< Jeremiah 45 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì sọ fún Baruku ọmọ Neriah ní ọdún kẹrin ti Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda. Lẹ́yìn tí Baruku ti kọ sínú ìwé kíká àwọn ọ̀rọ̀ tí Jeremiah ti ń sọ:
Las palabras que el profeta Jeremías dijo a Baruc, hijo de Nerías, cuando escribió estas palabras en un libro de la boca de Jeremías, en el cuarto año de Joacim, hijo de Josías, rey de Judá; él dijo,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ fún ọ, Baruku.
Esto es lo que el Señor, el Dios de Israel, ha dicho de ti, Baruc:
3 Ìwọ wí pé, ‘Ègbé ni fún mi! Olúwa ti fi ìbànújẹ́ kún ìrora mi, àárẹ̀ mú mi nínú ẹ̀dùn mi, èmi kò sì rí ìsinmi.’”
Tú dijiste: ¡El dolor es mío! porque el Señor me ha dado pena además de mi dolor; Estoy cansado con el sonido de mi tristeza, y no puedo descansar.
4 Olúwa wí pé sọ èyí fún un, “Èyí ni Ọlọ́run sọ: ‘Èyí tí èmi ti kọ́ ni èmi yóò wò lulẹ̀, àti èyí tí èmi ti gbìn ni èmi yóò fàtu, àní ní orí gbogbo ilẹ̀.
Esto es lo que debes decirle: El Señor ha dicho: “En verdad, el edificio que levanté se derrumbará, y el que fue plantado por mí será arrancado, es decir, toda está tierra;
5 Ṣé ìwọ sì ń wá ohun títóbi fún ara rẹ? Nítorí náà, má ṣe wá wọn. Èmi yóò mú ibi wá sí orí àwọn ènìyàn gbogbo ni Olúwa wí, ṣùgbọ́n níbikíbi tí ìwọ bá lọ ni èmi yóò jẹ́ kí o sá àsálà pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ.’”
Y en cuanto a ti, ¿estás buscando grandes cosas para ti mismo? No tengas ningún deseo por ellas, porque verdaderamente enviaré el mal a toda carne, dice el Señor, pero tu vida la mantendré a salvo de los ataques dondequiera que vayas.