< Jeremiah 45 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì sọ fún Baruku ọmọ Neriah ní ọdún kẹrin ti Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda. Lẹ́yìn tí Baruku ti kọ sínú ìwé kíká àwọn ọ̀rọ̀ tí Jeremiah ti ń sọ:
Реч коју рече Јеремија пророк Варуху сину Ниријином, кад писаше ове речи у књигу из уста Јеремијиних, четврте године Јоакима, сина Јосијиног, говорећи:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ fún ọ, Baruku.
Овако вели Господ Бог израиљев за тебе, Варуше:
3 Ìwọ wí pé, ‘Ègbé ni fún mi! Olúwa ti fi ìbànújẹ́ kún ìrora mi, àárẹ̀ mú mi nínú ẹ̀dùn mi, èmi kò sì rí ìsinmi.’”
Рекао си: Тешко мени! Јер Господ додаде ми жалост на тугу; изнемогох уздишући, и мира не налазим.
4 Olúwa wí pé sọ èyí fún un, “Èyí ni Ọlọ́run sọ: ‘Èyí tí èmi ti kọ́ ni èmi yóò wò lulẹ̀, àti èyí tí èmi ti gbìn ni èmi yóò fàtu, àní ní orí gbogbo ilẹ̀.
Реци му ово: Овако вели Господ: Ево, шта сам саградио ја разграђујем, и шта сам посадио искорењавам по свој тој земљи.
5 Ṣé ìwọ sì ń wá ohun títóbi fún ara rẹ? Nítorí náà, má ṣe wá wọn. Èmi yóò mú ibi wá sí orí àwọn ènìyàn gbogbo ni Olúwa wí, ṣùgbọ́n níbikíbi tí ìwọ bá lọ ni èmi yóò jẹ́ kí o sá àsálà pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ.’”
А ти ли ћеш тражити себи велике ствари? Не тражи; јер ево, ја ћу пустити зло на свако тело, говори Господ; али ћу теби дати душу твоју место плена у свим местима, куда одеш.

< Jeremiah 45 >