< Jeremiah 50 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
Yahweh gave to [me, ] Jeremiah the prophet, a message about Babylon [city] and the country of Babylonia.
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
[This is what Yahweh says]: “Proclaim [DOU] [a message] among the nations; do not withhold any of it; raise up a signal flag to announce that Babylon will be captured. [Its chief god] Marduk, [whose other name is] Bel, will be completely disgraced, and all the [other] statues and idols will be shattered.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
[The army of] a nation will come from the north to attack Babylon and destroy the city very thoroughly, [with the result that] no one will live there [again]. Both people and animals will run away.”
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
“But [I, ] Yahweh, say that in the future, when that is about to happen, the people of Israel and the people of Judah will join together. They will be weeping and wanting [to worship] me, their God.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
They will inquire about the road to Jerusalem, [and then] they will start traveling [IDM] toward it. They will say [to each other], ‘We must return to Yahweh [again]!’ They will make an everlasting agreement with me that they will never forget.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
My people have been [like] [MET] lost sheep. Their [leaders/rulers] have caused them [to abandon me] like [MET] shepherds who have allowed their sheep to wander in the hills and mountains. [My people are like] [MET] sheep that do not know the path to return to the sheepfold.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
All their enemies who found them attacked them. They said, ‘We did not sin [by attacking them], because they sinned against Yahweh; he is the one who provides what they need; he is the one to whom they should have remained faithful; he is the one whom their ancestors confidently expected [to help them].’
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
[But now, I say to the leaders of my people], ‘Flee from Babylon! Leave the land of Babylonia! Be like [SIM] male goats [that go] in front of [the rest of] the flock; [lead my people back to their own land].
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
[Do that] because I am going to gather an army of great nations to the north [of Babylon]. They will join together to attack Babylon and will capture it. Their arrows will be like [SIM] skilled warriors that always hit what they aim at.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
Babylonia will be conquered, and those who conquer it will take away everything they want. [That will surely happen because I, ] Yahweh, have said it.’”
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
“You people [of Babylon] who (plundered/stole everything valuable from) my chosen people, now you are very happy [DOU]. You run around joyfully like [SIM] a calf in a meadow, and are happy like [SIM] male horses are happy when they are neighing.
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
But [soon] your people will be very disgraced [DOU] [as a result of being conquered]. Your country will be the most insignificant nation; it will be a desert, a dry and deserted land.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
Because [I, ] Yahweh, am angry [with you people of Babylon], I will cause your city to become completely deserted. All who pass by will be horrified and will (gasp/be shocked) because of the destruction there.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
[All you nations that surround Babylon, ] prepare to attack it! Tell your archers to shoot at their enemies; shoot all of your arrows at them [LIT], because [the people/leaders of Babylon have sinned against me, ] Yahweh.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Shout [war-cries] against Babylon from all sides [of the city]. [The soldiers of] Babylon will surrender; the towers and walls will be torn down. It is [I, ] Yahweh, who will be getting revenge [on the people of Babylon], [so help me to] get revenge. Do to [the people of] Babylon what they have done to others!
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Take away from Babylon those who plant [crops] and those who reap the harvests! Because of the swords carried by those who will attack [Babylon], [those people in Babylon who have come from other countries] should all run away, back to their own countries [DOU]!”
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
“The Israeli [people] are [like] [MET] sheep that have been scattered by lions. First [the army of] the King of Assyria defeated them. Then [the army of] King Nebuchadnezzar of Babylon smashed them.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
So this is what I, the Commander of the armies of angels, the God whom the Israeli people [worship], say: ‘Now I will punish the King of Babylon and the people of his land, like I punished the King of Assyria.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
And I will bring the people of Israel back to their own land where they will eat [the food that grows] in the fields of the Carmel and Bashan [regions], and [the people in] the hilly areas of Ephraim and Gilead will have all they want to eat.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
At that time, there will not be people in Israel and in Judah who [are still guilty for having] sinned [DOU], because I will forgive the small group of people whom I enable to still be alive.’”
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
“[So, I, Yahweh, say to the enemies of Babylonia, ]‘Attack [the people who live in] the Merathaim [region] and the people in the Pekod [region of Babylonia]. Pursue them, kill them, and completely get rid of them, as I have commanded you to do.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Shout your battle cries throughout the land; shout [when you are causing] great destruction.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
[The army of Babylon is like] [MET] the most powerful hammer on the earth, but it will be completely shattered. Babylon will be deserted among the [other] nations.’
