< Jeremiah 46 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa àwọn Orílẹ̀-èdè.
Šis ir Tā Kunga vārds, kas notika uz pravieti Jeremiju pret pagānu tautām:
2 Nípa Ejibiti. Èyí ni ọ̀rọ̀ nípa àwọn ọmọ-ogun Farao Neko ọba Ejibiti ẹni tí a borí rẹ̀ ní Karkemiṣi, ní odò Eufurate láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:
Pret Ēģipti, pret Faraonu Nekus, Ēģiptes ķēniņa, karaspēku, kas bija pie Eifrat upes, pie Karķemisa, ko Nebukadnecars, Bābeles ķēniņš, sakāva Jojaķima, Josijas dēla, Jūda ķēniņa, ceturtā gadā.
3 “Ẹ múra àpáta, èyí tí ó tóbi, àti èyí tí ó kéré, kí ẹ sì súnmọ́ ojú ìjà!
Taisiet gatavas bruņas un sedzamas bruņas un ejat karā.
4 Ẹ di ẹṣin ní gàárì, kí ẹ sì gùn ún. Ẹ dúró lẹ́sẹẹsẹ pẹ̀lú àṣíborí yín! Ẹ dán ọ̀kọ̀ yín, kí ẹ sì wọ ẹ̀wù irin.
Sedlojiet zirgus un kāpiet virsū, jātnieki, nostājaties vara cepurēs, triniet šķēpus, apvelciet krūšu bruņas.
5 Kí ni nǹkan tí mo tún rí? Wọ́n bẹ̀rù, wọ́n sì ń padà sẹ́yìn, wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn jagunjagun. Wọ́n sá, wọn kò sì bojú wẹ̀yìn, ìbẹ̀rù sì wà níbi gbogbo,” ni Olúwa wí.
Kāpēc Es tos redzu bailīgus un atpakaļ bēgam, un viņu varenos sakautus un bēgam, ka neskatās atpakaļ? Briesmas visapkārt, saka Tas Kungs.
6 “Ẹni tí ó yára kì yóò le sálọ, tàbí alágbára kò ní lè sá àsálà. Ní àríwá ní ibi odò Eufurate wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
Ne čaklais var izbēgt, ne varenais izsprukt; pret ziemeli pie Eifrat upes krasta tie klūp un krīt.
7 “Ta ni èyí tí ó gòkè wá bí odò Ejibiti, tí omi rẹ̀ ń ru gẹ́gẹ́ bí odò wọ̀n-ọn-nì?
Kas tas, kas ceļas, kā upe, kam ūdeņi veļas kā straumes?
8 Ejibiti dìde bí odò náà, bí omi odò tí ń ru. Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò dìde, n ó sì bo gbogbo ilẹ̀ ayé.’ Èmi yóò pa ìlú àti àwọn ènìyàn rẹ̀ run.
Ēģiptes zeme ceļas kā upe, un viņas ūdeņi veļas kā straumes un saka: “Es celšos liela, es apklāšu zemi, es maitāšu pilsētas, un kas tur dzīvo.”
9 Ẹ gòkè wá ẹ̀yin ẹṣin, ẹ sì sáré kíkankíkan ẹ̀yin kẹ̀kẹ́. Kí àwọn alágbára túbọ̀ tẹ̀síwájú, àwọn ará Kuṣi àti àwọn ará Puti tí ń di asà mú; àti àwọn ará Lidia tí ń fa ọrun.
Ceļaties, zirgi, rībiet, rati! Lai varoņi iziet, Moru ļaudis un no Puta, kas bruņas tura, un Līdieši, kas stopu nes un uzvelk.
10 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà jẹ́ ti Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọjọ́ ìgbẹ̀san, ìgbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Idà yóò sì jẹ́ títí yóò fi ní ìtẹ́lọ́rùn, títí yóò fi pa òǹgbẹ rẹ̀ rẹ́ pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀. Nítorí pé Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò rú ẹbọ ní ilẹ̀ gúúsù ní odò Eufurate.
Šī diena ir Tā Kunga, Tā Kunga Cebaot atriebšanās diena, ka Viņš atriebjās pie Saviem pretiniekiem, un zobens ēdīs un rīs un piedzersies no viņu asinīm. Jo Tam Kungam, Tam Kungam Cebaot, ir kauja ziemeļu zemē pie Eifrat upes.
