< Jeremiah 50 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
Babilon hoi Khaldean taminaw e ram taranlahoi profet Jeremiah e pahni hno lahoi BAWIPA ni a dei e lawk teh,
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Miphunnaw koe dei pouh nateh pâpho haw. Lukkarei vo awh na teh, pathang awh. Hrawk awh hanh. Babilon la e lah ao vaiteh, Bel teh yeiraipo lah ao han. Merodak e cathut teh a kâkhoe toe. Babilon e meikaphawknaw teh yeiraipo awh teh, reppasei lah a kâbawng toe.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Bangkongtetpawiteh, ahni taranlahoi miphun buet touh atunglah hoi a tho teh, apihai kho sak hoeh nahanlah a ram hah kingdi, tami hoi moithangnaw hai yawng awh vaiteh awm awh mahoeh toe.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Hatnae hnin hoi tueng nah teh, Isarel catounnaw hah tho awh vaiteh, amamouh hoi Judah catounnaw hoi khuika laihoi tho awh vaiteh, BAWIPA Cathut a tawng awh han, telah BAWIPA ni a dei.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
Zion lah ceinae lamthung hah a pacei awh han, tho awh, yungyoe lawkkam pahnim hoeh nahanlah BAWIPA hnai awh telah ati awh han.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Ka taminaw teh tu kahmat e lah o awh. Tukhoumnaw ni mon dawk lam a payonsak toe. Ahnimanaw teh mon buet touh hoi buet touh dawk lam a kahma awh teh roumnae hmuen a pahnim awh toe.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
Kahmawtnaw pueng ni a kei awh teh, a tarannaw ni maimouh payon hoeh, BAWIPA e lannae kânguenae, a mintoenaw ni ngaihawinae BAWIPA lathueng roeroe vah yonnae a sak awh dawk doeh ati awh.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Babilon hoi kampuen awh, Khaldean ram dawk hoi tâcawt awh, hmaehu e rahak vah hmaetan patetlah awm awh.
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Bangkongtetpawiteh, thaihaw! Babilon tuk hanlah atunglae ram dawk hoi kalenpounge miphun hah thakasai sak vaiteh, ama tuk hanlah a kâcai vaiteh, hawvah man e lah ao han, a tahroe teh athakaawm ni teh tarantuk kathoume tami, ka thaw boihoeh e patetlah o han.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
Khaldean teh raphoe e lah awm vaiteh, haw vah ka raphoekungnaw kaboumlah ao awh han, telah BAWIPA ni a dei.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
Kaie râw na raphoe awh dawkvah, kanawmcalah na lunghawi awh nateh, hramkahring dawk maitolaca ka pâ e hoi marangtan ka cai e patetlah na o awh nakunghai,
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
na manu yeiraipo vaiteh, na kakhekung yeiraipo han. Khenhaw! miphunnaw thung dawk hoi ka rahnoumpoung e, ka ke ram, ramke, thingyeiyawn lah na o han.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
BAWIPA lungkhueknae kecu dawk apihai awm laipalah, kingdi lah o han. Babilon lah ka cet e taminaw pueng ni puen khai awh vaiteh, a rawkphainae dawk pathoenae lawk a dei awh han.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Babilon kalup awh nateh ven awh, pala hoi ka awh, thaw awh hanh, bangkongtetpawiteh, BAWIPA taranlahoi a yo toe.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
A tengpam vah hramki sak awh, amahoima a kâhmoun toe. A rapan rawm vaiteh, tapangnaw a tip han. Bangkongtetpawiteh, BAWIPA ni moipathung e doeh. A lathueng vah moipathung awh, a sak e patetlah a lathueng sak van awh.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Babilon vah cati kapatuekung hoi cangkaanaw hoi cangkatinnaw hah tâkhawng awh, repcoungroenaw e tahloi taki dawk mae taminaw koe pâtam awh vaiteh, mae ram lah a yawng awh han.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
Isarel teh tu kâhei e doeh. Sendek ni a pakhi, hatei siangpahrang ni ahni a ca teh a poutnae koe Babilon siangpahrang Nebukhadnezar ni a hru totouh be a khoe.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
Hatdawkvah, ransahu BAWIPA Isarel Cathut ni hettelah a dei. Khenhaw! Assiria siangpahrang ka rek patetlah Babilon siangpahrang hoi a ram hah ka rek han.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
Isarel teh yampa a onae koe ka hrawi han. Karmel hoi Bashan vah a pawngpa han. Ephraim mon hoi Gilead vah ahni teh kaboumcalah ao han.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
Hatnae hnin hoi tueng dawk Isarel yonnae ka tawng eiteh, hmawt mahoeh. Judah yonnae hai hmawt mahoeh. Bangkongtetpawiteh, kacawi ni teh ka pâhlung e naw hah ka ngaithoum awh, telah BAWIPA ni a dei.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
Marathaim ram heh tuk awh, A ram hoi Pekod vah khokasaknaw hah thet awh, he baw ditouh tâkhawng awh nateh kâ na poe e patetlah sak awh, telah BAWIPA ni a dei.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Hote ram dawk taran pawlawk hoi ka patawpoung e rawkkahmanae ao.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Talaivan pueng e cakkin a lawt teh a kâbawng toe. Miphunnaw thung hoi Babilon teh banghloimaw a rawk.
