< Jeremiah 50 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
La parole que Yahweh prononça sur Babylone, sur le pays des Chaldéens, par l'intermédiaire de Jérémie, le prophète.
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Annoncez-le parmi les nations, publiez-le; élevez un étendard, publiez-le; ne le cachez pas, dites: Babel est prise! Bel est confondu, Mérodach est abattu; ses idoles sont confondues, ses faux dieux sont abattus.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Car du septentrion un peuple monte contre elle; il fera de son pays une solitude, il n'y aura plus d'habitant; hommes et bêtes ont fuit, se sont en allés.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
En ces jours-là et en ce temps-là, — oracle de Yahweh, les enfants d'Israël reviendront, eux et les enfants de Juda avec eux; ils marcheront en pleurant, et chercheront Yahweh, leur Dieu.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
Ils demanderont Sion, et tourneront leur face vers elle. " Venez et attachons-nous à Yahweh par une alliance éternelle, qui ne soit jamais oubliée. "
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Mon peuple était un troupeau de brebis qui se perdaient; leurs bergers les égaraient sur des montagnes perfides; elles allaient de montagne en colline, oubliant leur bercail.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
Tous ceux qui les trouvaient les dévoraient, et leurs ennemis disaient: " Nous ne sommes pas coupables! " Parce qu'elles avaient péché contre Yahweh, la demeure de justice, contre Yahweh, l'espérance de leurs pères.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Fuyez du milieu de Babylone, et sortez du pays des Chaldéens; soyez comme les boucs, à la tête du troupeau.
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Car voici que je vais susciter et faire marcher contre Babel une réunion de grands peuples; venant du pays du septentrion. Ils se rangeront contre elle, et de ce côté-là elle sera prise; leurs flèches sont celles d'un guerrier habile, qui ne revient pas à vide.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
Et la Chaldée sera mise au pillage, tous ceux qui la pilleront se rassasieront, — oracle de Yahweh.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
Oui, réjouissez-vous; oui, livrez-vous à l'allégresse, pillards de mon héritage; oui, bondissez comme une génisse dans la prairie, hennissez comme des étalons!
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
Votre mère est couverte de confusion; celle qui vous a enfantés rougit de honte. Voici qu'elle est la dernière des nations, un désert, une steppe, une terre aride.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
A cause de la colère de Yahweh, elle ne sera plus habitée, ce ne sera plus qu'une solitude; quiconque passera près de Babel s'étonnera et sifflera à la vue de ses plaies.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Rangez-vous contre Babel, tout autour, vous tous, archers! Tirez contre elle, n'épargnez pas les flèches, car elle a péché contre Yahweh.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Poussez de tous côtés contre elle un cri de guerre; elle tend les mains; ses tours s'écroulent, ses murs sont renversés. Car c'est la vengeance de Yahweh: vengez-vous sur elle; faites-lui comme elle a fait!
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Exterminez de Babel celui qui sème, et celui qui manie la faucille au jour de la moisson. Devant le glaive destructeur, que chacun se tourne vers son peuple, que chacun fuie vers son pays.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
Israël est une brebis égarée a qui les lions ont fait la chasse; le premier l'a dévorée: le roi d'Assyrie; puis cet autre lui a brisé les os: Nabuchodonosor, roi de Babel.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
C'est pourquoi ainsi parle Yahweh des armées, Dieu d'Israël: Voici que je vais visiter le roi de Babel et son pays, comme j'ai visité le roi d'Assyrie.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
Et je ramènerai Israël dans sa demeure; et il paîtra au Carmel et en Basan; et sur la montagne d'Ephraïm et de Galaad, il ira se rassasier.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
En ces jours-là et en ce temps-là, — oracle de Yahweh, on cherchera l'iniquité d'Israël, et elle ne sera plus; le péché de Juda, et on ne le trouvera plus; car je pardonnerai au reste que j'aurai laissé.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
Monte contre le pays de Rébellion et contre les habitants de Punition; détruis, extermine-les, les uns après les autres, — oracle de Yahweh, et fais-leur tout ce que je t'ai ordonné.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Bruit de bataille dans le pays et grand massacre!
