< Jeremiah 49 >

1 Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
Pret Amona bērniem Tas Kungs tā saka: vai tad Israēlim nav bērnu, vai viņam nav mantinieka? Kāpēc tad Malkoms ir Gada mantinieks, un viņa ļaudis dzīvo šajās pilsētās?
2 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
Tādēļ redzi, nāks dienas, saka Tas Kungs, ka Es pār Amona Rabu likšu dzirdēt kara brēkšanu, un tā taps par gruvešu kopu, un viņas apkārtēji ciemi taps ar uguni sadedzināti. Un Israēls iemantos savus mantotājus, saka Tas Kungs.
3 “Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
Kauc, Hešbona, jo Aja ir postīta; kauciet, Rabas meitas, apjoziet maisus, vaidiet un skraidiet apkārt gar mūriem, jo Malkoms ies cietumā ar visiem saviem svētītājiem un lielkungiem.
4 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
Ko tu lielies ar savām ielejām? Tavas ielejas ir pārplūdušas, tu atkāpēja meita, kas paļaujies uz savām mantām (un saki): kas celsies pret mani?
5 Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Redzi, saka Tas Kungs Dievs Cebaot, es pār tevi vedīšu bailes no visiem, kas ir ap tevi; jūs tapsiet izdzīti, ikkatrs taisni projām, un neviena nebūs, kas tos bēdzējus sapulcina.
6 “Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
Bet pēclaikā Es vedīšu atpakaļ Amona bērnu cietumniekus, saka Tas Kungs.
7 Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
Pret Edomu Tas Kungs Cebaot tā saka: vai tad gudrības vairs nav Temanā? Vai padoms iznīcis pie tiem prātīgiem?
8 Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
Vai viņu gudrība izzudusi? Bēdziet, griežaties, slēpjaties, Dedana iedzīvotāji, jo Es vedu nelaimi pār Ēsavu viņa piemeklēšanas laikā.
9 Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
Ja vīna lasītāji tev būtu uznākuši, tad tie kādus ķekarus būtu atstājuši; kad zagļi būtu nākuši naktī, vai tie nebūtu samaitājuši pēc vajadzības?
10 Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
Bet Es Ēsavu esmu atsedzis, Es viņa slepenās vietas esmu atklājis, ka tas nevarēs apslēpties; viņa dzimums ir postīts un viņa brāļi un viņa kaimiņi, un to vairs nav.
11 Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
Atstāj savus bāriņus, tad Es tos uzturēšu dzīvus, un savas atraitnes, lai tās cerē uz Mani.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
Jo tā saka Tas Kungs: redzi, kam tiesa nebija biķeri dzert, tiem tiešām jādzer, vai tad tu paliksi bez sodības? Tu nepaliksi bez sodības, bet tu tiešām dzersi.
13 Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
Jo Es esmu zvērējis pie Sevis paša, saka Tas Kungs, ka Bocrai būs tapt par posta vietu, par apsmieklu, par tuksnesi un par lāstu, un visas viņas pilsētas taps par mūžīgiem tuksnešiem.
14 Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
Es esmu dzirdējis ziņu no Tā Kunga, un vēsts ir sūtīta tautām: sapulcinājaties un nāciet pret viņu un ceļaties karā.
15 “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
Jo redzi, Es tevi mazu daru tautu starpā, nicinātu pie cilvēkiem.
16 Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
Bailes no tevis tevi pievīlušas, un tava sirds lepnība, tāpēc ka tu dzīvo klints plaisumos un mīti uz augstiem kalniem. Jebšu tu savu ligzdu tik augsti taisītu kā ērglis, tomēr Es tevi no turienes nogrūdīšu, saka Tas Kungs.
17 “Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
Tā Edoms būs par tuksnesi, visi, kas viņam ies garām, iztrūcināsies un svilpos par visām viņa mokām;
18 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
Tā kā Sodoma un Gomora ir apgāztas līdz ar saviem kaimiņiem, saka Tas Kungs, tā tur neviens nedzīvos, un cilvēka bērns tur nemitīs.
19 “Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Redzi, viņš ceļas kā lauva no Jardānes vareniem biezumiem pret stipriem dzīvokļiem; jo Es viņu no turienes piepeši aizdzīšu, un kas izredzēts, to Es pār to celšu. Jo kas ir tāds kā Es, un kas Mani sauks tiesā, un kas ir tas gans, kas Manā priekšā pastāvēs?