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
Oe Babilon nang hanlah karap ka patung, panuek laipalah na kâman toe. BAWIPA na taran dawkvah, hnephnap e hoi man e lah na o han.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
BAWIPA ni senehmaica bom a paawng teh lungkhueknae puengcang a la toe. Ransahu Jehovah Bawipa ni Khaldean taminaw e ram dawk sak hane a tawn.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Ramri poutnae koehoi tuk awh nateh, hnoim hah paawng awh. Kamkhueng awh nateh, he raphoe awh, banghai pâhlung hanh awh.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
A maitotan kanawnaw hah he thet awh, he thei e lah awm naseh. A yawkathout e lah ao awh. Bangkongtetpawiteh, a hnin a pha toe, ahni rek hnin roeroe a pha toe.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
BAWIPA Cathut ni moipathungnae, a bawkim moipathungnae hah Zion vah pathung hanlah Babilon hoi a yawng teh ka tâcawt e taminaw e pawlawk hah
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Babilon tuk hanlah palakathoumnaw pueng hah kaw awh. A tengpam vah tungpupnae rim sak awh nateh, apihai tâcawt hanh naseh. A sak awh e patetlah moipathung awh. A sak awh e naw pueng hah a lathueng sak pouh van awh. Bangkongtetpawiteh, BAWIPA Isarel Tami Kathoung hah hnephnap laihoi a kâoup.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
Hatdawkvah, a thoundounnaw kho thung vah a due awh vaiteh, ransanaw hot hnin vah a due awh han, telah BAWIPA ni a dei.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
Khenhaw! nang ka kâoup e tami, kai ni na taran telah ransahu Jehovah Bawipa ni ati. Bangkongtetpawiteh, nang reknae hnin teh a pha toe.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
Ka kâoup e tami a rawpnae koehoi apinihai bout pathaw mahoeh. Khopuinaw dawk hmai ka tâco sak vaiteh, a tengpam kaawmnaw pueng he ka kak sak han.
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Ransahu BAWIPA ni hettelah a dei, Isarel catoun hoi Judah catoun teh repcoungroe e lah ao awh, san lah kahrawikungnaw ni a paung awh teh, tâcawt ngai awh hoeh.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
Ahnimouh karatangkung teh a thakasai e a min teh ransahu Jehovah doeh. Ahnimouh koe lah ama teh kampang vaiteh Babilon vah khokasaknaw hah runae a poe vaiteh, ram dawk roumnae hah ka pha sak han.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
Khaldean taminaw e lathueng tahloi a pha. Babilon e kho ka sak e kahrawikungnaw hoi, tami lungkaangnaw e lathueng hai a pha telah BAWIPA ni a dei.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
Tahloi ni kutkhetkathoumnaw a taran teh tamipathu lah ao awh han. Tahloi ni athakaawme taminaw hah taran vaiteh a pâyaw awh han.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
Tahloi ni marang hoi ranglengnaw hoi athung e tami kâkalawtnaw pueng hai a taran. Napui patetlah ao awh han. Tahloi ni a râwnaw taran vaiteh lawp e lah ao han.
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
Tui a hak teh remphui pouh. Bangkongtetpawiteh, meikaphawk ram lah ao. Meikaphawk hah a pathukhai awh.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
Hatdawkvah kahrawng e sarang hoi Asuinaw hawvah kho a sak awh han. Kalauk, tavanaw hai hawvah kho a sak awh han. Ring e lah awm mahoeh toe, nâtuek hai ring e lah awm mahoeh toe.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
Cathut ni Sodom hoi Gomorrah hoi a tengpam e khonaw a raphoe e patetlah hawvah apihai khosak mahoeh toe. Tami capa apinihai pâtam mahoeh toe, telah BAWIPA ni a dei.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Khenhaw! atunglae ram dawk hoi taminaw a tho awh. Talai poutnae koehoi miphun kalen hoi siangpahrang moikapap a tâco.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Licung hoi tahroe a hrawm awh teh a nuencang kamathoutpoungnaw doeh. Lungmanae tawn awh hoeh. Ahnimae pawlawk teh tâlî, tuicapa pawlawk patetlah ao teh, marang dawk a kâcui awh teh, tami pueng tarantuk e patetlah a kamthoup awh teh, Oe! Babilon canu a tuk awh han.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
A pawlawk thai toteh Babilon siangpahrang e kut tha a youn toe. Camokhe tawmlei pataw e patetlah hote patawnae ni a man awh.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Khenhaw! Jordan kâoupnae thung hoi sendek, saring onae hmuen koe a luen takhang e patetlah a tho han. Hatei ahni koehoi ahnimouh ka yawng sak han. A lathueng vah kâ tawn hane ka rawi e ka ta han. Kai patetlah e apimaw kaawm, apipatet ni maw kaie tueng a khoe thai han. Tukhoumkung apimaw ka hmalah kangdout thai han.
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
Hatdawkvah, Babilon kong dawk BAWIPA pouknae, Khaldean taminaw e lathueng pouknae a tawn. Sarangnaw hah lawp lah ao vaiteh, pawngpanae hmuennaw kingdi lah ao han.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Babilon hah tuk teh lawp lah onae kamthang dawk hoi talai a kâhuet teh a khuinae kamthang miphunnaw pueng ni a thai awh han.

< Jeremiah 50 >