< Jeremiah 45 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì sọ fún Baruku ọmọ Neriah ní ọdún kẹrin ti Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda. Lẹ́yìn tí Baruku ti kọ sínú ìwé kíká àwọn ọ̀rọ̀ tí Jeremiah ti ń sọ:
After Jehoiakim the son of King Josiah had been ruling Judah for almost four years, [I, ] Baruch, wrote down [all] the messages that the prophet Jeremiah had dictated to me. Then Jeremiah gave me a message. He said,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ fún ọ, Baruku.
“Baruch, Yahweh, the God whom [we] Israelis [worship], has a message for you.
3 Ìwọ wí pé, ‘Ègbé ni fún mi! Olúwa ti fi ìbànújẹ́ kún ìrora mi, àárẹ̀ mú mi nínú ẹ̀dùn mi, èmi kò sì rí ìsinmi.’”
You have said, ‘Terrible things [are happening] to me! I have endured much pain already. And now Yahweh is causing me to be very sad, in addition to my having pain. I am exhausted from my (groaning/being sad), and I am unable to rest!’
4 Olúwa wí pé sọ èyí fún un, “Èyí ni Ọlọ́run sọ: ‘Èyí tí èmi ti kọ́ ni èmi yóò wò lulẹ̀, àti èyí tí èmi ti gbìn ni èmi yóò fàtu, àní ní orí gbogbo ilẹ̀.
But [Baruch], this is what Yahweh says: ‘I will destroy this nation that I established. [This nation is like a tree] [MET] that I planted and that I will now pull up with its roots.
5 Ṣé ìwọ sì ń wá ohun títóbi fún ara rẹ? Nítorí náà, má ṣe wá wọn. Èmi yóò mú ibi wá sí orí àwọn ènìyàn gbogbo ni Olúwa wí, ṣùgbọ́n níbikíbi tí ìwọ bá lọ ni èmi yóò jẹ́ kí o sá àsálà pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ.’”
So, should you [RHQ] desire that people do things to honor you in a special way? Do not desire that. [It is true that] I will cause all these people to experience a great disaster, but wherever you go, I will protect you, and you will not be killed.’”