< Jeremiah 5 >
1 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
Jerusalem khothung vah yawng nateh, thongma hoi khen nateh panuek awh. Thongma tanghling hah khen awh nateh, tami buet touh banghai lawkkatang ka tawng e lawkcengkung na hmawt awh pawiteh Jerusalem teh ka ngaithoum han.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
BAWIPA a hring telah a dei awh nakunghai, laithoe hoi thoe a kâbo awh.
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
Oe, BAWIPA lawkkatang teh, hmu han na ngai e nahoehmaw. Na hem awh nakunghai ka lung mathout hoeh. Na raphoe nakunghai, na tounnae hah tawm ngai awh hoeh. Lungsongpui hlak hai a pata teh, a tampanaw hah a te sak teh bout ban ngai kalawn aw hoeh.
4 Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
Hatdawkvah, kai ni, hetnaw heh tami karoedengnaw doeh, ahnimouh teh a pathu awh, bangkongtetpawiteh, BAWIPA e lam hoi amamae Cathut lawkcengnae hah panuek awh hoeh.
5 Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
Tami kalentoenaw koe ka cei vaiteh, ahnimouh koe lawk ka dei han. bangkongtetpawiteh, ahnimouh ni, BAWIPA e lam hoi amamae Cathut lawkcengnae han a panue awh, telah ka ti. Hateiteh, hetnaw ni, lungthin suetalah kahnam hah a khoe awh teh, kateknae rui a rathap awh.
6 Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
Hatdawkvah, ratu thung e sendek ni ahnimouh teh a kei awh han. Asui ni a raphoe awh han. Takai ni khopui pawm vaiteh, ka tâcawt e pueng vekrasen lah a phi han. Bangkongtetpawiteh, lawkeknae hah apap teh, hnuklah kamlangnae apap poung.
7 “Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
Hete hno dawk, bangtelamaw na ngaithoum thai han. Na canaw ni na ceitakhai awh teh, Cathut lah kaawmhoehnaw koe lah thoe a kâbo awh. Kaboumcalah ka kawkhik torei teh, a uicuk awh teh, tak kâyawt e im vah, a kamkhueng awh te, a yon awh.
8 Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
King kaboumlah rawca ka cat e marang patetlah ao awh, tami pueng ni amamae imri e a yunaw hah a nôe awh teh a cairing sin awh.
9 Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Hete hnonaw kecu dawkvah, ka rek mahoeh namaw telah BAWIPA ni ati, hot patet e miphun lathueng vah, ka pathung mahoeh namaw.
10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
A rapan dawkvah, kâen nateh, koung raphoe awh. Hateiteh, abuemlah teh raphoe hanh awh, a cakang hah lat awh. Bangkongtetpawiteh, BAWIPA e nahoeh.
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
Bangkongtetpawiteh, Isarel imthung naw hoi Judah imthung ni ka lathueng vah, huenghai hawi a sak awh, telah BAWIPA ni a dei.
12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
BAWIPA teh laikathout e lah a pouk awh teh, ahni ni banghai tet katang mahoeh, rucatnae hai maimouh lathueng phat sak katang mahoeh, tahloi hoi takang hai kâhmo katang mahoeh.
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
Profetnaw teh kahlî doeh, ahnimouh dawk lawkkatang awm hoeh, hatdawkvah ahnimae a lawk teh amamouh hanelah awm yawkaw seh, ati awh.
14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
Hatdawkvah kalvan ransabawi ni hettelah a dei, ahnimanaw ni hete lawk a dei tangcoung dawkvah, kai ni ka lawknaw heh na pahni dawk hmai lah ka o sak vaiteh he e taminaw heh thing lah kacoungsak vaiteh hmai ni koung a kak awh han.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
Oe Isarel imthungkhunaw, nangmanaw ka tuk hanelah kho hlanae koehoi miphun thasai ka kaw han, ayan hoi kaawm boi e tha kaawm poung, nangmouh ni a lawk na thai panuek awh hoeh e taminaw ka kaw han, telah BAWIPA ni a ti.
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
Ahnimae palanaw teh sut kamawng e phuen lah ao teh abuemlahoi thakasai pong e lah ao awh.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
Ahnimouh ni na tangcoung e cang hai na ca han e rawca pueng haiyah koung a ca vaiteh, na capanaw hoi na canunaw ni a ca awh hane hai koung a ca awh han. Na maitonaw hoi na tunaw hai a ca han, na misurkung hoi thaibunglungnaw hai a ca han, rapan ka tawn e khonaw hai telah hoi koung a raphoe awh han.
18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
Hahoi teh hatnae hnin nah kai ni koung na pathup awh mahoeh, telah BAWIPA ni a ti.
19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
Taminaw ni, bangkongmaw maimouh BAWIPA Cathut ni hettelah maimouh van hno a sak vai. Telah na pacei awh vah, nangmouh ni ahnimouh koe, “nangmouh ni kai na hnoun awh teh ramlouk cathut thaw hah na ram thung na sak van awh e patetlah, atu na ramdawk e laipalah ram alouke thaw teh na tawk a han toe teh poeh, telah BAWIPA ni a pâpho.
20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
Hete lawk heh Jakop imthungkhu koe dei poeh, Judah ram thung vah pâpho awh.
21 Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
Oe nangmouh tamipathu hoi panuenae laipalah, mit na tawn awh eiteh, kahmawthoehnaw, hnâ na tawn awh eiteh kathaihoehnaw hetheh thai awh haw.
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
Na taket awh hoeh maw. Telah BAWIPA ni a dei. Ka hmalah na pâyaw awh mahoeh maw. Kai ni tuipui teng vah langri hanlah sadi ka sak, tapoung thai hoeh nahan yungyoe sak hanelah ao. Tuipui tuicapa ka tho nakunghai, tapoung thai mahoeh.
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
Hatei ka taminaw ni a lungpata awh teh taranthawnae lungthin a tawn awh; tarantuk hanlah a yawng awh.
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
Amamouh roeroe ni a lungthin hoi hai, “a tue nah hmaloe kho hoi hnuk ten kho ka rak sakkung, canga tue nah ka kesakkung, BAWIPA maimae Cathut heh takhet awh haw sei”, tet awh hoeh.
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
Namamae na sak payonnae ni hetnaw pueng heh a kahma sak teh, na yonnae naw pueng koung a ngang.
26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
Ka taminaw rahak vah tamikathoutnaw ao teh tangkam kapatûngnaw ni tava a pawp awh e patetlah a pawp awh teh tangkam heh a patung pouh awh.
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
Tapawm dawk tava a kawi e patetlah, a im dawk dumnae hai akawi, a bawi awh teh hnopai moikapap tawn awh.
28 wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
Athaw awh teh minhmai a kâpi awh. Tamikathoutnaw ni sak e ka tapuetlah thoenae a sak awh, hno kathout saknae ni, na pa katawnhoehnaw koe laidei awh hoeh, roedengnaw ni hmu han kawi koelah kangdoutkhai awh hoeh.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Hete hnonaw dawkvah sak laipalah ka o han namaw telah BAWIPA ni a dei. Het patetlae miphunnaw lathueng moipathung laipalah ka o han namaw.
30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
Kângairu hnonaw, hoi takikathopoung hno teh ram thungvah a sak awh.
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?
Profetnaw ni laithoe a dei awh teh, vaihmanaw ni amamae kâ lahoi a uk awh. Het patetlae naw hah ka taminaw ni a lungpataw awh. Hatei a poutnae koe lah teh bangmaw na sak awh han.