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Comment a été rompu et brisé, le marteau de toute la terre? Comment Babel, est-elle devenue un objet d'horreur, au milieu des nations?
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
J'ai tendu des lacets, et tu as été prise, Babel, sans t'en douter; tu as été trouvée et saisie, parce que tu t'es mise en guerre contre Yahweh.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
Yahweh a ouvert son arsenal, et il en a tiré les armes de sa colère; car le Seigneur Yahweh des armées, a affaire au pays des Chaldéens.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Arrivez contre elle de toutes parts, ouvrez ses greniers, entassez tout comme des gerbes, et exterminez; qu'il n'en reste rien!
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Tuez tous les taureaux, qu'ils descendent à la boucherie! Malheur à eux car leur jour est arrivé, le temps où ils seront visités.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Cris des fuyards et de ceux qui se sauvent du pays de Babel! ils annoncent en Sion la vengeance de Yahweh, notre Dieu, la vengeance de son temple.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Appelez contre Babel des archers, tous ceux qui bandent l'arc; campez autour d'elle: que personne n'échappe! Rendez-lui selon ses œuvres, tout ce qu'elle a fait, faites-le lui; car elle s'est élevée contre Yahweh, contre le Saint d’Israël.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
C'est pourquoi ses jeunes gens tomberont sur ses places, et tous ses hommes de guerre périront en ce jour, — oracle de Yahweh.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
Me voici contre toi, insolente! — oracle du Seigneur Yahweh des armées; car ton jour est venu, le temps où je visite.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
Elle chancellera, l'insolente, elle tombera, et personne ne la relèvera; je mettrai le feu à ses villes, et il dévorera tous ses alentours.
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Ainsi parle Yahweh des armées: Les enfants d'Israël sont opprimés et avec eux les enfants de Juda; tous ceux qui les ont emmenés captifs les retiennent; et refusent de les lâcher.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
Mais leur vengeur est fort; Yahweh des armées est son nom; il défendra puissamment leur cause, pour donner le repos à la terre, et faire trembler les habitants de Babel.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
Epée contre les Chaldéens, — oracle de Yahweh, et contre les habitants de Babel, et contre ses chefs et contre ses sages!
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
Epée contre les imposteurs, et qu'ils perdent le sens! Epée contre ses braves, et qu'ils tremblent!
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
Epée contre ses chevaux et ses chars, et contre toute la tourbe des gens qui sont au milieu d'elle, et qu'ils soient comme des femmes! Epée contre ses trésors, et qu'ils soient pillés!
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
Sécheresse sur ses eaux, et qu'elles tarissent! Car c'est un pays d'idoles, et devant ces épouvantails ils délirent.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
Aussi les animaux du désert s'y établiront avec les chacals; les autruches y feront leur demeure; elle ne sera jamais plus peuplée; elle ne sera plus habitée d'âge en âge.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
Comme lorsque Dieu détruisit Sodome, Gomorrhe et les villes voisines, — oracle de Yahweh, personne n'y demeurera, aucun fils d'homme n'y séjournera.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Voici qu'un peuple arrive du Septentrion; une grande nation et des rois nombreux se lèvent des extrémités de la terre.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Ils tiennent à la main l'arc et le javelot; ils sont cruels et sans pitié. Leur voix gronde comme la mer; ils sont montés sur des chevaux, rangés comme un seul homme pour la guerre, contre toi, fille de Babel.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
Le roi de Babel a appris la nouvelle, et ses mains ont défailli; l'angoisse l'a saisi, les douleurs d'une femme qui enfante.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Pareil à un lion, voici qu’il monte des halliers du Jourdain au pâturage perpétuel; et soudain je les en ferai fuir, et j'y établirai celui que j'ai choisi. Car qui est semblable à moi? Qui me provoquerait, et quel est le berger qui me tiendrait tête?
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
Ecoutez donc la résolution de Yahweh qu'il a prise contre Babel, et les desseins qu'il a médités contre le pays des Chaldéens: Oui, on les entraînera comme de faibles brebis; oui, le pâturage en sera dans la stupeur!
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Au bruit de la prise de Babel, la terre tremble, un cri se fait entendre chez les nations!

< Jeremiah 50 >