< Jeremiah 50 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
Słowo, które mówł Pan przeciwko Babilonowi, i przeciwko ziemi Chaldejskiej przez Jeremijasza proroka;
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Opowiadajcie między narodami, a rozgłaszajcie, podnieście chorągiew, rozgłaszajcie, nie tajcie, mówcie: Wzięty będzie Babilon, pohańbiony będzie Bel, potarty będzie Merodach, pohańbione będą bałwany jego, pokruszeni będą plugawi bogowie jego.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Bo przyciągnie przeciwko niemu naród z północy, który ziemię jego obróci w pustynię, tak, że nie będzie, coby mieszkał w niej; tak ludzie jako i bydlęta ruszą się i odejdą.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
W onych dniach, i w onych czasach, mówi Pan, przyjdą synowie Izraelscy, oni i synowie Judzcy; płacząc społem ochotnie pójdą, a Pana, Boga swego, szukać będą.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
O drodze do Syonu pytać się będą, a obuciwszy się tam twarzą, rzekną: Pójdźcie, a przyłączcie się do Pana przymierzem wiecznem, które nie przyjdzie w zapamiętanie.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Lud mój jest jako trzoda owiec straconych, pasterze ich zawiedli ich w błąd, po górach rozegnali ich: z góry na pagórek chodziły, zapomniawszy legowiska swego.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
Wszyscy, którzy ich znajdują, pożerają ich, a nieprzyjaciele ich mówią: Nie będziemy nic winni, przeto, że zgrzeszyli Panu w przybytku sprawiedliwości, Panu, który jest nadzieją ojców ich.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Uchodźcie z pośrodku Babilonu, a z ziemi Chaldejskiej wychodzcie, i będźcie jako kozły przed trzodą.
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Bo oto Ja wzbudzę i przywiodę na Babilon zgromadzenie narodów wielkich z ziemi północnej; którzy się uszykują przeciwko niemu, a stamtąd go wezmą; których strzały są jako mocarza osieracającego, z których żadna się nie wróci próżno.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
I będzie Chaldejska ziemia na łup, a wszyscy, którzy ją złupią, nasyceni będą, mówi Pan.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
Przeto, że się weselicie, przeto, że się radujecie, rozchwytając dziedzictwo moje, przeto, żeście nabrali ciała jako jałowica utuczona, a wyskakujecie jako mocarze.
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
Zawstydzona będzie matka wasza bardzo; zapłonie się rodzicielka wasza; oto najpośledniejszą będzie z narodów, pustą ziemią, suchą i bezdrożną.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
Dla gniewu Pańskiego nie bądą w niej mieszkać, ale ona wszystka obróci się w pustynię; ktokolwiek pójdzie mimo Babilonu, zdumieje się, i zaświśnie nad wszystkiemi plagami jego.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Szykujcie wojska przeciw Babilonowi zewsząd wszyscy, co ciągniecie łuk, strzelajcie do niego, nie żałujcie strzał; bo przeciwko Panu zgrzeszył.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Wołajcie przeciwko niemu zewsząd; poddał się, upadły grunty jego, skażone są mury jego; bo pomsta Pańska jest. Pomścijcież się nad nim; jako on czynił innym, tak mu też uczyńcie.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Wytraćcie siejącego z Babilonu, i tego, który trzyma śierp czasu żniwa; przed ostrzem miecza burzącego każdy niech się do ludu swego obróci, i każdy do ziemi swojej niech uciecze.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
Izrael jest jako bydlądko zagnane, które lwy zapłoszyły. Król Assyryjski najpierwszy był, który go żreć począł, a ten ostateczny, Nabuchodonozor, król Babiloński, kości jego pokruszył.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
Przetoż tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Oto Ja nawiedzę króla Babilońskiego i ziemię jego, jakom nawiedził króla Assyryskiego;
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
I przywrócę zaś Izraela do mieszkania jego, a paść się będzie na Karmelu, i na Basanie, i na górze Efraimowej, a w Galaadzie nasycona będzie dusza jego.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
W onych dniach i w onych czasach, mówi Pan, będą szukać nieprawości Izraelowej, ale żadnej nie będzie; i grzechów Judzkich, ale nie będą znalezione; bo odpuszczę tym, których pozostawię.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
Wyciągnij przeciwko tej ziemi odpornych, przeciwko niej, mówię, a obywateli jej nawiedź; spustosz a wygładź, goniąc ich, mówi Pan; uczyńże według wszystkiego, jakoć rozkazuje.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Niech będzie głos wojenny w tej ziemi, i spustoszenie wielkie.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Jakożby posiekany i połamany być miał młot wszystkiej ziemi? Jakożby się Babilon stał zdumienie między narodami?
