< Jeremiah 49 >

1 Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
Ammón fiairól. Így szól az Örökkévaló: Vajon gyermekei nincsenek-e Izraelnek, avagy nincs-e örököse? Miért foglalta el Malkám Gádot és népe az ő városaiban telepedett le?
2 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
Azért, íme napok jönnek, úgymond az Örökkévaló, és harcnak riadását hallatom Ammón fiainak Rabbája ellen és rommá, pusztasággá lesz, leányvárosai pedig tűzben gyújtatnak föl; és elfoglalja Izrael az ő elfoglalóit, úgymond az Örökkévaló.
3 “Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
Jajgass Chesbón, mert elpusztíttatott Áj, kiáltsatok Rabba leányai, kössetek föl zsákokat, gyászt tartsatok és barangoljatok az aklok közt, mert Malkám számkivetésbe megy, papjai és nagyjai egyetemben.
4 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
Mit dicsekszel a völgyekkel, bővelkedő völgyeddel, te elpártolt leány, aki kincseiben bízik: ki jöhet ellenem?
5 Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Íme én hozok rád remegést, úgymond az Úr, az Örökkévaló, a seregek ura, mind a körülötted levőktől, és el fogtok taszíttatni kiki maga elé és senki sem gyűjti össze a bujdosót.
6 “Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
De azután vissza fogom hozni Ammón fiainak foglyait, úgymond az Örökkévaló.
7 Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
Edómról. Így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Vajon nincs-e többé bölcsesség Témánban, elveszett-e tanács az értelmesektől, megromlott-e bölcsességük?
8 Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
Fussatok, forduljatok, mélyre menjetek lakni, Dedán lakói, mert Ézsáu balsorsát hozom rá, amely időben megbüntetem.
9 Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
Ha szüretelők jönnek hozzád, nem hagynak böngészetet, ha tolvajok éjjel, rontanak, amennyi elég nekik.
10 Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
Mert én megmeztelenítettem Ézsáut, feltártam rejtekeit, elbújni nem tud; elpusztíttatott a magzatja, meg testvérei és szomszédjai, és ő nincs meg.
11 Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
Hagyjad el árváidat, én majd életben tartom, és özvegyeid bennem bízzanak.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
Mert így szól az Örökkévaló: íme akiket nem illet meg inniuk a serleget, inniuk kell, és épen te maradnál büntetlen? Nem maradsz büntetlen, hanem innod kell.
13 Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
Mert magamra esküszöm, úgymond az Örökkévaló, bizony iszonyattá, gyalázattá, borzadássá és átokká lesz Boczra, és mind a városai örök romokká lesznek.
14 Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
Hírt hallottam az Örökkévalótól, és a nemzetek közé küldött követet: gyülekezzetek és jöjjetek ellene és keljetek fel a harcra.
15 “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
Mert íme kicsinnyé teszlek a nemzetek között, megvetetté az emberek közt.
16 Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
Rémület rád! Elámított téged szíved kevélysége, aki lakozol sziklahasadékokban, aki tartod a domb magasságát. Ha fennen rakod fészkedet, mint a sas, onnan döntlek le, úgymond az Örökkévaló.
17 “Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
És pusztulássá lesz Edóm; bárki elmegy mellette, eliszonyodik és pisszeg mind a csapásai fölött.
18 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
Szodoma és Amóra és szomszédjai feldúlásaként, mondja az Örökkévaló, nem fog ott lakni senki és nem tartózkodik benne ember fia.
19 “Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Íme, mint oroszlán, mely felszáll a Jordán büszkeségéből szilárd tanyára, egy szempillantás alatt elűzöm őt onnan és aki csak ki van választva, azt rendelem ellene. Mert ki olyan, mint én, ki idézhet meg engem és ki az a pásztor, aki megáll előttem?
20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
Azért halljátok az Örökkévaló határozatát, melyet Edómról határozott, és gondolatait, melyeket gondolt Témán lakóiról: bizony elhurcolják őket, a juhok legkisebbjeit, bizony elpusztítják velük együtt a tanyájukat.
21 Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
Esésük zajától megrendült a föld, jajkiáltás – a nádastengernél hallatszott a hangja.
22 Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
Íme mint a sas száll föl és repül és kiterjeszti szárnyait Boczra felett; és lesz Edóm hőseinek szíve azon a napon, mint: a vajúdó asszony szíve.
23 Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
Damaszkusról. Megszégyenült Chamát és Arpád, mert rossz hírt hallottak, elcsüggednek; a tengeren aggódás van, nem bír lecsillapodni.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
Ellankadt Damaszkus, futásra fordult és reszketés fogta el, kín és fájdalmak ragadták meg, mint a szülő nőt.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
Hogy nem hagyatott el a dicsőség városa, vígságom vára!
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Azért esnek el ifjai a piacain és mind a harcosok megsemmisülnek azon a napon, úgymond az Örökkévaló, a seregek ura.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
És tüzet gyújtok Damaszkus falában, hogy megeméssze Ben-Hadád kastélyait.
28 Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
Kédárról és Cháczór királyságairól, melyeket megvert Nebúkadnecczár, Bábel királya. Így szól az Örökkévaló Föl, vonuljatok fel Kédár ellen és pusztítsátok el a Kelet fiait.
29 Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
Sátraikat és juhaikat el fogják venni, kárpitjaikat és mind az edényeiket meg tevéiket el fogják vinni és azt kiáltják felőlük: rémület köröskörül!
30 “Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
Fussatok, bujdossatok nagyon, mélyre menjetek lakni, ti Cháczór lakói, úgymond az Örökkévaló; mert határozott ellenetek Nebúkadnecczár, Bábel királya határozatot és gondolt ellenetek gondolatot.
31 “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
Föl, vonuljatok fel egy boldog, biztonságban lakó nemzet ellen, úgymond az Örökkévaló, sem ajtói, sem retesze neki, egymagában lakik.
32 Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
És tevéik prédává lesznek és jószáguk sokasága zsákmánnyá és elszórom őket minden szélnek, a levágott hajfürtűeket; és minden oldalról elhozom balsorsukat, úgymond az Örökkévaló.
33 “Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
És lesz Cháczór sakálok tanyájává, pusztaság mindörökké, nem fog ott lakni senki, nem tartózkodik benne ember fia.
34 Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
Amely igéje az Örökkévalónak lett Jirmejáhú prófétához, Élámról, Czidkijáhú, Jehúda királya uralkodásának kezdetén, mondván:
35 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
Így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Íme én eltöröm Élám íját, vitézségük javát.
36 Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
És hozok Élámra négy szelet az ég négy végéről, elszórom őket mind a szeleknek; és nem lesz az a nemzet, ahova nem jönnének Élám elszéledtjei.
37 Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
És megrettentem Élámot ellenségeik előtt és azok előtt, kik életükre törnek és veszedelmet hozok rájuk, fellobbant haragomat, úgymond az Örökkévaló, és utánuk bocsátom a kardot, míg ki nem pusztítattam őket.
38 Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
És elhelyezem trónomat Élámban es elveszítek onnan királyt és nagyokat, úgymond az Örökkévaló.
39 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.
De lesz a napok végén, visszahozom Élám foglyait, úgymond az Örökkévaló.

< Jeremiah 49 >