< Jeremiah 50 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
Nämät ovat ne sanat, jotka Herra on propheta Jeremian kautta puhunut Babelin ja Kaldealaisten maata vastaan.
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Julistakaat pakanain seassa ja tiettäväksi tehkäät, nostakaat lippu ylös, kuuluttakaat ja älkäät sitä salatko, ja sanokaat: Babel on voitettu, Bel on häpiään joutunut, Merodak on rikottu, hänen epäjumalansa ovat häpiään tulleet, ja hänen jumalansa ovat murskaksi lyödyt.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Sillä pohjoisesta nousee kansa heitä vastaan, jonka pitää heidän maansa hävittämän, niin ettei kenenkään pidä siinä asuman, vaan sekä ihmiset että eläimet sieltä pakeneman.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Niinä päivinä ja siihen aikaan, sanoo Herra, pitää Israelin lasten Juudan lasten kanssa tuleman, ja pitää joudukkaasti käymän ja itkemän, ja etsimän Herraa Jumalaansa.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
Heidän pitää kysymän tietä Zioniin ja kääntämän itsensä sinne: tulkaat, ja me tahdomme pysyä Herrassa ijankaikkisella liitolla, joka ei ikänä pidä unhotettaman.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Minun kansani on tullut kadonneeksi laumaksi; heidän paimenensa ovat heidät vietelleet ja antaneet heidän eksyksissä kävellä vuorilla, niin että he ovat vuorilta menneet kukkuloille, ja ovat unhottaneet majansa.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
Kuka ikänä heidän tykönsä tuli, se söi heitä, ja heidän vihollisensa sanoivat: emmepä me tee väärin, sillä he ovat rikkoneet Herraa vastaan vanhurskauden asumuksessa, ja Herraa vastaan, joka heidän isänsä toivo on.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Paetkaat Babelista ja lähtekäät pois Kaldealaisten maasta ulos, ja laittakaat teitänne niinkuin kauriit lauman edellä.
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Sillä katso, minä nostan suuren väen joukoittain pohjan maalta, ja annan heidän tulla Babelin eteen; heidän pitää varustaman itsensä häntä vastaan, ja voittaman hänen. Heidän nuolensa ovat niinkuin taitavan sotamiehen, joka ei tyhjään ammu.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
Ja Kaldean maa pitää tuleman saaliiksi, niin että kaikkein, jotka sitä ryöstävät, pitää siitä kyllä saaman, sanoo Herra.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
Että te iloitsette siitä ja kerskaatte itsiänne, että te olette minun perintöni ryöstäneet, ja hyppelette niinkuin lihavat vasikat, ja hirnutte niinkuin väkevät (hevoset).
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
Teidän äitinne on suureen häpiään joutunut, ja se häpee, joka teidät on synnyttänyt; katso, hän on pakanain seassa kaikkein huonoin, autio, kuiva ja hävinnyt.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
Herran vihan tähden ei pidä siinä asuttaman, vaan se kokonansa autiona oleman; niin että kaikkein, jotka menevät ohitie Babelia, pitää ihmettelemän ja viheltämän kaikkein hänen vaivainsa tähden.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Varustakaat teitänne Babelia vastaan, joka taholta kaikki ampujat, ampukaat häntä, älkäät säästäkö nuolia; sillä hän on rikkonut Herraa vastaan.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Riekukaat häntä vastaan joka taholta; hänen pitää myötä antaman, hänen perustuksensa ovat langenneet, ja hänen muurinsa hajonneet; sillä se on Herran kosto, kostakaat hänelle, ja tehkäät hänelle niinkuin hän on tehnyt.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Hävittäkäät sekä kylväjä että se, joka sirppiin rupee elonaikana; niin että jokainen kääntää itsensä kansansa tykö hävittäjän miekan tähden, ja jokainen pakenee maallensa.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
Israelin täytyy olla hajoitetun lammaslauman, jonka jalopeurat ovat hajoittaneet. Ensisti söi Assurian kuningas hänen, sitte särki Nebukadnetsar, Babelin kuningas, hänen luunsa.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
Sentähden sanoo Herra Zebaot, Israelin Jumala, näin: minä etsin Babelin kuninkaan ja hänen maansa, niinkuin minä olen Assurian kuninkaan etsinyt.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
Mutta Israelin minä annan tulla jälleen kotia asumasiaansa, niin että hänen pitää itsensä elättämän Karmelissa ja Basanissa, ja Ephraimin vuorella, ja Gileadissa pitää hänen sielunsa ravituksi tuleman.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
Niinä päivinä ja siihen aikaan, sanoo Herra, pitää Israelin pahateko etsittämän, ja ei löyttämän, ja Juudan synti, ja ei pidä löyttämän; sillä minä olen armollinen niille, jotka minä jätän.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
Mene kapinan nostajain maahan, mene sinne ylös, ja etsi etsikon asuvaisia; hävitä ja tapa heidän jälkeentulevaisensa, sanoo Herra, ja tee kaikki, mitä minä olen käskenyt sinulle.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Maalla on sodanriekuna ja iso suru.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Kuinka se on tullut, että koko maailman vasara on taitettu ja rikottu? Kuinka Babel on autioksi joutunut pakanain seassa?
