< Jeremiah 48 >

1 Nípa Moabu. Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Ègbé ni fún Nebo nítorí a ó parun. A dójútì Kiriataimu, a sì mú un, ojú yóò ti alágbára, a ó sì fọ́nká.
Concerning Moab: “Thus said YHWH of Hosts, God of Israel: Woe to Nebo, for it is spoiled, Kiriathaim has been captured [and] put to shame, The high tower has been put to shame, Indeed, it has been broken down.
2 Moabu kò ní ní ìyìn mọ́, ní Heṣboni ni wọn ó pète ìparun rẹ̀, ‘Wá, kí a pa orílẹ̀-èdè náà run.’ Àti ẹ̀yin òmùgọ̀ ọkùnrin pàápàá ni a ó pa lẹ́nu mọ́, a ó fi idà lé e yín.
There is no longer praise of Moab, In Heshbon they devised evil against her: Come, and we cut it off from [being] a nation, Also, O Madmen, you are cut off, A sword goes after you.
3 Gbọ́ igbe ní Horonaimu, igbe ìrora àti ìparun ńlá.
A voice of a cry [is] from Horonaim, Spoiling and great destruction.
4 Moabu yóò di wíwó palẹ̀; àwọn ọmọdé rẹ̀ yóò kígbe síta.
Moab has been destroyed, Her little ones have caused a cry to be heard.
5 Wọ́n gòkè lọ sí Luhiti, wọ́n ń sọkún kíkorò bí wọ́n ti ń lọ; ní ojú ọ̀nà sí Horonaimu igbe ìrora ìparun ni à ń gbọ́ lọ.
For the ascent of Luhith with weeping, Weeping goes up, For in the descent of Horonaim Adversaries have heard a cry of desolation.
6 Sá! Àsálà fún ẹ̀mí yín; kí ẹ sì dàbí aláìní ní aginjù.
Flee, deliver yourselves, You are as a naked thing in a wilderness.
7 Níwọ́n ìgbà tí o gbẹ́kẹ̀lé agbára àti ọrọ̀ rẹ, a ó kó ìwọ náà ní ìgbèkùn, Kemoṣi náà yóò lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn pẹ̀lú àlùfáà àti àwọn aláṣẹ rẹ̀.
For because of your trusting in your works, And in your treasures, even you are captured, And Chemosh has gone out in a removal, His priests and his heads together.
8 Gbogbo ìlú rẹ ni apanirun yóò dojúkọ, ìlú kan kò sì ní le là. Àfonífojì yóò di ahoro àti ilẹ̀ títẹ́ ni a ó run, nítorí tí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
And a spoiler comes to every city, And no city escapes, And the valley has perished, And the plain has been destroyed, as YHWH said.
9 Fi iyọ̀ sí Moabu, nítorí yóò ṣègbé, àwọn ìlú rẹ yóò sì di ahoro láìsí ẹni tí yóò gbé inú rẹ̀.
Give wings to Moab, that she may go forth and flee away, And her cities are for a desolation, Without an inhabitant in them.
10 “Ìfibú ni fún ẹni tí ó fi ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ Olúwa, ìfibú ni fún ẹni tí ó pa idà mọ́ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
Cursed [is] he who is doing the work of YHWH slothfully, And cursed [is] he Who is withholding his sword from blood.
11 “Moabu ti wà ní ìsinmi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá bí i ọtí wáìnì lórí gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀, tí a kò dà láti ìgò kan sí èkejì kò tí ì lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn rí. Ó dùn lẹ́nu bí ó ti yẹ, òórùn rẹ̀ kò yí padà.
Moab is secure from his youth, And he [is] at rest for his preserved things, And he has not been emptied out from vessel to vessel, And he has not gone into captivity, Therefore his taste has remained in him, And his fragrance has not been changed.
