< Jeremiah 50 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
Az a szó, a melyet szóla az Úr Babilon felől és a Káldeusok földje felől, Jeremiás próféta által.
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Hirdessétek a nemzetek között és hallassátok, emeljétek fel a zászlót: hallassátok és el ne titkoljátok; ezt mondjátok: Bevétetett Babilon, megszégyenült Bél, letöretett Merodák, megszégyenültek az ő faragott képei, letörettek az ő bálványai.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Mert északról nép jön fel ellene, pusztává teszi ez az ő földét, és nem lesz, a ki lakozzék benne; embertől fogva a baromig elfutnak, elmennek.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Azokban a napokban, és abban az időben, azt mondja az Úr, eljőnek az Izráel fiai, ők és a Júda fiai együtt, sírva jönnek és mennek és keresik az Urat, az ő Istenöket.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
A Sion felől kérdezősködnek, arrafelé fordítják orczájokat. Eljőnek és oda adják magokat az Úrnak örök szövetségre, a mely feledhetetlen.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Elveszett juhnyáj volt az én népem, pásztorai félrevezették őket, a hegyekben bujdostatták őket, hegyről halomra jártak, elfelejtkeztek az ő tanyájukról.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
A ki csak reájok talált, emésztette őket, és az ő elnyomóik ezt mondták: Nem vétkeztünk, mert vétettek az Úr ellen, pedig igazság otthona, atyáiknak reménysége volt az Úr.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Fussatok ki Babilonból és jőjjetek ki Káldea földéből, és olyanok legyetek, mint a kecskebakok a nyáj előtt;
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Mert ímé, én nagy nemzetek gyülekezetét támasztom és hozom fel Babilonra északnak földéről, és sorakoznak ellene, legott bevétetik. Nyilai olyanok, mint a legyőzhetetlen vitézé, a ki nem tér vissza sikertelenül.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
És Káldea prédává lesz, a kik prédára vetik őt, mind betelnek vele, azt mondja az Úr.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
Csak örüljetek, csak tomboljatok örökségem elpusztítói: csak ugrándozzatok, mint a nyomtató tinó, és nyerítsetek, mint a ménlovak.
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
Megszégyenül a ti anyátok, a ti szűlőtök igen csúffá lesz: Ímé, a nemzetek seprejévé, pusztává, szárazfölddé, sivataggá lesz.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
Az Úr haragja miatt nem lakoznak rajta, hanem egészen pusztasággá lesz, a ki csak átmegy Babilonon, álmélkodik és sziszeget egész veresége felett.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Sorakozzatok köröskörül Babilon ellen, mind ti ijjászok, lőjjetek reá, ne kiméljétek a nyilat; mert az Úr ellen vétkezett!
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Kiáltsatok reá köröskörül, kezét adta, lehullottak az ő szegletkövei, leromlottak az ő kőfalai: bizony az Úr büntetése ez; büntessétek meg őt, és a mint cselekedett, úgy cselekedjetek vele.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Vágjátok ki Babilonból a magvetőt és a ki sarlót fog aratás idején; a gyilkos fegyver elől kiki az ő népéhez szalad, kiki az ő földe felé fut.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
Elszéledt juhnyáj az Izráel, oroszlánok kergették szét; először benyelte őt Assiria királya, végre pedig ez a Nabukodonozor, a babiloni király megtörte az ő csontjait.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
Azért ezt mondja a Seregek Ura, az Izráel Istene: Ímé, én megfenyítem a babiloni királyt és az ő földét, miként megfenyítém az assiriai királyt.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
És visszaviszem az Izráelt az ő lakhelyére, és Básánban legel és a Kármelen, és az Efraim hegyén és Gileádban megelégszik az ő lelke.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
Azokban a napokban és abban az időben, azt mondja az Úr, kerestetik az Izráel bűne, de nem lesz; a Júda vétkei, de nem találtatnak: mert kegyelmes leszek azokhoz, a kiket meghagyok.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
A kétszer pártütők földére menj fel, és a meglátogattatás lakóit irtsd ki, öljed és irtsad őket, azt mondja az Úr, és mind a szerint cselekedjél, a mint parancsoltam néked.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Harczi zaj a földön és nagy romlás.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Hogy elmúlott és összetört az egész föld pőrölye! milyen útálatossá lett Babilon a nemzetek között.
