< Jeremiah 48 >

1 Nípa Moabu. Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Ègbé ni fún Nebo nítorí a ó parun. A dójútì Kiriataimu, a sì mú un, ojú yóò ti alágbára, a ó sì fọ́nká.
Nea ɛfa Moab ho: Sɛɛ na Awurade, Israel Nyankopɔn se: “Nebo nnue, na wɔbɛsɛe no. Wobegu Kiriataim anim ase, na wɔafa; wobegu aban dennen no anim ase, na wɔadwiriw agu fam.
2 Moabu kò ní ní ìyìn mọ́, ní Heṣboni ni wọn ó pète ìparun rẹ̀, ‘Wá, kí a pa orílẹ̀-èdè náà run.’ Àti ẹ̀yin òmùgọ̀ ọkùnrin pàápàá ni a ó pa lẹ́nu mọ́, a ó fi idà lé e yín.
Wɔrenkamfo Moab bio; Hesbon mmarima bɛbɔ nʼasehwe ho pɔw; ‘Mommra, momma yɛnkɔbɔ saa ɔman yi.’ Mo nso, Madmen mmarima mobɛka mo ano ato mu; afoa no bɛtaa mo.
3 Gbọ́ igbe ní Horonaimu, igbe ìrora àti ìparun ńlá.
Muntie osu a efi Horonaim, adesɛe ne ɔsɛe ho su.
4 Moabu yóò di wíwó palẹ̀; àwọn ọmọdé rẹ̀ yóò kígbe síta.
Wɔbɛbɔ Moab: na ne mma nketewa bɛteɛteɛ mu.
5 Wọ́n gòkè lọ sí Luhiti, wọ́n ń sọkún kíkorò bí wọ́n ti ń lọ; ní ojú ọ̀nà sí Horonaimu igbe ìrora ìparun ni à ń gbọ́ lọ.
Wɔforo kɔ Luhit, wɔde agyaadwotwa a mu yɛ den na ɛrekɔ; ɔkwan a ɛkɔ Horonaim so no wɔte ahoyeraw nteɛteɛmu wɔ adesɛe no ho.
6 Sá! Àsálà fún ẹ̀mí yín; kí ẹ sì dàbí aláìní ní aginjù.
Munguan! muntu mmirika mpere mo nkwa. Monyɛ sɛ wura wɔ nweatam so.
7 Níwọ́n ìgbà tí o gbẹ́kẹ̀lé agbára àti ọrọ̀ rẹ, a ó kó ìwọ náà ní ìgbèkùn, Kemoṣi náà yóò lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn pẹ̀lú àlùfáà àti àwọn aláṣẹ rẹ̀.
Esiane sɛ mode mo ho to mo nneyɛe ne mo ahonya so nti, mo nso wɔbɛfa mo nnommum, na Kemos bɛkɔ nnommum mu, ɔne nʼasɔfo ne adwumayɛfo.
8 Gbogbo ìlú rẹ ni apanirun yóò dojúkọ, ìlú kan kò sì ní le là. Àfonífojì yóò di ahoro àti ilẹ̀ títẹ́ ni a ó run, nítorí tí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Ɔsɛefo no betu kurow biara so sa, na mu biara rennya ne ho ntetew. Wɔbɛsɛe obon no na wasɛe mmepɔw mpampam a ɛyɛ tamaa no, efisɛ Awurade akasa.
9 Fi iyọ̀ sí Moabu, nítorí yóò ṣègbé, àwọn ìlú rẹ yóò sì di ahoro láìsí ẹni tí yóò gbé inú rẹ̀.
Momfa nkyene nhyɛ Moab, efisɛ wɔrebɛsɛe no; ne nkurow bɛda mpan a obiara rentena mu.
10 “Ìfibú ni fún ẹni tí ó fi ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ Olúwa, ìfibú ni fún ẹni tí ó pa idà mọ́ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
“Nnome nka nea ɔtwentwɛn ne nan ase wɔ Awurade adwumayɛ ho! Nnome nka nea ɔmmfa nʼafoa nhwie mogya ngu!
11 “Moabu ti wà ní ìsinmi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá bí i ọtí wáìnì lórí gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀, tí a kò dà láti ìgò kan sí èkejì kò tí ì lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn rí. Ó dùn lẹ́nu bí ó ti yẹ, òórùn rẹ̀ kò yí padà.
“Moab atena ase asomdwoe mu fi ne mmerantebere mu, te sɛ nsa ase puw a ataa dinn, wonnhwie mfi ahina mu nkogu ahina foforo mu, ɔnkɔɔ nnommum mu da. Enti ɔte sɛ nea ɔte ara, na ne ho hua nsakrae ɛ.
