< Jeremiah 49 >

1 Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
Referitor la amoniți, astfel spune DOMNUL: Nu are Israel fii? Nu are el moștenitor? De ce atunci împăratul lor moștenește Gadul și poporul său locuiește în cetățile lui?
2 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
De aceea, iată, vin zilele, spune DOMNUL, că voi face să fie auzit zgomot de război în Raba amoniților; și aceasta va fi o movilă pustiită și fiicele ei vor fi arse cu foc; atunci Israel va fi moștenitorul celor ce au fost moștenitorii lui, spune DOMNUL.
3 “Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
Urlă, Hesbonule, pentru că cetatea Ai este jefuită; strigați, fiice ale Rabei, încingeți-vă cu pânză de sac; plângeți și alergați încoace și încolo lângă îngrădituri, pentru că împăratul lor va merge în captivitate și preoții lui și prinții lui împreună.
4 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
Pentru ce te lauzi tu cu văile, valea ta curgătoare, fiică decăzută? care se încrede în tezaurele ei, spunând: Cine va veni la mine?
5 Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Iată, voi aduce o frică asupra ta, spune Domnul DUMNEZEUL oștirilor, de la toți cei care sunt în jurul tău; și veți fi alungați fiecare om, drept înainte; și nimeni nu îl va aduna pe cel care rătăcește.
6 “Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
Și după aceea voi aduce înapoi pe captivii copiilor lui Amon, spune DOMNUL.
7 Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
Referitor la Edom, astfel spune DOMNUL oștirilor: Nu mai este înțelepciune în Teman? A pierit sfatul de la cei chibzuiți? A dispărut înțelepciunea lor?
8 Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
Fugiți, întoarceți-vă înapoi, locuiți în adânc locuitori ai Dedanului, pentru că voi aduce nenorocirea lui Esau asupra lui, la timpul când îl voi cerceta.
9 Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
Dacă culegătorii de struguri vin la tine, nu ar lăsa ei câteva boabe de cules? Dacă hoți vin noaptea, ei vor distruge până când au destul.
10 Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
Dar eu l-am dezgolit pe Esau, am descoperit locurile lui tainice și el nu va fi în stare să se ascundă; sămânța lui este jefuită, și frații lui, și vecinii lui, și el nu mai este.
11 Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
Lasă pe ai tăi copii fără tată, eu îi voi păstra în viață; și văduvele tale să se încreadă în mine.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
Pentru că astfel spune DOMNUL: Iată, cei a căror judecată nu era să bea din pahar, îl vor bea negreșit; și ești tu acela care va rămâne cu totul nepedepsit? Nu vei rămâne nepedepsit, ci îl vei bea negreșit.
13 Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
Pentru că am jurat pe mine însumi, spune DOMNUL, că Boțra va deveni o pustiire, o ocară, o risipire și un blestem; și toate cetățile ei vor fi risipiri veșnice.
14 Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
Am auzit un zvon de la DOMNUL și un ambasador este trimis printre păgâni, spunând: Adunați-vă și veniți împotriva ei și ridicați-vă la bătălie.
15 “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
Pentru că, iată, te voi face mic printre păgâni și disprețuit printre oameni.
16 Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
Groaza ta și mândria inimii tale te-a înșelat, tu care locuiești în crăpăturile stâncii, care ții înălțimea dealului; chiar dacă ți-ai face cuibul la fel de înalt ca acvila, te voi coborî de acolo, spune DOMNUL.
17 “Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
De asemenea Edomul va fi o pustiire; oricine trece pe lângă el va fi înmărmurit și va șuiera la toate plăgile lui.
18 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
Ca la dărâmarea Sodomei și Gomorei și a cetăților vecine lor, spune DOMNUL, niciun om nu va trăi acolo, niciun fiu al omului nu va locui în el.
19 “Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Iată, el va urca precum un leu din umflarea Iordanului împotriva locuinței celui tare; dar deodată îl voi face să fugă din ea; și cine este un om ales pe care să îl rânduiesc peste el? Pentru că cine este ca mine? Și cine îmi va rândui timpul? Și cine este acest păstor care va sta în picioare înaintea mea?