12 Ṣùgbọ́n ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí n ó rán àwọn tí ó n da ọtí láti inú àwọn ìgò tí wọ́n ó sì dà á síta; wọn ó sọ àwọn ìgò rẹ̀ di òfo, wọn ó sì fọ́ àwọn ife rẹ̀.
Therefore, behold, days are coming, A declaration of YHWH, And I have sent wanderers to him, And they have caused him to wander, And they empty out his vessels, And they dash his bottles in pieces.
13 Nígbà náà Moabu yóò sì tú u nítorí Kemoṣi, bí ojú ti í ti ilé Israẹli nígbà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Beteli.
And Moab has been ashamed because of Chemosh, As the house of Israel has been ashamed Because of Beth-El, their confidence.
14 “Báwo ni o ṣe lè sọ pé, ‘Ajagun ni wá, alágbára ní ogun jíjà’?
How do you say, We [are] mighty, And men of strength for battle?
15 A ó pa Moabu run, a ó sì gba àwọn ìlú rẹ̀; a ó sì dúńbú àwọn arẹwà ọkùnrin rẹ̀,” ni ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Moab is spoiled, and has gone up [from] her cities, And the choice of its young men Have gone down to slaughter, An affirmation of the King, YHWH of Hosts [is] His Name.
16 “Ìṣubú Moabu súnmọ́; ìpọ́njú yóò dé kánkán.
The destruction of Moab is near to come, And his calamity has hurried exceedingly.
17 Ẹ dárò fún, gbogbo ẹ̀yin tí ó yí i ká gbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ bí ó ti ní òkìkí tó. Ẹ sọ pé, ‘Báwo ni ọ̀pá agbára rẹ títóbi tí ó sì lógo ṣe fọ́!’
Bemoan for him, all you around him, And all knowing his name, say, How it has been broken, the staff of strength, The rod of beauty!
18 “Sọ̀kalẹ̀ níbi ògo rẹ, kí o sì jókòó ní ilẹ̀ gbígbẹ, ẹ̀yin olùgbé ọmọbìnrin Diboni, nítorí tí ẹni tí ó pa Moabu run yóò dojúkọ ọ́ yóò sì pa àwọn ìlú olódi rẹ run.
Come down from glory, sit in thirst, O inhabitant, daughter of Dibon, For a spoiler of Moab has come up to you, He has destroyed your fortifications.
19 Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o sì wòran, ìwọ tí ń gbé ní Aroeri. Bí ọkùnrin tí ó sálọ àti obìnrin tí ó ń sá àsálà ‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀?’
Stand on the way, and watch, O inhabitant of Aroer, Ask the fugitive and escaped, Say, What has happened?
20 Ojú ti Moabu nítorí tí a wó o lulẹ̀. Ẹ hu, kí ẹ sì kígbe! Ẹ kéde rẹ̀ ní Arnoni pé, a pa Moabu run.
Moab has been put to shame, For it has been broken down, Howl and cry, declare in Arnon, For Moab is spoiled,
21 Ìdájọ́ ti dé sí àwọn òkè pẹrẹsẹ, sórí Holoni, Jahisa àti Mefaati,
And judgment has come to the land of the plain—to Holon, And to Jahazah, and on Mephaath,
22 sórí Diboni, Nebo àti Beti-Diblataimu,
And on Dibon, and on Nebo, And on Beth-Diblathaim, and on Kirathaim,
23 sórí Kiriataimu, Beti-Gamu àti Beti-Meoni,
And on Beth-Gamul, and on Beth-Meon,
24 sórí Kerioti àti Bosra, sórí gbogbo ìlú Moabu, nítòsí àti ní ọ̀nà jíjìn.
And on Kerioth, and on Bozrah, And on all cities of the land of Moab, The far off and the near.
25 A gé ìwo Moabu kúrò, apá rẹ̀ dá,” ni Olúwa wí.
The horn of Moab has been cut down, And his arm has been broken, A declaration of YHWH.