12 Ṣùgbọ́n ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí n ó rán àwọn tí ó n da ọtí láti inú àwọn ìgò tí wọ́n ó sì dà á síta; wọn ó sọ àwọn ìgò rẹ̀ di òfo, wọn ó sì fọ́ àwọn ife rẹ̀.
Nanso nna bi reba,” Awurade na ose, “a mɛsoma mmarima a wohwie fi ahina mu, na wobehwie no agu; wɔbɛma nʼahina mu ayɛ hwee na wɔabobɔ ne nkuruwa.
13 Nígbà náà Moabu yóò sì tú u nítorí Kemoṣi, bí ojú ti í ti ilé Israẹli nígbà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Beteli.
Afei Kemos ho bɛyɛ Moab aniwu, sɛnea Israelfi anim guu ase bere a wɔde wɔn ho too Bet-El so no.
14 “Báwo ni o ṣe lè sọ pé, ‘Ajagun ni wá, alágbára ní ogun jíjà’?
“Ɛbɛyɛ dɛn na wutumi ka se, ‘Yɛyɛ dɔmmarima, mmarima akokodurufo wɔ ɔsa mu’?
15 A ó pa Moabu run, a ó sì gba àwọn ìlú rẹ̀; a ó sì dúńbú àwọn arẹwà ọkùnrin rẹ̀,” ni ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Wɔbɛsɛe Moab na wɔatu ne nkurow so sa; wobekunkum ne mmerante a wɔte apɔw no,” nea Ɔhene a wɔfrɛ no Asafo Awurade no se ni.
16 “Ìṣubú Moabu súnmọ́; ìpọ́njú yóò dé kánkán.
“Moab asehwe abɛn; nʼamanehunu bɛba ntɛm.
17 Ẹ dárò fún, gbogbo ẹ̀yin tí ó yí i ká gbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ bí ó ti ní òkìkí tó. Ẹ sọ pé, ‘Báwo ni ọ̀pá agbára rẹ títóbi tí ó sì lógo ṣe fọ́!’
Munsu no, mo a motete ne ho nyinaa, ne mo a munim ne din nyinaa; monka se, ‘Ɛyɛɛ dɛn na wɔabubu ahempema a ɛyɛ den yi ɛyɛɛ dɛn wɔabu anuonyam pema fɛfɛ yi mu!’
18 “Sọ̀kalẹ̀ níbi ògo rẹ, kí o sì jókòó ní ilẹ̀ gbígbẹ, ẹ̀yin olùgbé ọmọbìnrin Diboni, nítorí tí ẹni tí ó pa Moabu run yóò dojúkọ ọ́ yóò sì pa àwọn ìlú olódi rẹ run.
“Fi wʼanuonyam mu, na bɛtena asase wosee no so, wo a wote Dibon Babea, efisɛ nea ɔsɛe Moab no betu aba wo so abɛsɛe wo nkuropɔn a ɛwɔ bammɔ no.
19 Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o sì wòran, ìwọ tí ń gbé ní Aroeri. Bí ọkùnrin tí ó sálọ àti obìnrin tí ó ń sá àsálà ‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀?’
Gyina kwankyɛn na hwɛ, wo a wote Aroer. Bisa ɔbarima a ɔreguan no ne ɔbea a ɔrefi mu afi, bisa wɔn se, ‘Asɛm bɛn na asi?’
20 Ojú ti Moabu nítorí tí a wó o lulẹ̀. Ẹ hu, kí ẹ sì kígbe! Ẹ kéde rẹ̀ ní Arnoni pé, a pa Moabu run.
Moab anim agu ase, efisɛ wɔabubu no pasaa; muntwa adwo na monteɛteɛ mu! Mommɔ dawuru wɔ Arnon ho se wɔasɛe Moab.
21 Ìdájọ́ ti dé sí àwọn òkè pẹrẹsẹ, sórí Holoni, Jahisa àti Mefaati,
Atemmu aba bepɔw tamaa so wɔ Holon, Yahas ne Mefaat,
22 sórí Diboni, Nebo àti Beti-Diblataimu,
Dibon ne Nebo ne Bet-Diblataim
23 sórí Kiriataimu, Beti-Gamu àti Beti-Meoni,
ne Kiriataim ne Bet Gamul ne Bet Meon
24 sórí Kerioti àti Bosra, sórí gbogbo ìlú Moabu, nítòsí àti ní ọ̀nà jíjìn.
ne Keriot ne Bosra wɔ Moab nkurow nyinaa, nea ɛwɔ akyirikyiri ne nea ɛbɛn.
25 A gé ìwo Moabu kúrò, apá rẹ̀ dá,” ni Olúwa wí.
Wɔatwa Moab mmɛn; na ne basa abu,” Awurade na ose.
