< Jeremiah 49 >

1 Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
Des enfants d'Ammon. Yahvé dit: « Israël n'a-t-il pas de fils? N'a-t-il pas d'héritier? Pourquoi donc Malcam possède-t-il Gad, et son peuple habite dans ses villes?
2 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
C'est pourquoi, voici que les jours viennent, » dit Yahvé, « que je ferai entendre une alarme de guerre contre Rabbah des enfants d'Ammon, et elle deviendra un tas de ruines, et ses filles seront brûlées par le feu; alors Israël possédera ceux qui l'ont possédé, » dit Yahvé.
3 “Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
« Gémis, Hesbon, car Aï est dévastée! Pleurez, filles de Rabbah! Habille-toi d'une toile de sac. Se lamenter, et courir d'avant en arrière entre les clôtures; car Malcam ira en captivité, ses prêtres et ses princes ensemble.
4 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
Pourquoi vous vantez-vous dans les vallées, ta vallée fluide, fille rebelle? Vous avez fait confiance à ses trésors, en disant: « Qui viendra à moi?
5 Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Voici, je vais faire venir la terreur sur vous, » dit le Seigneur, Yahvé des Armées, « de tous ceux qui vous entourent. Vous serez tous chassés complètement, et il n'y aura personne pour rassembler les fugitifs.
6 “Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
« Mais ensuite, je renverserai la captivité des enfants d'Ammon, » dit Yahvé.
7 Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
Sur Edom, Yahvé des Armées dit: « La sagesse n'existe-t-elle plus à Teman? Le conseil a-t-il péri chez les prudents? Leur sagesse a-t-elle disparu?
8 Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
Fuyez! Faites demi-tour! Habitez dans les profondeurs, habitants de Dedan; car je ferai venir sur lui la calamité d'Ésaü quand je le visiterai.
9 Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
Si des vendangeurs venaient chez vous, ne laisseraient-ils pas quelques raisins à glaner? Si les voleurs venaient la nuit, ne voleraient-ils pas jusqu'à ce qu'ils en aient assez?
10 Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
Mais j'ai dépouillé Ésaü, J'ai découvert ses endroits secrets, et il ne pourra pas se cacher. Sa progéniture est détruite, avec ses frères et ses voisins; et il n'est plus.
11 Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
Laissez vos enfants sans père. Je vais les préserver en vie. Que vos veuves se confient en moi. »
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
Car Yahvé dit: « Voici, ceux à qui il n'appartenait pas de boire de la coupe vont certainement boire; et toi, es-tu celui qui restera impuni? Tu ne resteras pas impuni, mais tu boiras certainement.
13 Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
Car je l'ai juré par moi-même, dit l'Éternel, que Bozra sera un objet d'étonnement, d'opprobre, de désolation et de malédiction. Toutes ses villes seront des ruines perpétuelles. »
14 Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
J'ai entendu des nouvelles de Yahvé, et un ambassadeur est envoyé parmi les nations, en disant: « Rassemblez-vous! Venez contre elle! Levez-vous pour la bataille! »
15 “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
« Car voici, je t'ai rendu petit parmi les nations, et méprisé parmi les hommes.
16 Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
Quant à ta terreur, l'orgueil de ton cœur t'a trompé, O vous qui habitez dans les fentes du rocher, qui détiennent la hauteur de la colline, mais tu devrais faire ton nid aussi haut que l'aigle, Je te ferai descendre de là, dit Yahvé.
17 “Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
« Edom deviendra un objet d'étonnement. Tous ceux qui passeront devant seront étonnés, et sifflera à tous ses fléaux.
18 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
Comme lors du renversement de Sodome et Gomorrhe et de ses villes voisines, dit Yahvé, « aucun homme n'y habitera, aucun fils de l'homme n'y vivra.
