< Jeremiah 50 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
Parole que le Seigneur dit sur Babylone et sur les Chaldéens par l’entremise de Jérémie, le prophète.
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Annoncez parmi les nations, et faites-le entendre; levez l’étendard, publiez, ne cachez point, dites: Babylone est prise. Bel est couvert de confusion, Mérodach est vaincu; ses images taillées au ciseau sont couvertes de confusion, leurs idoles sont vaincues.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Parce qu’une nation est montée contre elle venant de l’aquilon, laquelle réduira sa terre en solitude; et il n’y aura personne qui habitera en elle depuis l’homme jusqu’à la bête; et ils ont été troublés, et ils s’en sont allés.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
En ces jours-là, et en ce temps-là, dit le Seigneur, viendront les fils d’Israël et les fils de Juda, et marchant ensemble, et pleurant, ils se hâteront et ils chercheront le Seigneur leur Dieu.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
Ils demanderont le chemin de Sion; vers elle se tourneront leurs faces. Ils viendront et s’uniront au Seigneur par une alliance éternelle qui ne sera nullement effacée par l’oubli.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Mon peuple est devenu un troupeau perdu; leurs pasteurs les ont séduits et les ont fait errer dans les montagnes; ils sont passés d’une montagne en une colline; ils ont oublié le lieu de leur repos.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
Tous ceux qui les ont trouvés les ont dévorés; et leurs ennemis ont dit: Nous n’avons pas péché; parce qu’ils ont péché contre le Seigneur, la splendeur de la justice, contre le Seigneur, l’attente de leurs pères.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Retirez-vous du milieu de Babylone, et sortez de la terre des Chaldéens; soyez comme des béliers devant un troupeau.
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Parce que voilà que moi je suscite et que j’amènerai contre Babylone une assemblée de grandes nations de la terre de l’Aquilon; et elles se prépareront contre elle; et de là elle sera prise; sa flèche, comme celle d’un homme fort qui tue, ne retournera pas vide.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
Et la Chaldée sera en proie: tous ses dévasteurs seront remplis de dépouilles, dit le Seigneur.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
Parce que vous exultez et dites de grandes choses en pillant mon héritage; parce que vous vous êtes répandus comme des veaux sur l’herbe et que vous avez mugi comme des taureaux.
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
Votre mère a été couverte de confusion extrêmement, et elle a été égalée à la poussière, celle qui vous a engendrés; voilà qu’elle sera la dernière parmi les nations, déserte, sans chemin frayé, et aride.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
À cause de la colère du Seigneur, elle ne sera pas habitée, mais elle sera tout entière réduite en une solitude; quiconque passera par Babylone, sera frappé de stupeur et sifflera sur toutes ses plaies.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Préparez-vous contre Babylone de tous côtes, vous tous qui tendez l’arc; combattez-la, n’épargnez point les flèches, parce que c’est contre le Seigneur qu’elle a péché.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Criez contre elle; partout elle a donné la main; ses fondements sont tombés, ses murs sont détruits, parce que c’est la vengeance du Seigneur, prenez vengeance d’elle; comme elle a fait, faites-lui.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Exterminez de Babylone le semeur, et celui qui tient la faucille au temps de la moisson; à la force du glaive de la colombe chacun vers son peuple retournera, et les uns après les autres dans leur terre s’enfuiront.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
C’est un troupeau dispersé qu’Israël; des lions l’ont chassé; le premier qui l’a mangé est le roi d’Assur; celui-ci, le dernier, lui a brisé les os, Nabuchodonosor, roi de Babylone.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur des armées, le Dieu d’Israël: Voilà que moi je visiterai le roi de Babylone, et sa terre, comme j’ai visité le roi d’Assur;
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
Et je ramènerai Israël dans sa demeure, il paîtra sur le Carmel et en Basan, et sur la montagne d’Ephraïm et de Galaad son âme se rassasiera.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
En ces jours-là, et en ce temps-là, dit le Seigneur, on cherchera l’iniquité d’Israël et elle ne sera pas; le péché de Juda et il ne sera pas trouvé; parce que je serai propice à ceux que j’aurai laissés.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
Monte sur la terre des dominateurs, et visite ses habitants; dissipe et tue ce qui est derrière eux, dit le Seigneur; et fais tout selon que je t’ai ordonné.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Voix de guerre sur la terre et grande destruction.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Comment a-t-il été rompu et brisé, le marteau de toute la terre? Comment Babylone a-t-elle été changée en un désert parmi les nations?