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
Tőrbe ejtettelek téged, és meg is fogattál Babilon, de nem tudtad, utól érettél és megragadtattál, mert pörlekedtél az Úrral.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
Felnyitotta az Úr az ő tárházát, és előhozta az ő haragjának szereit: mert e cselekedet az Úré, a Seregek Uráé Káldea földén.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Törjetek reá a szélekről, nyissátok fel az ő magtárait, tapodjátok őt, mint a kévét, és irtsátok ki, hogy ne legyen maradéka.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Döfjétek le minden tulkát, le velök a vágóhídra! Oh jaj nékik; mert eljött az ő napjok, az ő megfenyíttetésök ideje!
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
A futók és a Babilon földéből menekülők zaja megjelentik majd a Sionon az Úrnak a mi Istenünknek bosszúállását, az ő templomáért való bosszúállását.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Gyűjtsetek össze Babilon ellen igen sokat, mindenkit a ki kézívet feszít, köröskörül járjatok ellene tábort, hogy senki el ne szaladhasson: fizessetek meg néki az ő cselekedete szerint, a mint ő cselekedett, úgy cselekedjetek vele; mert az Úr ellen kevélykedett, az Izráelnek Szentje ellen!
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
Azért elhullanak az ő ifjai az ő utczáiban, és minden vitéze elvész azon a napon, azt mondja az Úr.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
Ímé, én ellened vagyok, te kevély, azt mondja az Úr, a Seregek Ura, mert eljött a te napod, a te megfenyítésed napja.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
És megbotlik a kevély és elesik, és senki nem lesz, a ki felköltse őt, és tüzet gyújtok az ő városaiban, hogy megemészsze azokat, a kik körülte vannak.
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Ezt mondja a Seregek Ura: Megnyomoríttattak az Izráel fiai és Júda fiai együtt és mindnyájan, a kik fogságra vitték őket, beléjök ragadnak, nem akarják őket elbocsátani.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
De az ő megváltójok erős, Seregek Ura az ő neve, bizonynyal felveszi az ő peröket, hogy megnyugtassa e földet, és Babilon lakóit megrettentse.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
Fegyver lesz a Káldeusokon, azt mondja az Úr, és Babilon lakóin és az ő fejedelmein és az ő bölcsein.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
Fegyver lesz az ő varázslóin, és megbolondulnak; fegyver lesz az ő vitézein, és elijednek.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
Fegyver lesz az ő lovain és szekerein és az egész egyveleg népen, a mely ő benne van, és hasonlók lesznek az asszonyokhoz. Fegyver lesz az ő kincsein, és elprédáltatnak.
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
Szárazság lesz az ő vizein, és kiszáradnak, mert bálványok földe az, és faragott képekkel dicsekednek.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
Azért sakálok lakoznak ott baglyokkal, és struczmadárnak fiai lakoznak benne, és soha többé nem lakják azt, és nem lesznek lakosai nemzedékről nemzedékre.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
A mint felforgatta Isten Sodomát és Gomorát és az ő szomszéd városait, azt mondja az Úr, ép úgy nem lakik ott egy ember sem, és embernek fia sem lakja azt.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Ímé, nép jött északról, és nagy nemzet és sok király támad fel a föld határaiból.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Ívet és paizst ragadnak, kegyetlenek azok, és semmi irgalmasság nem lesz bennök, szavok mint a tenger zúgása, és lovakon jőnek, mind viadalra készek te ellened, te Babilon leánya!
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
Hallja a babiloni király az ő híröket, és kezei elesnek, szorongás fogja el őt, fájdalom, mint a gyermekszűlőt.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Ímé, mint a Jordán erdőségéből való oroszlán, úgy jön fel az örökzöld ligetre, de hamar kiűzöm őt arról, és a ki arra választatott, azt teszem azon fejedelemmé, mert kicsoda hasonlatos hozzám? és ki szab nékem törvényt, és ki az a pásztor, a ki ellenem álljon?
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
Azért halljátok meg az Úr tervét, a melyet Babilon ellen tervezett, és az ő gondolatait, a melyeket Káldea ellen gondolt. Bizony elhajtják őket, a nyáj kicsinyeit, és álmélkodik felettök a legelő.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Babilon bevételének zajától megindul a föld, és kiáltása hallatszik a nemzetek között!

< Jeremiah 50 >