< Jeremiah 5 >
1 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
[Perwerdigar]: — Yérusalémning reste-kochilirida uyan-buyan aylinip yügürünglar, obdan körüp biliwélinglar; meydanliridin izdep körünglar; adalet bilen ish köridighan, wediside turushqa intilidighan birla ademni tapsanglar, shunda men bu [sheherni] kechürimen!
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
Gerche ular: «Perwerdigarning hayati bilen!» dep qesem ichken bolsimu, ular yalghandin sözleydu, [dédi].
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
— I Perwerdigar, közüng adalet-bitereplikni izdep yüridu emesmu? Sen bularni urdung, lékin ular azablanmaydu; Sen ularni nabut qilip tügeshtürdüng, lékin ular terbiye qobul qilishni ret qilip keldi; ular yüzlirini tashtin qattiq qildi, ular yolidin yénishni ret qilidu»
4 Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
— men: «Shübhisizki, bundaq qilghanlar peqet namratlar, ular nadanlar; chünki ular Perwerdigarning yolini, Xudasining höküm-körsetmilirini bilmeydu» — dédim.
5 Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
— «Men mötiwerlerning yénigha bérip ulargha sözleymen; chünki ular Perwerdigarning yolini, Xudasining höküm-körsetmilirini bilidu». Biraq ularmu boyunturuqni üzül-késil buzup, rishtilirini üzüp tashlighan.
6 Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
— Shunga ormandin chiqqan bir shir ularni öltüridu, bayawandin chiqqan bir böre ularni weyran qilidu; yilpiz sheherlerge qarap paylaydu; sheherlerdin chiqqan herbiri titma-titma qilinidu; chünki ularning asiyliqliri köpiyip, wapasizliqliri awuydu.
7 “Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
Men zadi némige asasen séni kechürimen? Séning baliliring Mendin waz kéchip, Xuda emeslerge qesem ichmekte; Men hemme hajetliridin chiqqan bolsammu, lékin ular zinaxorluq qilip, pahishilerning öyige top-top bolup méngiwatidu.
8 Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
Ular semrigen ishqwaz ayghirlar, ular herbiri öz yéqinining ayaligha hewes qilip kishnewatidu.
9 Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Bu ishlar tüpeylidin ularni jazalimay qoyamdim? — deydu Perwerdigar, — Méning jénim mushundaq bir eldin qisas almay qoyamdu?
10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
Uning üzüm chünekliridin ötüp, tallirini weyran qilinglar; lékin ularni pütünley nabut qilmanglar; shaxlirini qirip tashlanglar, chünki ular Perwerdigargha tewe emestur;
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
chünki Israil jemeti we Yehuda jemeti Manga mutleq wapasizliq qildi, — deydu Perwerdigar.
12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
Ular: «U héchnéme qilmaydu! Bizge héch apet chüshmeydu; ne qilich ne qehetchilikni körmeymiz!» — dep Perwerdigardin ténip ketti.
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
Peyghemberler bolsa peqet bir shamaldin ibaret bolidu, xalas; [Perwerdigarning] söz-kalami ularda yoqtur; ularning sözliri öz béshigha yansun!
14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
Shunga Perwerdigar, samawi qoshunlarning Serdari bolghan Xuda manga mundaq deydu: — Bu xelq mushu sözni qilghini üchün, mana, Men aghzinggha salghan sözlirimni ot, bu xelqni otun qilimenki, ot ularni köydürüp tashlaydu.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
— Mana, Men yiraqtin bir elni élip kélimen, i Israil jemeti, — deydu Perwerdigar, — U küchlük bir el, qedimiy bir el, tilini sen bilmeydighan we geplirini sen héch chüshenmeydighan bir el bolidu;
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
ularning oqdéni yoghan échilghan bir gördur; ularning hemmisi batur palwanlardur.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
Ular hosulingni we néningni yep kétidu, oghul-qizliringni yep kétidu, kala-qoy padiliringni yep kétidu, üzüm talliringni we enjur derexliringni yep kétidu; ular sen tayan’ghan mustehkem sheherliringni qilich bilen weyran qilidu.
18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
Halbuki, — deydu Perwerdigar, — shu künlerdimu silerni pütünley tügeshtürmeymen.
19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
Shu chaghda [xelqing]: «Perwerdigar Xudayimiz némishqa mushu ishlarning hemmisini béshimizgha chüshürgen?» — dep sorisa, emdi sen [Yeremiya] ulargha: «Siler Mendin yüz örüp, öz zémininglarda yat ilahlarning qulluqida bolghininglardek, siler öz wetininglar bolmighan bir zéminda yat bolghanlarning qulluqida bolisiler» — dégin.
20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
— Yaqupning jemetide shuni jakarlighinki we Yehuda arisida shuni élan qilghinki,
21 Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
«Buni anglanglar, i nadan we eqli yoq, közi turup körmeydighan, quliqi turup anglimaydighan bir xelq: —
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
Mendin qorqmamsiler? — deydu Perwerdigar, — Déngiz süyi üchün sahilni menggülük cheklime qilip, «Bu yerdin ötme» dep békitken Méning aldimda tewrimemsiler? Mana, dolqunliri örkeshligini bilen ular sahil üstidin héch ghelibe qilmaydu; shawqunlighini bilen bu chektin hergiz halqip ötelmeydu.
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
Lékin bu xelqning jahil we asiyliq köngli bardur; ular yoldin chiqip öz béshimchiliq qilip ketti.
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
Ular könglide: «Öz waqtida yamghurlarni, yeni awwalqi hem kéyinki yamghurlarni Bergüchi, bizge hosul peslini békitip aman-ésen Saqlighuchi Perwerdigar Xudayimizdin eymineyli» dégenni héch démeydu.
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
Silerning qebihlikliringlar mushu ishlarni silerge nésip qilmighan; silerning gunahliringlar silerdin beriketni mehrum qilghan.
26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
Chünki xelqim arisida reziller bardur; ular pistirmida yatqan qiltaqchilardek paylap yüridu; ular tuzaq sélip, ademlerni tutuwalidu.
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
Tutqan qushlargha tolghan qepestek, ularning öyliri aldamchiliqtin érishken mallar bilen tolghan; ular shu yol bilen büyük hem bay bolup ketti.
28 wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
Ular semrip, parqirap ketti; berheq, ular rezil ishlarni qilishqa mahir bolup ketti; ular öz menpeetini közlep xeqlerning dewasini, yétim-yésirlerning dewasini sorimaydu; namratlarning hoquqini qoghdaydighan hökümni ular chiqarmaydu.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Bu ishlar tüpeylidin ularni jazalimay qoyamdim?! — deydu Perwerdigar, — Méning jénim mushundaq bir eldin qisas almay qoyamdu?
30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
Zéminda intayin qorqunchluq we yirginchliq bir ish sadir qilin’ghanki —
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?
Peyghemberler yalghan-saxta bésharetlerni bermekte; kahinlar bolsa öz hoquq dairisini kéngeytip hökümranliq qilmaqta; Méning xelqimmu bu ishlarni yaqturidu. Lékin bularning aqiwitide qandaq qilisiler?