20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
Tāpēc klausiet Tā Kunga padomu, ko Viņš nospriedis par Edomu, un Viņa domas, ko Viņš nodomājis par Temana iedzīvotājiem. Tiešām, viņus aizvedīs kā ganāmā pulka jērus; tiešām, viņu ganības iztrūcināsies par viņiem.
21 Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
Zeme trīcēs no viņu krišanas trokšņa; kliegšana, viņas balss būs dzirdama pie niedru jūras.
22 Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
Redzi, viņš celsies un skries kā ērglis un izplētīs savus spārnus pār Bocru. Un Edoma vareno sirds būs tai dienā kā sievas sirds bērnu sāpēs.
23 Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
Pret Damasku: Hamata un Arpada kaunas; tās izbijušās, tāpēc ka dzirdējušas bailīgu ziņu; jūrmalā ir bailes, ka nevar dusēt.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
Damaskus ir noguris, ir griezies uz bēgšanu, drebuļi to sagrābuši, bailība un sāpes to sagrābušas kā sievu, kas dzemdē.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
Kā? Vai tā nu nav atstāta, tā slavenā pilsēta, Mana prieka pilsēta?
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Tāpēc viņas jaunekļi kritīs pa viņas ielām, un visi karavīri taps izdeldēti tai dienā, saka Tas Kungs Cebaot.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
Un es iededzināšu uguni Damaskus mūros, un tas norīs BenHadada skaistos namus. -
28 Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
Pret Ķedaru un Hacora valstīm, ko Nebukadnecars, Bābeles ķēniņš, sakāva, Tas Kungs tā saka: ceļaties, ejat pret Ķedaru, un postait austruma bērnus.
29 Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
Tie paņems viņu dzīvokļus un ganāmos pulkus, viņu teltis un visus viņu rīkus, un aizvedīs sev viņu kamieļus un izsauks pār tiem: briesmas visapkārt!
30 “Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
Bēdziet, skrieniet ātri, paslēpjaties, Hacora iedzīvotāji, saka Tas Kungs! Jo Nebukadnecars, Bābeles ķēniņš, pret jums nospriedis padomu un pret jums nodomājis domas.
31 “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
Ceļaties, ejat pret tiem ļaudīm, kas mierīgi un droši dzīvo, saka Tas Kungs, kam nedz durvju, nedz aizšaujamo, - tie dzīvo par sevi.
32 Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
Viņu kamieļi būs par laupījumu, un viņu lielie ganāmie pulki taps aizvesti. Un Es izkaisīšu visos vējos tos, kam apcirptas bārdas, un no visām pusēm Es pār viņiem atvedīšu samaitāšanu, saka Tas Kungs.
33 “Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
Un Hacors būs par mājas vietu tuksneša zvēriem un postā(neauglīgu vietu) mūžam; tur neviens nedzīvos, cilvēka bērns tur nemitīs.
34 Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
Šis ir Tā Kunga vārds, kas notika uz pravieti Jeremiju pret Elamu, Cedeķijas, Jūda ķēniņa, valdīšanas iesākumā, sacīdams:
35 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
Tā saka Tas Kungs Cebaot: redzi, Es salauzīšu Elama stopu, viņa stiprāko varu.
36 Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
Un Es vedīšu pār Elamu tos četrus vējus no tām četrām debess malām, un Es tos izkaisīšu šinīs vējos, un tautas nebūs, kurp nenāks Elama aizdzītie.
37 Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
Un Es izbiedināšu Elamu viņa ienaidnieku priekšā un to priekšā, kas meklē viņa dvēseli, un vedīšu pār tiem ļaunumu, savas dusmības karstumu, saka Tas Kungs; un Es sūtīšu zobenu tiem pakaļ, tiekams tiem būšu galu darījis.
38 Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
Un Es celšu Savu goda krēslu Elamā un iznīcināšu no turienes ķēniņu un lielkungus, saka Tas Kungs.
39 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.
Bet pēclaikā Es vedīšu atpakaļ Elama cietumniekus, saka Tas Kungs.

< Jeremiah 49 >