< Jeremiah 5 >
1 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
Run ye to and fro through the streets of Jerusalem, And see I pray you and know and seek out in the broad places thereof, Whether ye can find, a man, Whether there is one Doing justice Demanding fidelity, —That I may pardon her.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
Even though they say By the life of Yahweh, Yet in fact falsely, do they swear.
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
O Yahweh! thine own eyes, are they not directed to fidelity? Thou hast smitten them Yet have they not grieved, Thou hast consumed them—They have refused to receive correction, —They have made their faces bolder than a cliff, They have refused to return.
4 Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
And, I, said, —Only, poor people, are they, —They act foolishly, For they know not the way of Yahweh, the justice of their God!
5 Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
I will betake me unto the great men, and will speak, with them! For, they, know the way of Yahweh, the justice of their God! Yea but, they, with one accord have broken the yoke, torn off the bands.
6 Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
For this cause, hath the lion out of the forest smitten them, The wolf of the waste plains, preyeth upon them, The leopard, is keeping watch over their cities, Every one that goeth out from thence, is torn in pieces, —For they have multiplied their transgressions, Numerous are their apostasies.
7 “Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
How, for this, can I pardon thee? Thine own sons, have forsaken me, And have sworn by No-gods, —When I had fed them to the full, Then committed they adultery, And the house of the unchaste woman, they used to throng:
8 Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
Lusty, well-fed horses, had they become, Every man unto his neighbour’s wife, would neigh!
9 Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
For these things, shall I not punish? Demandeth Yahweh: Yea on a nation such as this, must not my soul avenge herself?
10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
Scale ye her walls and destroy, But a full end, do not make, —Remove her tendrils, For not to Yahweh, do, they, belong!
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
For very treacherously, have the house of Israel and the house of Judah dealt with me, Declareth Yahweh.
12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
They have acted deceptively against Yahweh, And have said, Not He! Neither shall there come upon us, calamity, Nor sword nor famine, shall we see;
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
But the prophets, shall prove to be wind, And there is no one speaking in them, —Thus, shall it be done to themselves!
14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
Therefore, Thus, saith Yahweh, God of hosts, Because ye have spoken this word, —Behold me! making my words in thy mouth to be fire, And, this people, —wood, So shall it devour them.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
Behold me! bringing upon you a nation from afar, O house of Israel, Declareth Yahweh, —A nation invincible, it is, A nation from age-past times, hath it been, A nation whose tongue thou shalt not know, Neither shalt thou understand what it speaketh:
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
Its quiver, is like an open sepulchre, —They all, are heroes:
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
Then shall it eat thy harvest and thy bread which thy sons and thy daughters should eat, —It shall eat thy flock and thy herd, It shall eat thy vine and thy fig-tree, —It shall destroy thy defenced cities wherein thou, art trusting, with the sword.
18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
Yet, even in those days, Declareth Yahweh, Will I not make of you, a full end.
19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
And it shall come to pass, when ye shall say, For what cause hath Yahweh our God done to us all these things? Then shalt thou say unto them, —As ye forsook me, and served the gods of the foreigner in your own land, So, shall ye serve aliens in a land not your own.
20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
Tell ye this, throughout the house of Jacob, —And let it be heard throughout Judah saying:
21 Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
Hear this, I pray you ye people—foolish and without heart, —Eyes, have they, and see not, Ears, have they, and hear not!
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
Even for me, will ye have no reverence? Enquireth Yahweh, And because of me, will ye not be pained? In that though I placed the sand as a bound to the sea, A decree age-abiding, and it should not pass beyond it, —When they would toss themselves Then should they not prevail, When the waves thereof would roar Then should they not pass beyond it,
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
Yet, this people hath an obstinate and rebellious heart, —They have turned aside, and gone their way;
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
Neither have they said in their heart, —Let us we pray you, revere Yahweh our God, Who giveth rain, even the early and the latter, in its season, —The appointed weeks of harvest, he reserveth for us.
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
Your iniquities, have thrust away these things, Yea, your sins, have withholden that which is good from you.
26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
For there have been found among my people lawless men, —One lieth in wait, as with the stooping of fowlers, They have set a trap, they capture men:
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
As, a cage, is full of birds, So, are, their houses, full of unrighteous gain, —For this cause, have they become great and waxen rich:
28 wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
They have waxed fat, they shine Yea they have overpassed the records of wickedness. The right, have they not determined, the right of the fatherless that they might prosper, —Yea justice to the helpless, have they not decreed.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Upon these things, shall I not bring punishment? Demandeth Yahweh. Or, on a nation such as this, shall not my soul avenge herself?
30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
An astounding and horrible thing, hath been brought to pass in the land:
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?
The prophets, have prophesied, falsely, And the priests tread down by their means, And, my people, love it, so, —What then can ye do as to her latter end?