26 “Ẹ jẹ́ kí a mú u mutí nítorí ó kó ìdọ̀tí bá Olúwa, jẹ́ kí Moabu lúwẹ̀ẹ́ nínú èébì rẹ̀, kí ó di ẹni ẹ̀gàn.
“Momma no mmow nsa, efisɛ wabu Awurade animtiaa. Momma Moab nyantam wɔ ne fe mu; momma no nyɛ nea wodi ne ho fɛw.
27 Ǹjẹ́ Israẹli kò di ẹni ẹ̀gàn rẹ? Ǹjẹ́ a kó o pẹ̀lú àwọn olè tó bẹ́ẹ̀ tí o ń gbọn orí rẹ̀ pẹ̀lú yẹ̀yẹ́ nígbàkígbà bí a bá sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀?
Ɛnyɛ Israel na na wudi ne ho fɛw? Wɔkyeree no akorɔmfo mu ana, a enti mowosow mo ti animtiaabu so bere biara a mobɛka ne ho asɛm?
28 Kúrò ní àwọn ìlú rẹ, kí o sì máa gbé láàrín àwọn òkúta, ẹ̀yin tí ó ti ń gbé inú ìlú Moabu. Ẹ dàbí i àdàbà tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí ẹnu ihò.
Mumfifi mo nkurow so nkɔtena abotan mu, mo a motete Moab. Monyɛ sɛ aborɔnoma a ɔyɛ ne berebuw wɔ ɔbodan ano.
29 “A ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu: àti ìwà mo gbọ́n tan rẹ̀ àti ìgbéraga ọkàn rẹ̀.
“Yɛate Moab ahantan no nʼahomaso ne gye a ogye ne ho di mmoroso; nʼahantan ne nʼahomaso, ne ne koma mu ahohoahoa.
30 Mo mọ àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n òfo ni,” ni Olúwa wí, “ìfọ́nnu rẹ̀ kò lè ṣe nǹkan kan.
Minim nʼasoɔden nanso ɛyɛ ɔkwa,” Awurade na ose, “na nʼahohoahoa mfa hwee mma.
31 Nítorí náà, mo pohùnréré ẹkún lórí Moabu fún àwọn ará Moabu ni mo kígbe lóhùn rara, mo kẹ́dùn fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti.
Enti mitwa adwo ma Moab, misu teɛ mu ma Moabfo nyinaa, midi awerɛhow ma nnipa a wɔwɔ Kir Hereset.
32 Mo sọkún fún ọ bí Jaseri ṣe sọkún ìwọ àjàrà Sibma. Ẹ̀ka rẹ tẹ̀ títí dé Òkun, wọn dé Òkun Jaseri. Ajẹnirun ti kọlu èso rẹ, ìkórè èso àjàrà rẹ.
Misu ma mo sɛnea Yaser su, mo Sibma bobe. Mo mman dennan kɔɔ po ho pɛɛ; koduu Yaser po ho. Ɔsɛefo no abegu mo nnuaba a abere ne mo bobe no so.
33 Ayọ̀ àti ìdùnnú ti kúrò nínú ọgbà àjàrà àti oko Moabu. Mo dá ọwọ́ ṣíṣàn ọtí wáìnì dúró lọ́dọ̀ olùfúntí; kò sí ẹni tí ó ń tẹ̀ wọ́n pẹ̀lú igbe ayọ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé igbe wà, wọn kì í ṣe igbe ti ayọ̀.
Ahosɛpɛw ne anigye atu afi Moab nnuaba nturo ne mfuw so. Matwa nsa a ɛteɛ fi nsakyiamoa no so; obiara mmfa ahosɛpɛw ntiatia bobe no so. Ɛwɔ mu nteɛteɛmu wɔ hɔ de, nanso ɛnyɛ ahosɛpɛw nteɛteɛmu.
34 “Ohùn igbe wọn gòkè láti Heṣboni dé Eleale àti Jahasi, láti Soari títí dé Horonaimu àti Eglati-Ṣeliṣi, nítorí àwọn omi Nimrimu pẹ̀lú yóò gbẹ.
“Wɔn su ano den gyigye fi Hesbon kɔ Eleale ne Yahas, fi Soar de kosi Horonaim ne Eglat Selisiya, mpo, nsu a ɛwɔ Nimrim no ayow.
35 Ní ti Moabu ni èmi yóò ti fi òpin sí ẹni tí ó rú ẹbọ ní ibí gíga àti ẹni tí ń sun tùràrí fún òrìṣà rẹ̀,” ni Olúwa wí.
Moab mu, mede sorɔnsorɔmmea afɔrebɔ ne nnuhuam a wɔhyew ma wɔn anyame no, bɛba awiei,” Awurade, na ose.
36 “Nítorí náà ọkàn mi ró fún Moabu bí fèrè, ọkàn mi ró bí fèrè fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti. Nítorí ìṣúra tí ó kójọ ṣègbé.