11 “Gòkè lọ sí Gileadi, kí o sì mú ìkunra, ìwọ wúńdíá ọmọbìnrin Ejibiti. Ṣùgbọ́n ní asán ni ìwọ ń lo oògùn, kì yóò sí ìwòsàn fún ọ.
Ej augšā uz Gileādu un dabū zalves(balzāmu), jaunava, Ēģiptes meita! Velti, ka tu daudz zāļojies, jo dziedināšanas tev nav.
12 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ nípa ìtìjú rẹ, igbe rẹ yóò kún gbogbo ayé. Jagunjagun yóò máa ṣubú lu ara wọn lórí rẹ, àwọn méjèèjì yóò sì jọ ṣubú papọ̀.”
Tautas dzird tavu kaunu, un zeme ir pilna tavas kaukšanas, jo ir straipelejuši varonis uz varoni, un abi kopā krituši.
13 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó bá Jeremiah wòlíì nì sọ nípa wíwá Nebukadnessari ọba Babeli láti lọ dojú ìjà kọ Ejibiti:
Šis ir tas vārds, ko Tas Kungs runāja uz pravieti Jeremiju par Nebukadnecara, Bābeles ķēniņa, nākšanu, kaut Ēģiptes zemi:
14 “Kéde èyí ní Ejibiti, sì sọ ọ́ ní Migdoli, sọ ọ́ ní Memfisi àti Tafanesi: ‘Dúró sí ààyè rẹ kí o sì múra sílẹ̀, nítorí pé idà náà ń pa àwọn tí ó yí ọ ká.’
Sludinājiet Ēģiptes zemē, dariet zināmu Migdalā, sauciet to arī Novā un Takvanesā, sakāt: celies un taisies gatava, jo zobens ir aprijis, kas ap tevi.
15 Èéṣe tí àwọn akọni rẹ fi ṣubú? Wọn kò ní le dìde dúró, nítorí Olúwa yóò tì wọ́n ṣubú.
Kāpēc tavi varenie nogāzti? Tie nepastāvēja, jo Tas Kungs tos gāzis.
16 Wọn yóò máa ṣubú léraléra wọn yóò máa ṣubú lu ara wọn. Wọn yóò sọ wí pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wa àti ilẹ̀ ìbí wa, kúrò níbi idà àwọn aninilára.’
Viņš dara, ka daudzi gāžas, un viens krīt uz otru, un tie saka: ceļaties, iesim atpakaļ pie saviem ļaudīm un uz savu dzimteni no rijēja zobena.
17 Níbẹ̀ ni wọn ó kígbe pé, ‘Ariwo lásán ni Farao ọba Ejibiti pa, ó ti sọ àǹfààní rẹ̀ nù.’
Tur sauc: Faraons, Ēģiptes ķēniņš, ir pagalam, viņš savu laiku nav licis vērā.
18 “Bí èmi ti wà láààyè,” ni ọba, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Nítòótọ́ gẹ́gẹ́ bí Tabori láàrín àwọn òkè àti gẹ́gẹ́ bi Karmeli lẹ́bàá Òkun bẹ́ẹ̀ ni òun yóò dé.
Tik tiešām kā Es dzīvoju, saka tas Ķēniņš, kam vārds ir Kungs Cebaot: viņš nāks kā Tābors starp kalniem un kā Karmels jūrmalā.
19 Ìwọ, ọmọbìnrin ti ń gbé Ejibiti pèsè ohun èlò ìrìnàjò fún ara rẹ nítorí Memfisi yóò di ahoro a ó sì fi jóná, láìní olùgbé.
Gādā sev ceļa lietas, iedzīvotāja, Ēģiptes meita, jo Nofa taps par tuksnesi un taps sadedzināta, ka neviens tur nedzīvos.
20 “Ẹgbọrọ abo màlúù tó lẹ́wà ní Ejibiti ṣùgbọ́n eṣinṣin ìparun dé, ó dé láti àríwá.
Ēģipte ir dižena tele, dundurs no ziemeļiem nāk, tiešām nāk.
