< Jeremiah 5 >
1 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
Обходете улиците на Ерусалим И вижте сега, научете се, и потърсете по площадите му Дали можете намери човек - Дали има някой - който да постъпва справедливо, да търси честност; И аз ще простя на тоя град.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
Защото, ако и да казват: заклевам се с живота на Господа! Те наистина лъжливо се кълнат.
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
Господи, очите Ти не търсят ли честност? Ударил си ги, но не ги заболя; Изнурил си ги, но не искаха да приемат поправление; Втвърдиха лицата си повече от камък; Не искаха да се върнат.
4 Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
Тогава аз рекох: Навярно това са сиромасите, те са безумни; Защото не знаят пътя Господен, Нито закона на своя Бог.
5 Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
Ще се обърна към големците Та ще говоря с тях; Защото те знаят пътя Господен, Закона на своя Бог, Но и те всички са строшили хомота, Разкъсали връзките.
6 Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
Затова, лъв от гората ще ги порази, Вълк от пустинята ще ги ограби, Рис ще причаква край градовете им; Всеки, който излезе от там, ще бъде разкъсан, Защото престъпленията им са много, Отстъпничествата им се умножиха.
7 “Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
Как ще ти простя това? Чадата ти Ме оставиха И кълняха се в ония, които не са богове; След като ги наситих, те прелюбодействуваха, И на тълпи отиваха в къщите на блудниците.
8 Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
Заран са като нахранени коне; Всеки цвили подир жената на ближния си.
9 Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Няма ли да накажа затова? казва Господ; И душата Ми не ще ли въздаде на такъв народ?
10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
Качете се на стените му и събаряйте; Но не нанасяйте съвършено изтребление; Махнете клоновете му, Защото не са Господни.
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
Защото Израилевият дом и Юдовият дом Се отнесоха много невярно към Мене, казва Господ.
12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
Отрекоха се от Господа, Казвайки: Не той ни заплашва с това; И няма да ни постигне зло, Нито ще видим нож или глад;
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
Пророците са вятър, И слово Господно няма в тях. На сами тях ще се сбъдне това.
14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
Затова, така казва Господ Бог на Силите: Понеже изговарят тия думи, Ето, Аз ще направя Моите слова в устата ти огън, И тия люде дърва, и ще ги пояде.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
Ето, доме Израилев, Аз ще доведа върху вас Народ от далеч, казва Господ; Народ траен е той, народ старовременен, Народ чийто език не знаеш, Нито разбираш що говорят,
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
Тулът им е като отворен гроб; Те всички са юнаци.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
Ще изпояждат жетвата ти и хляба ти, Който синовете ти и дъщерите ти трябваше да ядат; Ще изпояждат стадата ти и чердите ти, Ще изпояждат лозята ти и смоковниците ти, Ще разбият с меч укрепените ти градове, На които ти уповаваш.
18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
Но и в ония дни, казва Господ, Не ща да ви нанеса съвършено изтребление.
19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
И когато речете: Защо Господ Бог наш Ни направи всичко това? Тогава да им речеш: Както Ме оставихте Та служихте на чужди богове във вашата земя, Така ще служите на чужденци в една земя, която не е ваша.
20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
Известете това на Якововия дом, И прогласете го в Юда, като кажете:
21 Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
Чуйте сега това, глупави и неразумни люде, Които имате очи, но не виждате, Които имате уши, но не чувате.
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
Не се ли боите от Мене? казва Господ, Не ще ли треперите пред Мене, Който с вечна заповед съм поставил пясъка за граница на морето, Която не може да премине; Тъй че, макар вълните му да се издигат, пак няма да преодолеят, При все че бучат, пак няма да я преминат?
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
Но тия люде имат бунтовно и непокорно сърце; Възбунтуваха се и отидоха.
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
Не казват в сърцето си: Нека се боим сега от Господа нашия Бог, Който дава ранния и късния дъжд на времето му, Който пази за нас определените седмици на жетвата.
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
Вашите беззакония отвърнаха тия неща, И вашите грехове ви лишиха от доброто.
26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
Защото се намират между людете Ми нечестивци, Които, наблюдавайки както причакващ ловец, Полагат примки, ловят човеци.
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
Както клетка е пълна с птици, Така къщите им са пълни с плод на измама, Чрез която те се възвеличиха и обогатиха,
28 wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
Отлъстяха, лъщят, Дори преляха със своите нечестиви дела; Не защищават делото - делото на сирачето, за да благоденствуват, И правото на бедните не отсъждат.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Няма ли да накажа затова? казва Господ; Душата Ми не ще ли въздаде на такъв народ?
30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
Удивително и ужасно нещо стана в тая страна:
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?
Пророците пророкуват лъжливо, И свещениците господствуват чрез тях; И людете Ми така обичат; А какво ще правите в окончателното следствие на това?