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
Je t’ai enlacée, et tu as été prise, Babylone, et tu ne le savais pas; tu as été trouvée et saisie, parce que c’est le Seigneur que tu as provoqué.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
Le Seigneur a ouvert son trésor et il en a tiré les instruments de sa colère, parce que le Seigneur, Dieu des armées, en a besoin dans la terre des Chaldéens.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Venez vers elle des confins les plus éloignés; ouvrez, afin que sortent ceux qui doivent la fouler aux pieds; ôtez de la voie les pierres, et mettez-les en monceaux, et tuez-la et qu’il n’y ait rien de reste.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Dissipez tous ses braves, qu’ils descendent à la tuerie; malheur à eux, parce qu’est venu leur jour, le temps de leur visite.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Voix de ceux qui fuient, de ceux qui sont échappés de la terre de Babylone, afin qu’ils annoncent à Sion la vengeance du Seigneur, notre Dieu, la vengeance de son temple.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Annoncez à tous ceux qui tendent l’arc en si grand nombre de marcher contre Babylone; tenez-vous contre elle tout au autour, et que personne n’échappe; rendez-lui selon son œuvre; selon tout ce qu’elle a fait, faites-lui, parce que c’est contre le Seigneur qu’elle s’est élevée, contre le saint d’Israël.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
C’est pour cela que ses jeunes hommes tomberont sur ses places et que tous ses hommes de guerre se tairont en ce jour-là, dit le Seigneur.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
Voilà que moi-même je viens à toi, superbe, dit le Seigneur, Dieu des armées, parce qu’est venu ton jour, le jour de ta visite.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
Et il tombera, le superbe, et il sera renversé, et il n’y aura personne qui le relèvera; et j’allumerai un feu dans ses villes; et il dévorera tout ce qui est autour de lui.
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Voici ce que dit le Seigneur des armées: Les fils d’Israël et les fils de Juda souffrent ensemble l’oppression: tous ceux qui les ont pris les retiennent, et ne veulent pas les laisser aller.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
Leur rédempteur est fort; son nom est le Seigneur des armées; en jugement il défendra leur cause, afin d’épouvanter la terre et d’agiter les habitants de Babylone.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
Glaive sur les Chaldéens, dit le Seigneur, sur les habitants de Babylone, sur ses princes et ses sages.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
Glaive sur ses devins qui seront insensés; glaive sur ses braves qui seront dans l’effroi.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
Glaive sur ses chevaux et sur ses chars, et sur tout le peuple qui est au milieu d’elle; et ils seront comme des femmes; glaive sur ses trésors qui seront pillés.
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
La sécheresse sera sur ses eaux, et elles tariront; parce que c’est la terre des images taillées au ciseau, et ils se glorifient dans des monstres.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
À cause de cela, les dragons y habiteront avec les faunes qui recherchent les figues; et les autruches habiteront en elle; et elle ne sera plus habitée à jamais, elle ne sera pas reconstruite dans la suite des générations.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
Ainsi que le Seigneur a renversé Sodome et Gomorrhe, et ses voisines, dit le Seigneur; un homme n’y habitera pas, et le fils d’un homme n’y séjournera pas.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Voilà qu’un peuple vient de l’Aquilon, et une grande nation, et un grand nombre de rois s’élèveront des confins de la terre.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Ils saisiront l’arc et le bouclier; ils sont cruels et impitoyables; leur voix comme la mer retentira; et sur leurs chevaux ils monteront comme un homme prêt au combat contre toi, fille de Babylone.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
Le roi de Babylone a appris la nouvelle de leur dessein, et ses mains ont défailli; l’angoisse l’a saisi, et la douleur, comme une femme en travail.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Voilà que comme un lion il montera de l’orgueil du Jourdain vers une beauté puissante; parce que soudain je le ferai courir vers elle; et quel est l’élu que je préposerai sur elle? car qui est semblable à moi? qui tiendra contre moi? et quel est le pasteur qui résistera à mon visage?
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
À cause de cela, écoutez le dessein que le Seigneur a conçu en son esprit contre Babylone, et les pensées qu’il a méditées contre la terre des Chaldéens; il a dit: Je jure si les petits troupeaux, ne les enlèveront pas; et si leur habitation ne sera pas détruite avec eux.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
À la voix de la captivité de Babylone, la terre a été agitée, et une clameur parmi les nations a été entendue.