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
Minä olen virittänyt paulan sinun etees, Babel, sentähden olet sinä myös vangittu, ennen kuin sinä havaitsitkaan; sinä olet osattu ja olet käsitetty, sillä sinä olet kehoittanut Herran.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
Herra on avannut tavarahuoneensa, ja vetänyt edes vihansa aseet; sillä tämä on Herran, Herran Zebaotin työ Kaldealaisten maalla.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Tulkaat tänne häntä vastaan, te viimeisistä ääristä, avatkaa hänen jyvähuoneensa, paiskatkaat häntä kokoon, ja tappakaat häntä, niin ettei hänelle mitään jää.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Surettakaat kaikki hänen mullinsa, viekäät häntä alas teurastettaa; voi heitä! sillä päivä on tullut, heidän etsikkonsa aika.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Huuto kuuluu paenneilta ja päässeiltä Babelin maasta, että heidän pitää julistaman Zionissa Herran meidän Jumalamme kostoa ja hänen kirkkonsa kostoa.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Kutsukaat monta Babelia vastaan, piirittäkäät häntä kaikki joutsenampujat joka taholta ympäri, ja älkäät yhtään päästäkö; kostakaat hänelle niin kuin hän on ansainnut; kaiken sen jälkeen kuin hän on tehnyt, niin tehkäät hänelle jälleen; sillä hän on ylpiästi tehnyt Herraa vastaan, Pyhää Israelissa.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
Sentähden pitää hänen nuorukaisensa lankeeman hänen kaduillansa, ja kaikki hänen sotamiehensä hukkuman siihen aikaan, sanoo Herra.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
Katso, sinä ylpeä, minä tahdon sinun kimppuus, sanoo Herra, Herra Zebaot: sillä sinun päiväs on tullut, sinun etsikkos aika.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
Silloin pitää ylpeän itsensä loukkaaman ja lankeeman, niin ettei kenenkään pidä häntä auttaman ylös; ja minä sytytän hänen kaupunkinsa palamaan tulella, jonka pitää kuluttaman kaikki, mitä siinä ympärillä on.
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Näin sanoo Herra Zebaot: katso, Israelin lasten ja Juudan lasten pitää ynnä väkivaltaa ja vääryyttä kärsimän; kaikki ne, jotka heidän ovat vankina vieneet, pitävät heidät, ja ei tahdo heitä päästää vallallensa.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
Mutta heidän vapahtajansa on väkevä, Herra Zebaot on hänen nimensä, hän on niin toimittava heidän asiansa, että hän saattaa maan lepäämään ja Babelin asuvaiset värisemään.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
Miekan pitää tuleman, sanoo Herra, Kaldealaisten päälle, ja Babelin asuvaisten päälle, ja hänen ruhtinastensa päälle, ja hänen tietäjäinsä päälle.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
Miekan pitää tuleman hänen noitainsa päälle, niin että heidän pitää tyhmäksi tuleman; miekan pitää tuleman hänen väkeväinsä päälle, että heidän pitää epäilemän.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
Miekan pitää tuleman hänen hevostensa ja ratastensa päälle ja kaiken yhteisen kansan päälle, joka hänen keskellänsä on, niin että heidän pitää tuleman niinkuin vaimot; miekan pitää tuleman hänen riistahuoneensa päälle, niin että ne pitää ryöstetyksi tuleman.
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
Kuivuuden pitää tuleman hänen vettensä päälle, niin että ne pitää kuivuman; sillä se on epäjumalain maa, ja he röyhkeilevät kauheista epäjumalistansa.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
Sentähden pitää petoin ja julmain lintuin siellä asuman, ja yökköin pitää myös siellä asuman; ja ei pidä ikänä enään siinä asuttaman, eikä jonkun siinä oleman suvusta sukuun.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
Niinkuin Herra Sodoman ja Gomorran lähikyläinsä kanssa kukistanut on, sanoo Herra, niin ei siellä kenenkään asuman pidä, eli jonkun ihmisen siellä oleman.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Katso, kansa tulee pohjoisesta; monta pakanaa ja monta kuningasta pitää nouseman maan ääristä.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Heillä on joutsi ja kilpi, he ovat julmat ja armottomat; heidän huutonsa on niinkuin meren pauhina; he ajavat hevosilla niinkuin sotamiehet, varustetut sinua vastaan, sinä Babelin tytär.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
Kuin Babelin kuningas on kuuleva heidän sanomansa, silloin pitää hänen kätensä maahan putooman; ahdistus pitää tuleman hänen päällensä, niinkuin synnyttäväisen vaiva.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Katso, hän nousee ylös niinkuin jalopeura ylpeästä Jordanista vahvoja majoja vastaan, sillä minä annan hänen nopiasti juosta sieltä; ja kuka tietää sen nuorukaisen, jonka minä olen varustava heitä vastaan? Sillä kuka on minun vertaiseni? kuka tahtoo minulle ajan määrätä? ja kuka on se paimen, joka voi olla minua vastaan?
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
Kuulkaat siis nyt Herran neuvoa, jonka hän piti Babelista, ja hänen ajatuksiansa, jotka hän ajatteli Kaldean maan asuvaisista: mitämaks että karjalaisten pitää riepoittaman heitä, ja kukistaman heidän asumansa.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Ja maan pitää vapiseman riekunasta, ja pitää kuuluman pakanain seassa, kuin Babel voitetaan.

< Jeremiah 50 >