20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
De aceea ascultați sfatul DOMNULUI, pe care el l-a hotărât împotriva Edomului; și scopurile lui pe care le-a hotărât împotriva locuitorilor Temanului: Într-adevăr cei mai mici ai turmei îi vor trage afară; într-adevăr el le va face locuințele pustii împreună cu ei.
21 Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
Pământul se mișcă la zgomotul căderii lor, la strigăt, zgomotul lui s-a auzit la Marea Roșie.
22 Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
Iată, el va urca și va zbura ca acvila și își va întinde aripile împotriva Boțrei; și în acea zi inima războinicilor Edomului va fi ca inima unei femei în junghiurile ei.
23 Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
Referitor la Damasc. Hamatul și Arpadul este încurcat, pentru că au auzit vești rele; ele au inima slabă; este tristețe pe mare; ea nu se poate liniști.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
Damascul a slăbit și se întoarce să fugă și frica l-a apucat; chin și întristări l-au apucat, ca pe o femeie în durerile nașterii.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
Cum nu este cetatea laudei lăsată, cetatea bucuriei mele!
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
De aceea tinerii ei vor cădea pe străzile ei și toți bărbații de război vor fi stârpiți în acea zi, spune DOMNUL oștirilor.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
Și eu voi aprinde un foc în zidul Damascului și acesta va mistui palatele lui Ben-Hadad.
28 Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
Referitor la Chedar și referitor la împărățiile Hațorului, pe care Nebucadnețar împăratul Babilonului le va lovi, astfel spune DOMNUL: Ridicați-vă, urcați-vă la Chedar și jefuiți pe bărbații estului.
29 Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
Corturile și turmele lor, ei le vor lua; vor lua pentru ei covoarele lor și toate vasele lor și cămilele lor; și vor striga către ei: Frică este de fiecare parte.
30 “Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
Fugiți, duceți-vă foarte departe, locuiți în adânc, voi locuitori ai Hațorului, spune DOMNUL, pentru că Nebucadnețar, împăratul Babilonului, a făcut sfat împotriva voastră și a conceput un plan împotriva voastră.
31 “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
Ridicați-vă, urcați-vă la națiunea bogată, care locuiește fără grijă, spune DOMNUL, care nu are nici porți nici zăvoare, care locuiește singură.
32 Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
Și cămilele lor vor fi o jefuire și mulțimea vitelor lor, o pradă; și eu îi voi împrăștia în toate vânturile pe cei din colțurile cele mai îndepărtate; și voi aduce nenorocirea lor din toate părțile lor, spune DOMNUL.
33 “Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
Și Hațorul va fi o locuință pentru dragoni și o pustiire pentru totdeauna; niciun om nu va trăi acolo, nici vreun fiu al omului nu va locui în el.
34 Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
Cuvântul DOMNULUI care a venit la profetul Ieremia împotriva Elamului la începutul domniei lui Zedechia, împăratul lui Iuda, spunând,
35 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
Astfel spune DOMNUL oștirilor: Iată, voi frânge arcul Elamului, măreția puterii lor.
36 Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
Și asupra Elamului voi aduce cele patru vânturi de la cele patru colțuri ale cerului și îi voi împrăștia spre toate acele vânturi, și nu va fi națiune la care cei alungați ai Elamului să nu vină.
37 Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
Fiindcă voi face Elamul să se descurajeze înaintea dușmanilor lor și înaintea celor care le caută viața; și voi aduce răul asupra lor, mânia mea înverșunată, spune DOMNUL; și voi trimite sabia după ei, până când îi voi fi mistuit;
38 Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
Și voi pune tronul meu în Elam și voi nimici de acolo pe împărat și pe prinți, spune DOMNUL.
39 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.
Dar se va întâmpla în zilele de pe urmă, că voi întoarce pe captivii Elamului, spune DOMNUL.

< Jeremiah 49 >