19 “Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
« Voici qu'il monte comme un lion de l'orgueil du Jourdain contre la demeure forte; car je les ferai fuir soudainement, et celui qui est choisi, Je le nommerai à ce poste. Car qui est comme moi? Qui me fixera une heure? Qui est le berger qui se tiendra devant moi? »
20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
Écoutez donc le conseil de l'Éternel, qu'il a pris contre Édom, et les desseins qu'il a conçus contre les habitants de Teman: Ils vont sûrement les traîner loin, les petits du troupeau. Il fera de leur habitation une désolation.
21 Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
La terre tremble au bruit de leur chute; il y a un cri, le bruit que l'on entend dans la Mer Rouge.
22 Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
Voici qu'il s'élève et vole comme l'aigle, et il a déployé ses ailes contre Bozrah. Le cœur des puissants d'Édom, en ce jour, sera comme le cœur d'une femme en proie aux douleurs.
23 Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
de Damas: « Hamath et Arpad sont confondus, car ils ont entendu de mauvaises nouvelles. Ils ont fondu. Il y a du chagrin sur la mer. Ça ne peut pas être tranquille.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
Damas s'est affaiblie, elle se tourne vers la fuite, et le tremblement l'a saisie. L'angoisse et la tristesse se sont emparées d'elle, comme d'une femme en travail.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
Comment la ville de la louange n'est pas abandonnée, la ville de ma joie?
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
C'est pourquoi ses jeunes gens tomberont dans ses rues, et tous les hommes de guerre seront réduits au silence en ce jour-là, » dit Yahvé des Armées.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
« Je vais allumer un feu dans la muraille de Damas, et il dévorera les palais de Ben Hadad. »
28 Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
Sur Kédar et sur les royaumes de Hatsor, que Nebucadnetsar, roi de Babylone, a frappés, Yahvé dit: « Lève-toi, monte à Kedar, et détruire les enfants de l'est.
29 Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
Ils prendront leurs tentes et leurs troupeaux. ils emporteront pour eux-mêmes leurs rideaux, tous leurs vaisseaux, et leurs chameaux; et ils leur crient: « Terreur de tous les côtés!
30 “Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
Fuyez! Partez au loin! Habitez dans les profondeurs, habitants de Hatsor, dit Yahvé; « car Nebuchadnezzar, roi de Babylone, a pris conseil contre vous, et a conçu un dessein contre vous.
31 “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
Levez-vous! Montez vers une nation qui est à l'aise, qui habite sans souci », dit Yahvé; « qui n'a ni portes ni barreaux, qui habite seul.
32 Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
Leurs chameaux seront un butin, et la multitude de leur bétail un butin. Je disperserai à tous les vents ceux qui ont les coins de leur barbe coupés; et j'amènerai leur calamité de chaque côté d'eux, » dit Yahvé.
33 “Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
Hatsor sera un repaire de chacals, une désolation pour toujours. Aucun homme n'y habitera, aucun fils de l'homme n'y vivra. »
34 Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
Parole de Yahvé qui fut adressée à Jérémie, le prophète, au sujet d'Élam, au commencement du règne de Sédécias, roi de Juda, en ces termes:
35 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
« Yahvé des armées dit: « Voici, je vais briser l'arc d'Elam. le chef de leur force.
36 Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
Je ferai venir sur Élam les quatre vents des quatre coins du ciel, et les dispersera vers tous ces vents. Il n'y aura pas de nation où les parias d'Élam ne viendront pas.
37 Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
Je ferai en sorte que l'Élam soit consterné devant ses ennemis, et devant ceux qui cherchent leur vie. Je ferai venir sur eux le malheur, mon ardente colère, dit Yahvé; et j'enverrai l'épée après eux, jusqu'à ce que je les aie consommés.
38 Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
Je placerai mon trône en Élam, et je détruirai de là le roi et les princes, dit Yahvé.
39 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.
« Mais cela arrivera dans la suite des temps ». que je renverserai la captivité d'Élam, dit Yahvé. »

< Jeremiah 49 >