26 “Ẹ jẹ́ kí a mú u mutí nítorí ó kó ìdọ̀tí bá Olúwa, jẹ́ kí Moabu lúwẹ̀ẹ́ nínú èébì rẹ̀, kí ó di ẹni ẹ̀gàn.
Declare him drunk, For he made himself great against YHWH And Moab has struck in his vomit, And he has been for a derision—even he.
27 Ǹjẹ́ Israẹli kò di ẹni ẹ̀gàn rẹ? Ǹjẹ́ a kó o pẹ̀lú àwọn olè tó bẹ́ẹ̀ tí o ń gbọn orí rẹ̀ pẹ̀lú yẹ̀yẹ́ nígbàkígbà bí a bá sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀?
And was Israel not the derision to you? Was he found among thieves? For since your words concerning him, You bemoan yourself.
28 Kúrò ní àwọn ìlú rẹ, kí o sì máa gbé láàrín àwọn òkúta, ẹ̀yin tí ó ti ń gbé inú ìlú Moabu. Ẹ dàbí i àdàbà tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí ẹnu ihò.
Forsake cities, and dwell in a rock, You inhabitants of Moab, And be as a dove making a nest in the passages of a pit’s mouth.
29 “A ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu: àti ìwà mo gbọ́n tan rẹ̀ àti ìgbéraga ọkàn rẹ̀.
We have heard of the arrogance of Moab, Exceedingly proud! His haughtiness, and his arrogance, And his pride, and the height of his heart,
30 Mo mọ àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n òfo ni,” ni Olúwa wí, “ìfọ́nnu rẹ̀ kò lè ṣe nǹkan kan.
I have known, a declaration of YHWH, His wrath, and [it is] not right, His boastings—they have done nothing right.
31 Nítorí náà, mo pohùnréré ẹkún lórí Moabu fún àwọn ará Moabu ni mo kígbe lóhùn rara, mo kẹ́dùn fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti.
Therefore I howl for Moab, even for Moab—all of it, I cry for men of Kir-Heres, it mourns,
32 Mo sọkún fún ọ bí Jaseri ṣe sọkún ìwọ àjàrà Sibma. Ẹ̀ka rẹ tẹ̀ títí dé Òkun, wọn dé Òkun Jaseri. Ajẹnirun ti kọlu èso rẹ, ìkórè èso àjàrà rẹ.
With the weeping of Jazer, I weep for you, O vine of Sibmah, Your branches have passed over a sea, They have come to the Sea of Jazer, On your summer fruits, and on your harvest, A spoiler has fallen.
33 Ayọ̀ àti ìdùnnú ti kúrò nínú ọgbà àjàrà àti oko Moabu. Mo dá ọwọ́ ṣíṣàn ọtí wáìnì dúró lọ́dọ̀ olùfúntí; kò sí ẹni tí ó ń tẹ̀ wọ́n pẹ̀lú igbe ayọ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé igbe wà, wọn kì í ṣe igbe ti ayọ̀.
And joy and gladness have been removed from the fruitful field, Even from the land of Moab, And I have caused wine to cease from winepresses, Shouting does not proceed, The shouting [is] not shouting!
34 “Ohùn igbe wọn gòkè láti Heṣboni dé Eleale àti Jahasi, láti Soari títí dé Horonaimu àti Eglati-Ṣeliṣi, nítorí àwọn omi Nimrimu pẹ̀lú yóò gbẹ.
Because of the cry of Heshbon to Elealeh, They have given their voice to Jahaz, From Zoar to Horonaim, A heifer of the third [year], For even [the] waters of Nimrim become desolations.
35 Ní ti Moabu ni èmi yóò ti fi òpin sí ẹni tí ó rú ẹbọ ní ibí gíga àti ẹni tí ń sun tùràrí fún òrìṣà rẹ̀,” ni Olúwa wí.
And I have caused to cease in Moab, A declaration of YHWH, Him who is offering in a high place, And him who is making incense to his god.
36 “Nítorí náà ọkàn mi ró fún Moabu bí fèrè, ọkàn mi ró bí fèrè fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti. Nítorí ìṣúra tí ó kójọ ṣègbé.
