< Jeremiah 46 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa àwọn Orílẹ̀-èdè.
Eyi ne asɛm a efi Awurade nkyɛn baa odiyifo Yeremia hɔ a ɛfa aman no ho.
2 Nípa Ejibiti. Èyí ni ọ̀rọ̀ nípa àwọn ọmọ-ogun Farao Neko ọba Ejibiti ẹni tí a borí rẹ̀ ní Karkemiṣi, ní odò Eufurate láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:
Nea ɛfa Misraim ho: Eyi ne nsɛm a etia Misraimhene Farao Neko asraafo a Babiloniahene Nebukadnessar dii wɔn so nkonim wɔ Karkemis, Asubɔnten Eufrate ho wɔ Yudahene Yosia babarima Yehoiakim adedi afe a ɛto so anan no:
3 “Ẹ múra àpáta, èyí tí ó tóbi, àti èyí tí ó kéré, kí ẹ sì súnmọ́ ojú ìjà!
“Siesie wo nkatabo akɛse ne nketewa nyinaa, na muntu santen nkɔ ɔsa!
4 Ẹ di ẹṣin ní gàárì, kí ẹ sì gùn ún. Ẹ dúró lẹ́sẹẹsẹ pẹ̀lú àṣíborí yín! Ẹ dán ọ̀kọ̀ yín, kí ẹ sì wọ ẹ̀wù irin.
Munsiesie apɔnkɔ no, na momforo ntenatena wɔn so. Munnyinagyina mo afa a mohyehyɛ mo nnade kyɛw! Monsew mo mpeaw ano, na monhyɛ mo nkatabo.
5 Kí ni nǹkan tí mo tún rí? Wọ́n bẹ̀rù, wọ́n sì ń padà sẹ́yìn, wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn jagunjagun. Wọ́n sá, wọn kò sì bojú wẹ̀yìn, ìbẹ̀rù sì wà níbi gbogbo,” ni Olúwa wí.
Dɛn na mihu? Wɔabɔ hu, wɔresan wɔn akyi, wɔn dɔmmarima adi nkogu. Woguan ntɛm so a wɔnhwɛ wɔn akyi, na ehu wɔ baabiara,” Awurade na ose.
6 “Ẹni tí ó yára kì yóò le sálọ, tàbí alágbára kò ní lè sá àsálà. Ní àríwá ní ibi odò Eufurate wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
Ɔhoɔharefo ntumi nguan, na ɔhoɔdenfo nso saa ara. Atifi fam wɔ Asubɔnten Eufrate ho wohintihintiw na wɔhwehwe ase.
7 “Ta ni èyí tí ó gòkè wá bí odò Ejibiti, tí omi rẹ̀ ń ru gẹ́gẹ́ bí odò wọ̀n-ọn-nì?
“Hena, na ɔma ne homene so sɛ Asubɔnten Nil, sɛ nsubɔnten a mu nsu woro yi?
8 Ejibiti dìde bí odò náà, bí omi odò tí ń ru. Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò dìde, n ó sì bo gbogbo ilẹ̀ ayé.’ Èmi yóò pa ìlú àti àwọn ènìyàn rẹ̀ run.
Misraim ma ne homene so sɛ Nil, sɛ nsubɔnten a mu nsu woro. Ɔka se, ‘Mɛsɔre akata asase no so; mɛsɛe nkuropɔn ne mu nnipa.’
9 Ẹ gòkè wá ẹ̀yin ẹṣin, ẹ sì sáré kíkankíkan ẹ̀yin kẹ̀kẹ́. Kí àwọn alágbára túbọ̀ tẹ̀síwájú, àwọn ará Kuṣi àti àwọn ará Puti tí ń di asà mú; àti àwọn ará Lidia tí ń fa ọrun.
Monkɔ mo anim, apɔnkɔ! Monka wɔn anibere so, mo nteaseɛnamkafo! Muntu nteɛ, dɔmmarima, Kus ne Put mmarima a mukura nkatabo, Lidia mmarima a motow agyan.
10 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà jẹ́ ti Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọjọ́ ìgbẹ̀san, ìgbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Idà yóò sì jẹ́ títí yóò fi ní ìtẹ́lọ́rùn, títí yóò fi pa òǹgbẹ rẹ̀ rẹ́ pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀. Nítorí pé Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò rú ẹbọ ní ilẹ̀ gúúsù ní odò Eufurate.
Nanso da no yɛ Awurade, Asafo Awurade dea, aweretɔda, nʼatamfo so aweretɔ. Afoa bekunkum akosi sɛ ɔbɛmee, akosi bere a ɔde mogya bedwudwo ne osukɔm ano. Efisɛ, Awurade, Asafo Awurade bɛbɔ afɔre wɔ atifi fam asase a ɛwɔ Asubɔnten Eufrate ho no so.