“Enti me koma su sɛ atɛntɛbɛn ma Moab; esu sɛ atɛntɛbɛn ma nnipa a wɔwɔ Kir Hereset. Ahonyade a wɔpɛe no kɔ.
37 Gbogbo orí ni yóò pá, gbogbo irùngbọ̀n ni a ó gé kúrò, gbogbo ọwọ́ ni a sá lọ́gbẹ́, àti aṣọ ọ̀fọ̀ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́.
Wɔabɔ eti biara tikwaw na wɔayi abogyesɛ biara; nsa nyinaa ho ayɛ akamakam na atweaatam sisi obiara asen.
38 Ẹkún ńlá ní yóò wà lórí gbogbo òrùlé Moabu, àti ní ìta rẹ̀, nítorí èmi ti fọ́ Moabu bí a ti ń fọ́ ohun èlò tí kò wu ni,” ni Olúwa wí.
Adan a ɛwɔ Moab nyinaa atifi ne ɔmanfo aguabɔbea nyinaa; biribiara nni hɔ sɛ awerɛhow, efisɛ mabubu Moab ayɛ no sɛ ahina a obiara mpɛ,” Awurade na ose.
39 “Èéṣe tí ẹ fi fọ́ túútúú, tí ẹ sì fi ń pohùnréré ẹkún! Báwo ni Moabu ṣe yí ẹ̀yìn padà ní ìtìjú! Moabu ti di ẹni ìtìjú àti ẹ̀gàn àti ìdààmú sí gbogbo àwọn tí ó yìí ká.”
“Hwɛ sɛnea wabubu afa! Hwɛ sɛnea wɔretwa adwo! Na hwɛ sɛnea Moab de aniwu dan nʼakyi! Moab ayɛ nea wodi ne ho fɛw, ne ahodwiriwde ama wɔn a wɔatwa ne ho ahyia nyinaa.”
40 Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀ ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Moabu.
Sɛɛ na Awurade se: “Monhwɛ! ɔkɔre rebɔ hoo aba fam. Watrɛw ne ntaban mu wɔ Moab so.
41 Kerioti ni a ó kó lẹ́rú àti ilé agbára ni ó gbà. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn akọni Moabu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.
Wɔbɛfa Keriot nnommum na wɔafa nʼabandennen no. Saa da no Moab dɔmmarima koma betu sɛ ɔbea a ɔrekyem wɔ awo so.
42 A ó pa Moabu run gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè nítorí pé ó gbéraga sí Olúwa.
Wɔbɛsɛe Moab na ɛrenyɛ ɔman bio, efisɛ obuu Awurade animtiaa.
43 Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídè ń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Moabu,” ní Olúwa wí.
Ehu, nkonomoa ne afiri retwɛn mo, Moabfo,” Awurade na ose.
44 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá fún ẹ̀rù yóò ṣubú sínú ọ̀fìn ẹnikẹ́ni tí o bá jáde síta nínú ọ̀fìn ní à ó mú nínú okùn dídè nítorí tí èmi yóò mú wá sórí Moabu àní ọdún ìjìyà rẹ,” ní Olúwa wí.
“Nea oguan nea ɛyɛ hu no bɛtɔ nkonomoa mu, nea ɔbɛforo afi nkonomoa no mu no afide beyi no; na mede Moab asotwe afe no bɛba ne so,” Awurade na ose.
45 “Ní abẹ́ òjìji Heṣboni àwọn tí ó sá dúró láìní agbára, nítorí iná ti jáde wá láti Heṣboni, àti ọwọ́ iná láti àárín Sihoni, yóò sì jó iwájú orí Moabu run, àti agbárí àwọn ọmọ aláriwo.
“Hesbon nwini ase na aguanfo no gyinagyina a wonni mmoa biara, efisɛ ogya bi atu afi Hesbon; ogyaframa bi fi Sihon mfimfini; ɛhyew Moab moma, ne ahohoahoafo a wɔn ano yɛ den no ti koraa.
46 Ègbé ní fún ọ Moabu! Àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè Kemoṣi ṣègbé a kó àwọn ọmọkùnrin rẹ lọ sí ilẹ̀ àjèjì àti àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ sí ìgbèkùn.
Nnome nka wo, wo Moab! Wɔasɛe Kemos nkurɔfo no; wɔde wo mmabarima kɔ nnommum mu na wo mmabea nso kɔ nkoasom mu.
47 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Moabu padà ní ọjọ́ ìkẹyìn,” ni Olúwa wí. Eléyìí ní ìdájọ́ ìkẹyìn lórí Moabu.
“Nanso mede Moab adenya bɛsan ama no wɔ nna a ɛbɛba no mu,” Awurade na ose. Moab atemmu no awiei ni.

< Jeremiah 48 >