Therefore My heart sounds as pipes for Moab, And My heart sounds as pipes for men of Kir-Heres, Therefore the abundance he made perished.
37 Gbogbo orí ni yóò pá, gbogbo irùngbọ̀n ni a ó gé kúrò, gbogbo ọwọ́ ni a sá lọ́gbẹ́, àti aṣọ ọ̀fọ̀ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́.
For every head [is] bald, and every beard diminished, On all hands—cuttings, and on the loins—sackcloth.
38 Ẹkún ńlá ní yóò wà lórí gbogbo òrùlé Moabu, àti ní ìta rẹ̀, nítorí èmi ti fọ́ Moabu bí a ti ń fọ́ ohun èlò tí kò wu ni,” ni Olúwa wí.
On all roofs of Moab, and in her broad-places, All of it—lamentation, For I have broken Moab as a vessel in which there is no pleasure,” A declaration of YHWH.
39 “Èéṣe tí ẹ fi fọ́ túútúú, tí ẹ sì fi ń pohùnréré ẹkún! Báwo ni Moabu ṣe yí ẹ̀yìn padà ní ìtìjú! Moabu ti di ẹni ìtìjú àti ẹ̀gàn àti ìdààmú sí gbogbo àwọn tí ó yìí ká.”
“How it has been broken down! They have howled, How Moab has turned the neck ashamed! And Moab has been for a derision And for a terror to all around her.”
40 Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀ ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Moabu.
For thus said YHWH: “Behold, he flees as an eagle, And has spread his wings to Moab.
41 Kerioti ni a ó kó lẹ́rú àti ilé agbára ni ó gbà. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn akọni Moabu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.
The cities have been captured, And the strongholds are caught, And the heart of the mighty of Moab Has been in that day as the heart of a distressed woman.
42 A ó pa Moabu run gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè nítorí pé ó gbéraga sí Olúwa.
And Moab has been destroyed from [being] a people, For he exerted himself against YHWH.
43 Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídè ń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Moabu,” ní Olúwa wí.
Fear, and a snare, and a trap, [are] for you, O inhabitant of Moab—a declaration of YHWH,
44 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá fún ẹ̀rù yóò ṣubú sínú ọ̀fìn ẹnikẹ́ni tí o bá jáde síta nínú ọ̀fìn ní à ó mú nínú okùn dídè nítorí tí èmi yóò mú wá sórí Moabu àní ọdún ìjìyà rẹ,” ní Olúwa wí.
Whoever is fleeing because of the fear falls into the snare, And whoever is coming up from the snare is captured by the trap, For I bring to her—to Moab—The year of their inspection, A declaration of YHWH.
45 “Ní abẹ́ òjìji Heṣboni àwọn tí ó sá dúró láìní agbára, nítorí iná ti jáde wá láti Heṣboni, àti ọwọ́ iná láti àárín Sihoni, yóò sì jó iwájú orí Moabu run, àti agbárí àwọn ọmọ aláriwo.
In the shadow of Heshbon fugitives have stood powerless, For fire has gone forth from Heshbon, And a flame from within Sihon, And it consumes the corner of Moab, And the crown of the sons of Shaon.
46 Ègbé ní fún ọ Moabu! Àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè Kemoṣi ṣègbé a kó àwọn ọmọkùnrin rẹ lọ sí ilẹ̀ àjèjì àti àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ sí ìgbèkùn.
Woe to you, O Moab, The people of Chemosh have perished, For your sons were taken with the captives, And your daughters with the captivity.
47 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Moabu padà ní ọjọ́ ìkẹyìn,” ni Olúwa wí. Eléyìí ní ìdájọ́ ìkẹyìn lórí Moabu.
And I have turned back [to] the captivity of Moab, In the latter end of the days,” A declaration of YHWH! “Until now [is] the judgment of Moab.”

< Jeremiah 48 >