11 “Gòkè lọ sí Gileadi, kí o sì mú ìkunra, ìwọ wúńdíá ọmọbìnrin Ejibiti. Ṣùgbọ́n ní asán ni ìwọ ń lo oògùn, kì yóò sí ìwòsàn fún ọ.
“Foro kɔ Gilead kogye aduru Misraim Babea Ɔbabun. Nanso nnuru bebrebe a wofa no yɛ ɔkwa, ayaresa biara nni hɔ ma wo.
12 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ nípa ìtìjú rẹ, igbe rẹ yóò kún gbogbo ayé. Jagunjagun yóò máa ṣubú lu ara wọn lórí rẹ, àwọn méjèèjì yóò sì jọ ṣubú papọ̀.”
Amanaman no bɛte wʼanimguase; wʼagyaadwo bɛhyɛ asase so ma. Ɔkofo baako behintiw afa ɔfoforo so; na wɔn baanu bɛbɔ mu ahwe ase.”
13 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó bá Jeremiah wòlíì nì sọ nípa wíwá Nebukadnessari ọba Babeli láti lọ dojú ìjà kọ Ejibiti:
Eyi ne asɛm a Awurade ka kyerɛɛ odiyifo Yeremia a ɛfa Babiloniahene Nebukadnessar ba a ɔbɛba abɛtow ahyɛ Misraim so:
14 “Kéde èyí ní Ejibiti, sì sọ ọ́ ní Migdoli, sọ ọ́ ní Memfisi àti Tafanesi: ‘Dúró sí ààyè rẹ kí o sì múra sílẹ̀, nítorí pé idà náà ń pa àwọn tí ó yí ọ ká.’
“Mommɔ eyi ho dawuru wɔ Misraim, na mompae mu nka wɔ Migdol; monka wɔ Memfis ne Tapanhes nso se, ‘Munnyinagyina na monyɛ krado, efisɛ, afoa rekunkum wɔn a wɔatwa mo ho ahyia.’
15 Èéṣe tí àwọn akọni rẹ fi ṣubú? Wọn kò ní le dìde dúró, nítorí Olúwa yóò tì wọ́n ṣubú.
Adɛn nti na mo dɔmmarima bɛbotow sɛɛ? Wɔrentumi nnyina, efisɛ, Awurade bɛbɔ wɔn ahwe fam.
16 Wọn yóò máa ṣubú léraléra wọn yóò máa ṣubú lu ara wọn. Wọn yóò sọ wí pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wa àti ilẹ̀ ìbí wa, kúrò níbi idà àwọn aninilára.’
Wobehintihintiw atoatoa so; wɔbɛhwehwe ase adeda wɔn ho wɔn ho so. Wɔbɛka se, ‘Monsɔre, momma yɛnkɔ yɛn nkyi nkɔ yɛn nkurɔfo nkyɛn ne faako a wɔwoo yɛn, na yemfi nhyɛsofo no afoa ano.’
17 Níbẹ̀ ni wọn ó kígbe pé, ‘Ariwo lásán ni Farao ọba Ejibiti pa, ó ti sọ àǹfààní rẹ̀ nù.’
Ɛhɔ na wɔbɛteɛ mu se, ‘Misraimhene Farao tu ne ho kwa; nʼakwannya a ɔwɔ no atwa mu.’
18 “Bí èmi ti wà láààyè,” ni ọba, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Nítòótọ́ gẹ́gẹ́ bí Tabori láàrín àwọn òkè àti gẹ́gẹ́ bi Karmeli lẹ́bàá Òkun bẹ́ẹ̀ ni òun yóò dé.
“Ampa ara sɛ mete ase yi” Ɔhene a ne din ne Asafo Awurade na ose, “Ɔbaako bɛba a ɔte sɛ Tabor wɔ mmepɔw no mu, sɛ Karmel wɔ mpoano.
19 Ìwọ, ọmọbìnrin ti ń gbé Ejibiti pèsè ohun èlò ìrìnàjò fún ara rẹ nítorí Memfisi yóò di ahoro a ó sì fi jóná, láìní olùgbé.
Mommoaboa mo nneɛma ano ntwɛn nnommumfa, mo a motete Misraim, efisɛ wɔbɛsɛe Memfis kurow na ɛbɛda mpan a obiara rentena mu.
20 “Ẹgbọrọ abo màlúù tó lẹ́wà ní Ejibiti ṣùgbọ́n eṣinṣin ìparun dé, ó dé láti àríwá.