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
Sidłom zastawił na cię, i będziesz pojmany, o Babilonie! nim się obaczysz; znaleziony nawet i pojmany będziesz, ponieważeś z Panem zwadę zaczął.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
Otworzył Pan skarb swój, a wyniósł naczynia gniewu swego; bo to jest sprawa Pana, Pana zastępów w ziemi Chaldejskiej.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Pójdźcież przeciwko niej od kończyn ziemi, otwórzcież szpichlerze jej podepczcie ją jako stogi, a wygładźcie ją tak, aby jaj nic nie zostało;
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Pozabijajcie wszystkie cielce jej, niech zstępują na zabicie. Biada im! bo przyszedł dzień ich, czas nawiedzenia ich.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Głos uciekających, i tych, co uchodzą, z ziemi Babilońskiej, aby oznajmili na Syonie pomstę Pana, Boga naszego, pomstę kościoła jego.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Zgromadzcie przeciwko Babilonowi wszystkich strzelców, którzy łuk ciągną; połóżcie się obozem przeciw niemu w około, aby nikt nie uszedł; oddajcie mu według spraw jego, według wszystkiego, co innym czynił, uczyńcie mu; bo się przeciwko Panu wynosił, przeciwko Świętemu Izraelskiemu.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
Przetoż polegną młodzieńcy jego na ulicach jego, i wszyscy mężowie waleczni jego wygładzeni będą dnia onego, mówi Pan.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
Otom ja przeciwko tobie, o hardy! mówi Pan, Pan zastępów; bo już przyszedł dzień twój i czas, abym cię nawiedził.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
Potknie się zaiste hardy, i upadnie, a nie będzie, ktoby go podniósł; i rozniecę ogień w miastach jego, który pożre wszystko około niego.
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Tak mówi Pan zastępów: Gwałt się dzieje synom Izraelskim i synom Judzkim społem, a wszyscy, którzy ich pojmali, trzymają ich, nie chcą ich puścić.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
Ale odkupiciel ich możny, Pan zastępów imię jego, pewnie że się ujmie o krzywdę ich, aby sprawił pokój tej ziemi, i poruszył obywateli Babilońskich.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
Miecz przyjdzie na Chaldejczyków, mówi Pan, i na obywateli Babilońskich, i na książąt jego, i na mędrców jego;
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
Miecz na kłamców, aby zgłupieli, miecz na mocarzy jego, aby skruszeni byli;
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
Miecz na konie jego, i na wozy jego, i na wszystko pospólstwo, które jest w pośrodku jego, aby byli jako niewasty; miecz na skarby jego, aby były rozchwycone;
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
Susza na wody jego, aby wyschły; bo ziemia jest pełna obrazów rytych, a przy bałwanach swoich szaleją.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
Przeto tam mieszkać będą bestyje i straszne zwierzęta, mieszkać w nim będą młode sowy; a nie będą w nim mieszkać więcej na wieki, i nie będą w nim mieszkać od narodu do narodu.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
Jako Pan podwrócił Sodomę i Gomorę, i przyległości ich, mówi Pan, tak się tam nikt nie osadzi, ani będzie mieszkał w niej syn człowieczy.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Oto lud przyciągnie od północy, i naród wielki, i królowie wielcy wzbudzeni będą ze stron ziemi.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Łuk i włóczni pochwycą, okrutnymi będą, a nie zmiłują się; głos ich jako morze zaszumi, a na koniach pojadą, uszykowani jako mąż do bitwy przeciwko tobie, o córko Babilońska!
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
Jako usłyszy król Babiloński wieść o nich, osłabieją ręce jego, a ucisk ogarnie go, i boleść jako rodzącą.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Oto aczkolwiek jako lew występuje, i bardzej niż nadętość Jordanu się podnosi przeciwko przybytkowi mocnego, wszakże go w okamgnieniu wypędzę z niej, a tego, który jest wybrany, przełożę nad nią; bo któż jest mnie podobnym; i kto mi da rok? a kto jest tym pasterzem, któryby się postawił przeciwko mnie?
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
Przetoż słuchajcie rady Pańskiej, którą uradził przeciwko Babilonowi; i zamysłów jego, które umyślił przeciwko ziemi Chaldejskiej; zaiste żeć ich wywloką najmniejsi z tej trzody, zaiste poburzą ich i przybytek ich.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Od huku przy dobywaniu Babilonu poruszy się ta ziemia, a krzyk między narodami słyszany będzie.