvar.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Nedgören alla dess tjurar, fören dem ned till att slaktas. Ve dem, ty deras dag har kommit, deras hemsökelses tid!
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Hör huru de fly och söka rädda sig ur Babels land, för att i Sion förkunna HERRENS, vår Guds, hämnd, hämnden för hans tempel.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Båden upp mot Babel folk i mängd, allt vad bågskyttar heter; lägren eder runt omkring det, låten ingen undkomma. Vedergällen det efter dess gärningar; gören mot det alldeles såsom det självt har gjort. Ty mot HERREN har det handlat övermodigt, mot Israels Helige.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
Därför skola dess unga man falla på dess gator, och alla dess stridsmän skola förgöras på den dagen, säger HERREN.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
Se, jag skall vända mig mot dig, du övermodige, säger Herren, HERREN Sebaot, ty din dag har kommit, den tid då jag vill hemsöka dig.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
Då skall den övermodige stappla och falla, och ingen skall kunna upprätta honom. Och jag skall tända eld på hans städer, och elden skall förtära allt omkring honom.
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Så säger HERREN Sebaot: Förtryckta äro Israels barn, och Juda barn jämte dem. Alla de som hava fart dem i fångenskap hålla dem fast och vilja icke släppa dem.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
Men deras förlossare är stark; HERREN Sebaot är hans namn. Han skall förvisso utföras deras sak, så att han skaffar ro åt jorden -- men oro åt Babels invånare.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
Svärd komme över kaldéerna, säger HERREN, över Babels invånare, över dess furstar och dess visa män!
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
Svärd komme över lögnprofeterna, så att de stå där såsom dårar! Svärd komme över dess hjältar, så att de bliva förfärade!
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
Svärd komme över dess hästar och vagnar och över allt främmande folk därinne, så att de bliva såsom kvinnor! Svärd komme över dess skatter, så att de bliva tagna såsom byte!
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
Torka komme över dess vatten, så att de bliva uttorkade! Ty det är ett belätenas land, och skräckgudar dyrka de såsom vanvettiga människor.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
Därför skola nu schakaler bo där tillsammans med andra ökendjur, och strutsar skola där få sin boning. Aldrig mer skall det bliva bebyggt, från släkte till släkte skall det vara obebott.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
Likasom när Sodom och Gomorra med sina grannstäder omstörtades av Gud, säger HERREN, så skall ingen mer bo där och intet människobarn där vistas.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Se, ett folk kommer norrifrån; ett stort folk och många konungar resa sig och komma från jordens yttersta ända.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
De föra båge och lans, de äro grymma och utan förbarmande. Dånet av dem är såsom havets brus, och på sina hästar rida de fram, rustade såsom kämpar till strid, mot dig, du dotter Babel.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
När konungen i Babel hör ryktet om dem, sjunka hans händer ned; ängslan griper honom, ångest lik en barnaföderskas.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Se, lik ett lejon som drager upp från Jordanbygdens snår och bryter in på frodiga betesmarker skall jag i ett ögonblick jaga dem bort därifrån; och den som jag utväljer skall jag sätta till herde över dem. Ty vem är min like, och vem kan ställa mig till ansvar? Och vilken är den herde som kan bestå inför mig?
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
Hören därför det råd som HERREN har lagt mot Babel, och de tankar som han har mot kaldéernas land: Ja, herdegossarna skola sannerligen släpas bort; sannerligen, deras betesmark skall häpna över dem.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
När man ropar: "Babel är intaget", då bävar jorden, och ett skriande höres bland folken.

< Jeremiah 50 >