“Misraim yɛ nantwi ba bere a ne ho yɛ fɛ, nanso ɔtɛn bi fi atifi fam reba ne so.
21 Àwọn jagunjagun rẹ̀ dàbí àbọ́pa akọ màlúù. Àwọn pẹ̀lú yóò yípadà, wọn ó sì jùmọ̀ sá, wọn kò ní le dúró, nítorí tí ọjọ́ ibi ń bọ̀ lórí wọn àsìkò láti jẹ wọ́n ní ìyà.
Asraafo apaafo a wɔwɔ wɔn mu no te sɛ nantwimma a wɔadodɔ srade. Wɔn nso bɛdan wɔn ho abɔ mu aguan, wɔrentumi nnyina wɔn anan so, efisɛ amanehunu da no reba wɔn so, bere a wɔde bɛtwe wɔn aso no.
22 Ejibiti yóò pòṣé bí ejò tí ń sá bí ọmọ-ogun ṣe ń tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú agbára. Wọn ó tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú àáké, gẹ́gẹ́ bí i ti agégi.
Misraim bɛteɛ mu sɛ ɔwɔ a ɔreguan bere a ɔtamfo de ahoɔden reba ne so no; wɔde mmonnua bɛba ne so te sɛ, mmarima a wobu nnua.
23 Wọn o gé igbó rẹ̀ lulẹ̀,” ni Olúwa wí, “nítorí ti a kò le rídìí rẹ̀. Nítorí pé wọ́n pọ̀ ju ẹlẹ́ǹgà lọ, wọ́n sì jẹ́ àìníye.
Wɔbɛsɛe ne kwae,” Awurade na ose, “sɛnea ayɛ kusuu yi mpo. Wɔdɔɔso bebree sen mmoadabi, na wɔrentumi nkan wɔn.
24 A ó dójútì ọmọbìnrin Ejibiti, a ó fà á lé ọwọ́ àwọn ènìyàn àríwá.”
Wobegu Misraim Babea anim ase, wɔde no bɛhyɛ atifi fam nnipa no nsa.”
25 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí pé: “Èmi yóò rọ̀jò ìyà mi sórí Amoni òrìṣà Tebesi, sórí Farao, sórí Ejibiti àti àwọn òrìṣà rẹ̀ àti sórí àwọn ọba rẹ̀ àti sórí àwọn tó gbẹ́kẹ̀lé Farao.
Asafo Awurade, Israel Nyankopɔn, ka se, “Mede asotwe reba Tebes nyame Amon, Farao, Misraim ne nʼanyame ne nʼahemfo ne wɔn a wɔde wɔn ho to Farao so no so.
26 Èmi ó sì fi wọ́n lé àwọn tó wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́, lé Nebukadnessari ọba Babeli, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Ejibiti yóò sì di gbígbé bí i ti àtijọ́,” ni Olúwa wí.
Mede wɔn bɛhyɛ wɔn a wɔpɛ sɛ wokum wɔn no, Babiloniahene Nebukadnessar ne nʼadwumayɛfo no nsa. Nanso akyiri no, nnipa bɛtena Misraim asase so te sɛ kan no,” Awurade na ose.
27 “Má bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má fòyà, ìwọ Israẹli. Dájúdájú èmi ó gbà ọ́ láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ ọmọ rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn. Jakọbu yóò tún ní àlàáfíà àti ààbò, kò sì ṣí ẹni tí yóò dẹ́rùbà á.
“Nsuro, Yakob me somfo; nni yaw, Israel. Ampa ara megye wo afi beae a ɛwɔ akyirikyiri, ne wʼasefo afi wɔn nnommumfa asase so Yakob bɛsan anya asomdwoe ne bammɔ, na obiara renhunahuna no.
28 Má bẹ̀rù, Jakọbu ìránṣẹ́ mi, nítorí pé mo wà pẹ̀lú rẹ,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, láàrín àwọn tí mo fọ́n yín ká sí. Èmi kò ní run yín tán. Èmi yóò jẹ ọ́ ní ìyà lórí òdodo, èmi kí yóò jọ̀wọ́ rẹ lọ́wọ́ lọ láìjẹ ọ́ ní yà.”
Nsuro, Yakob me somfo; na me ne wo wɔ hɔ,” Awurade na ose. “Ɛwɔ mu, mesɛe aman no nyinaa koraa aman a mehwetee mo kɔɔ so no de, nanso merensɛe mo korakora. Mede trenee nko ara na ɛbɛteɛteɛ mo so; meremma mommfa mo ho nni a merentwe mo aso.”