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
You [people of] Babylon, [listen, ] [because] I have set a trap for you; you will be caught [in that trap], because you fought against me.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
[It is as though] I have opened the place where I store my weapons, and I have brought out [all] the weapons [to use against the people with whom] I am angry. [I, ] the Commander of the armies of angels, have [a lot of] work to do [to punish] the people of Babylonia.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
[So, you enemies of Babylonia, ] come from distant lands and attack it. Break open the places where they store the grain. Crush the walls of the city and the houses and pile up [the rubble like] [SIM] heaps of grain. Destroy everything; do not leave anything that is not destroyed.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Destroy all the [young men who are as strong as] [MET] bulls; take them to where you will slaughter them. It will be terrible for them, because it will be time for them to be punished.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Listen to the people who have fled and escaped from Babylon while they tell in Jerusalem how [I, ] Yahweh, have gotten revenge against those who destroyed my temple [in Jerusalem].
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Summon archers [DOU] to come to attack Babylon; surround the city in order that no one will escape. Do to [the people of] Babylon what they have done to others [DOU], because they have defied [me, ] the Holy One of the Israeli [people].
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
The young men of Babylon will fall in the streets; all their soldiers will be killed in one day.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
[I, ] the Commander of the armies of angels, say this: ‘You arrogant/proud people, it is now the time; it is the time [DOU] when I will punish you.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
[Your land is full of] proud people, but you will stumble and fall, and no one will lift you up [again]. I will light a fire in the cities in Babylonia that will burn up everything that is nearby.’
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
[I], the Commander of the armies of angels, also say this: ‘The people of Israel and Judah were (oppressed/treated cruelly); those who captured them guarded them carefully and would not allow them to leave [Babylon].
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
But I am strong, and I will free them. I am the Commander of the armies of angels; I will defend my people and enable them [to return to] their land where they will have peace, but the people of Babylonia will not have peace.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
[I will send enemy soldiers carrying] swords [PRS] to strike the people of Babylonia; they will strike the officials and wise men and all the [other] people who live in Babylon.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
They will strike their false prophets with swords and they will become foolish. They will strike the [strongest] warriors of Babylonia, and they will all be terrified.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
They will strike their horses and chariots and the foreigners who are in the army of Babylonia, and they will [all] become [as weak] as [MET] women. They will seize [MTY] all the valuable things there in Babylon and take them away.
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
[I] cause the streams to become dry. [I will do all those things] because the [entire] land [of Babylonia] is filled with idols, and those [horrible] idols have caused the people [who worship them] to become crazy.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
[Soon only] hyenas and [other] wild creatures will live there; and it will be a place where owls live. People will never live there again; it will be uninhabited forever [DOU].
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
[I will destroy Babylon] like I destroyed Sodom and Gomorrah and the nearby towns; no one will [ever] live there [again] [DOU].
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Look! A [great] army will come from the north. A great nation far away with many kings is preparing [to attack you people of Babylon].
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Their [army] has bows [and arrows] and spears; they are [very] cruel, and do not act mercifully [to anyone]. [As] they ride along on [their] horses, the sound of the horses’ hooves is like [SIM] the roaring of the ocean [waves]; they are riding in battle formation to attack you, you people of Babylon.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
The King of Babylon says, “[I] have heard reports about the enemy [approaching]; [so I am very frightened, with the result that] I am weak. I am [very fearful, and] anguished/worried, like [SIM] a woman who is about to give birth to a baby.”
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
I, [Yahweh], will come to Babylon [suddenly] like a lion comes out of the jungle and [leaps on the sheep that are eating] the good pastureland. I will quickly chase the people of Babylonia from their land. And [then] I will appoint for them [a leader] whom I will choose; [I will do that] because there is no one [RHQ] like me who can say that what I have done is not right. No ruler can [RHQ] oppose me.
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
Listen to what I have planned to do to the people of Babylon [city] and the rest of Babylonia: [even] the little children will be dragged away, and I will completely destroy the people [MET] who live there.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
When Babylon is destroyed, the noise will be extremely loud, with the result that the earth will shake, and the wailing of the people will be heard by the [people of other] nations.’”