21 Àwọn jagunjagun rẹ̀ dàbí àbọ́pa akọ màlúù. Àwọn pẹ̀lú yóò yípadà, wọn ó sì jùmọ̀ sá, wọn kò ní le dúró, nítorí tí ọjọ́ ibi ń bọ̀ lórí wọn àsìkò láti jẹ wọ́n ní ìyà.
Arī viņas karavīri viņas vidū ir kā baroti teļi; tomēr arī tie griež muguru, visi kopā bēg un nestāv, jo viņu nelaimes diena tiem uzbrukusi, viņu piemeklēšanas laiks.
22 Ejibiti yóò pòṣé bí ejò tí ń sá bí ọmọ-ogun ṣe ń tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú agbára. Wọn ó tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú àáké, gẹ́gẹ́ bí i ti agégi.
Viņas balss būs, tā kā čab, čūskai lienot, jo tie celsies uz turieni ar karaspēku un nāks pie viņiem ar cirvjiem, kā malkas cirtēji.
23 Wọn o gé igbó rẹ̀ lulẹ̀,” ni Olúwa wí, “nítorí ti a kò le rídìí rẹ̀. Nítorí pé wọ́n pọ̀ ju ẹlẹ́ǹgà lọ, wọ́n sì jẹ́ àìníye.
Tie nocirtīs viņas mežu, saka Tas Kungs, jebšu tas ir liels un biezs, jo to ir vairāk nekā siseņu, ka tos nevar skaitīt.
24 A ó dójútì ọmọbìnrin Ejibiti, a ó fà á lé ọwọ́ àwọn ènìyàn àríwá.”
Ēģiptes meita stāv kaunā, rokā dota ļaudīm no ziemeļiem.
25 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí pé: “Èmi yóò rọ̀jò ìyà mi sórí Amoni òrìṣà Tebesi, sórí Farao, sórí Ejibiti àti àwọn òrìṣà rẹ̀ àti sórí àwọn ọba rẹ̀ àti sórí àwọn tó gbẹ́kẹ̀lé Farao.
Tas Kungs Cebaot, Israēla Dievs, saka: redzi, Es piemeklēšu Amonu Noā un Faraonu un Ēģipti un viņas dievus un viņas ķēniņus, Faraonu un tos, kas uz viņu paļaujas;
26 Èmi ó sì fi wọ́n lé àwọn tó wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́, lé Nebukadnessari ọba Babeli, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Ejibiti yóò sì di gbígbé bí i ti àtijọ́,” ni Olúwa wí.
Un Es tos nodošu tiem rokā, kas viņu dvēseles meklē, un Nebukadnecara, Bābeles ķēniņa, rokā, un viņa kalpu rokā. Bet pēcgalā tur dzīvos tā kā vecos laikos, saka Tas Kungs.
27 “Má bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má fòyà, ìwọ Israẹli. Dájúdájú èmi ó gbà ọ́ láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ ọmọ rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn. Jakọbu yóò tún ní àlàáfíà àti ààbò, kò sì ṣí ẹni tí yóò dẹ́rùbà á.
Bet tu, nebīsties, Mans kalps Jēkab, un neiztrūcinājies, Israēl! Jo redzi, Es tevi atpestīšu no tālienes un tavu dzimumu no viņa cietuma zemes; un Jēkabs griezīsies atpakaļ un paliks mierā, un viņam klāsies labi, un neviens viņu neiztrūcinās.
28 Má bẹ̀rù, Jakọbu ìránṣẹ́ mi, nítorí pé mo wà pẹ̀lú rẹ,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, láàrín àwọn tí mo fọ́n yín ká sí. Èmi kò ní run yín tán. Èmi yóò jẹ ọ́ ní ìyà lórí òdodo, èmi kí yóò jọ̀wọ́ rẹ lọ́wọ́ lọ láìjẹ ọ́ ní yà.”
Tu tad nebīsties, Mans kalps Jēkab, saka Tas Kungs; jo Es esmu pie tevis. Jo Es darīšu galu visām pagānu tautām, kurp Es tevi biju aizdzinis, bet tev Es nedarīšu galu, bet Es tevi pārmācīšu pēc taisnības, un tevi nepametīšu nepārmācītu.

< Jeremiah 46 >