< Jeremiah 5 >

1 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
Кутреераць улицеле Иерусалимулуй, уйтаци-вэ, ынтребаць ши кэутаць ын пеце, дакэ се гэсеште ун ом, дакэ есте вреунул каре сэ ынфэптуяскэ че есте дрепт, каре сэ се цинэ де адевэр, ши вой ерта Иерусалимул.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
Кяр кынд зик: ‘Виу есте Домнул!’ ей журэ стрымб.”
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
Доамне, ну вэд окий Тэй адевэрул? Ту-й ловешть, ши ей ну симт нимик; ый нимичешть, ши ну вор сэ я ынвэцэтурэ; яу о ынфэцишаре май таре декыт стынка, ну вор сэ се ынтоаркэ ла Тине.
4 Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
Еу зичям: „Нумай чей мичь сунт аша; ей лукрязэ фэрэ минте, пентру кэ ну куноск каля Домнулуй, Леӂя Думнезеулуй лор!
5 Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
Мэ вой дуче деч ла чей марь ши ле вой ворби, кэч ей куноск каля Домнулуй, Леӂя Думнезеулуй лор!” Дар тоць ау сфэрымат жугул ши ау рупт легэтуриле.
6 Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
Де ачея ый омоарэ леул дин пэдуре ши-й нимичеште лупул дин пустиу. Стэ ла пындэ пардосул ынаинтя четэцилор лор; тоць чей че вор еши дин еле вор фи сфышияць, кэч фэрэделеӂиле лор сунт мулте, абатериле лор с-ау ынмулцит!
7 “Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
„Кум сэ те ерт?”, зиче Домнул. „Копиий тэй М-ау пэрэсит ши журэ пе думнезей каре н-ау фиинцэ. Ши, дупэ че ле-ам примит журэминтеле, се дедау ла прякурвие ши аляргэ ку грэмада ын каса курвей!
8 Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
Ка ниште кай бине хрэниць, каре аляргэ ынкоаче ши ынколо, фиекаре некязэ дупэ неваста апроапелуй сэу.
9 Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Сэ ну педепсеск Еу ачесте лукрурь”, зиче Домнул, „сэ ну Мэ рэзбун Еу пе ун асеменя попор?
10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
Суици-вэ пе зидуриле ей ши дэрымаць, дар ну нимичиць де тот! Луаци-й бутучий ачештя, кэч ну сунт ай Домнулуй!
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
Кэч каса луй Исраел ши каса луй Иуда Мь-ау фост некрединчоасе”, зиче Домнул.
12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
Ей тэгэдуеск пе Домнул ши зик: „Ну есте Ел! Ши ну ва вени ненорочиря песте ной; ну вом ведя нич сабия, нич фоаметя.
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
Пророчий сунт вынт, ши ну Думнезеу ворбеште ын ей. Аша сэ ли се факэ ши лор!”
14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
Де ачея, аша ворбеште Домнул Думнезеул оштирилор: „Пентру кэ аць зис лукрул ачеста, ятэ, Кувынтул Меу ыл фак фок ын гура та ши попорул ачеста, лемне, ка сэ-й ардэ фокул ачеста.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
Ятэ, адук де департе ун ням ымпотрива воастрэ, касэ а луй Исраел”, зиче Домнул, „ун ням таре, ун ням стрэвекь, ун ням а кэруй лимбэ н-о куношть ши але кэруй ворбе ну ле причепь.
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
Толба луй ку сэӂець есте ка ун мормынт дескис; тоць сунт ниште витежь.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
Ел ыць ва мынка сечеришул ши пыня, ыць ва мынка фиий ши фийчеле, ыць ва мынка оиле ши боий, ыць ва мынка вия ши смокинул ши ыць ва трече прин сабие четэциле ынтэрите, ын каре те ынкрезь.
18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
Дар, ши ын зилеле ачеля”, зиче Домнул, „ну вэ вой нимичи де тот.
19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
Дакэ вець ынтреба атунч: ‘Пентру че не-а фэкут тоате ачестя Домнул Думнезеул ностру?’, аша ле вей рэспунде: ‘Дупэ кум вой М-аць пэрэсит ши аць служит унор думнезей стрэинь ын цара воастрэ, тот аша акум вець служи унор стрэинь ынтр-о царэ каре ну есте а воастрэ!’
20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
Спунець лукрул ачеста касей луй Иаков, вестици-л ын Иуда ши зичець:
21 Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
‘Аскултаць лукрул ачеста, попор фэрэ минте ши фэрэ инимэ, каре аре окь, ши ну веде, урекь, ши н-ауде!
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
Ну воиць сэ вэ темець де Мине’, зиче Домнул, ‘ну воиць сэ тремураць ынаинтя Мя? Еу ам пус мэрий ка хотар нисипул, хотар вешник, пе каре ну требуе сэ-л трякэ. Ши кяр дакэ валуриле ей се ынфурие, тотушь сунт непутинчоасе; урлэ, дар ну-л трек.
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
Попорул ачеста ынсэ аре о инимэ дырзэ ши рэзврэтитэ; се рэскоалэ ши плякэ
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
ши ну зик ын инима лор: «Сэ не темем де Домнул Думнезеул ностру, каре дэ плоае ла време, плоае тимпурие ши тырзие, ши не пэстрязэ сэптэмыниле хотэрыте пентру сечериш.»
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
Дин причина нелеӂюирилор воастре н-ау лок ачесте орындуирь, пэкателе воастре вэ липсеск де ачесте бунэтэць.
26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
Кэч ын попорул Меу сунт оамень рэй; ей пындеск ка пэсэрарул каре ынтинде лацурь, ынтинд курсе ши принд оамень.
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
Кум се умпле о коливие де пэсэрь, аша се умплу каселе лор прин виклешуг; аша ажунг ей путерничь ши богаць.
28 wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
Се ынграшэ, луческ де грэсиме; ынтрек орьче мэсурэ ын рэу, ну апэрэ причина, причина орфанулуй, ка сэ ле мяргэ бине, ну фак дрептате челор липсиць.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Сэ ну педепсеск Еу ачесте лукрурь’, зиче Домнул, ‘сэ ну-Мь рэзбун Еу пе ун асеменя попор?’
30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
Грозаве лукрурь, урычоасе лукрурь се фак ын царэ.
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?
Пророчий пророческ неадевэрурь, преоций стэпынеск ку ажуторул лор, ши попорулуй Меу ый плак ачесте лукрурь. Дар че вець фаче ла урмэ?

< Jeremiah 5 >