< Jeremiah 44 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
Beseda, ki je prišla Jeremiju glede vseh Judov, ki prebivajo v egiptovski deželi, ki prebivajo v Migdólu, v Tahpanhésu, v Nofu in v deželi Patrós, rekoč:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
»Tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Videli ste vse zlo, ki sem ga privedel nad Jeruzalem in nad vsa Judova mesta, in glejte, ta dan so ta opustošenje in noben človek ne prebiva tam
3 Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
zaradi njihove zlobnosti, ki so jo zagrešili, da me dražijo do jeze v tem, da so odšli zažigat kadilo in da služijo drugim bogovom, ki jih niso poznali niti oni, da, niti vaši očetje.
4 Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
Vendar sem vam pošiljal vse svoje služabnike preroke, vzdigujoče zgodaj in jih pošiljal, rekoč: ›O ne storite te gnusne stvari, ki jo sovražim.‹
5 Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
Toda niso prisluhnili niti nagnili svojega ušesa, da se odvrnejo od svoje zlobnosti, da ne bi zažigali kadila drugim bogovom.
6 Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
Zato sta bila moj bes in moja jeza izlita naprej in vžgana v Judovih mestih in na ulicah Jeruzalema; in ta so opustošena in zapuščena kakor ta dan.‹
7 “Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
Zaradi tega sedaj tako govori Gospod, Bog nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Zakaj ste zagrešili to veliko zlo zoper svoje duše, da izmed sebe iztrebite moškega in žensko, otroka in dojenčka, ven iz Juda, da nikogar ne pustite, da preostane.
8 Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
V čem ste me dražili do besa z deli svojih rok, zažigajoč kadilo drugim bogovom v egiptovski deželi, kamor ste odšli, da prebivate, da se lahko sami odrežete in da ste lahko prekletstvo in graja med vsemi narodi zemlje?‹
9 Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Mar ste pozabili zlobnost svojih očetov, zlobnost Judovih kraljev, zlobnost njihovih žena, svojo lastno zlobnost in zlobnost svojih žena, ki so jo zagrešili v Judovi deželi in na ulicah Jeruzalema?
10 Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
Niso se ponižali celó do tega dne, niti se niso bali, niti hodili po moji postavi, niti po mojih zakonih, ki sem jih postavil pred vas in vaše očete.
11 “Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
Zato tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Glejte, svoj obraz bom naravnal zoper vas za zlo in da iztrebim vsega Juda.
12 Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
Vzel bom preostanek Juda, ki so svoje obraze naravnali, da gredo v egiptovsko deželo, da začasno prebivajo tam in vsi bodo použiti in padli v egiptovski deželi; torej použiti bodo z mečem in z lakoto. Umrli bodo, od najmanjših celo do največjih, z mečem in z lakoto, in bodo preziranje in osuplost, prekletstvo in graja.
13 Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
Kajti kaznoval bom tiste, ki prebivajo v egiptovski deželi, kakor sem kaznoval Jeruzalem, z mečem, z lakoto in s kužno boleznijo,
14 Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
tako da ne bo nihče izmed Judovega preostanka, ki so odšli v egiptovsko deželo, da začasno prebivajo tam, ušel ali preostal, da bi se vrnil v Judovo deželo, h kateri so imeli željo, da se vrnejo, da prebivajo tam. Kajti nihče se ne bo vrnil, razen tistih, ki bodo pobegnili.‹«
15 Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
Potem so vsi možje, ki so vedeli, da so njihove žene zažigale kadilo drugim bogovom in vse ženske, ki so stale poleg, velika množica, celo vse ljudstvo, ki prebiva v egiptovski deželi, v Patrósu, odgovorili Jeremiju, rekoč:
16 “Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
» Glede na besedo, ki si nam jo govoril v imenu Gospoda, ti ne bomo prisluhnili,
17 Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
temveč bomo zagotovo počeli katerokoli stvar, izhajajočo iz naših lastnih ust, da zažigamo kadilo kraljici neba in da ji izlivamo pitne daritve, kakor smo počeli mi in naši očetje, naši kralji in naši princi v Judovih mestih in na ulicah Jeruzalema, kajti tedaj smo imeli obilico živeža in smo bili dobro in nismo videli zla.
18 Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
Toda odkar smo prenehali zažigati kadilo kraljici neba in ji izlivati pitne daritve, smo bili v potrebi vseh stvari in smo použiti z mečem in z lakoto.«
19 Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
»In ko smo zažigale kadilo kraljici neba in ji izlivale pitne daritve, mar smo ji naredile kolačke, da jo obožujemo in ji izlivale pitne daritve, brez naših moških?«
20 Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
Potem je Jeremija rekel vsemu ljudstvu, moškim in ženskam in vsemu ljudstvu, ki mu je dalo ta odgovor, rekoč:
21 “Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
»Kadilo, ki ste ga zažigali po Judovih mestih in po ulicah Jeruzalema, vi in vaši očetje, vaši kralji, vaši princi in ljudstvo dežele, ali se jih ni Gospod spomnil in ali to ni prišlo v njegov um?
22 Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
Tako da Gospod ni mogel več trpeti zaradi zla vaših početij in zaradi ogabnosti, ki ste jih zagrešili; zato je vaša dežela opustošenje, osuplost in prekletstvo, brez prebivalca, kakor na ta dan.
23 Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
Ker ste zažigali kadilo in ker ste grešili zoper Gospoda in niste ubogali Gospodovega glasu, niti hodili po njegovi postavi, niti po njegovih zakonih, niti po njegovih pričevanjih, zato se vam je zgodilo to zlo, kakor na ta dan.«
24 Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
Poleg tega je Jeremija rekel vsemu ljudstvu in vsem ženskam: »Poslušajte besedo od Gospoda, ves Juda, ki ste v egiptovski deželi:
25 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
›Tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog, rekoč: ›Vi in vaše žene ste tako govorili s svojimi usti in s svojo roko izpolnili, rekoč: ›Zagotovo bomo izvajali svoje zaobljube, ki smo se jih zaobljubili, da zažigamo kadilo kraljici neba in da ji izlivamo pitne daritve.‹ Zagotovo boste dokončali svoje zaobljube in zagotovo boste izvedli svoje zaobljube.
26 Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
Zato poslušajte besedo od Gospoda, ves Juda, ki prebiva v egiptovski deželi: ›Glejte, prisegel sem pri svojem velikem imenu, ‹ govori Gospod, ›da moje ime ne bo več imenovano v ustih kateregakoli moškega iz Juda in po vsej egiptovski deželi, rekoč: ›Gospod Bog živi.‹
27 Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
Glej, bedel bom nad njimi za zlo in ne za dobro; in vsi Judovi možje, ki so v egiptovski deželi, bodo použiti z mečem in z lakoto, dokler jih ne bo konec.
28 Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
Vendar se bo malo število, ki pobegne meču, vrnilo iz egiptovske dežele v Judovo deželo in ves preostanek Juda, ki so odšli v egiptovsko deželo, da tam začasno prebiva, bo vedel čigave besede bodo obstale, moje ali njihove.
29 “‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
To vam bo znamenje, ‹ govori Gospod, ›da vas bom kaznoval na tem kraju, da boste lahko vedeli, da bodo moje besede zagotovo obstale zoper vas v zlo.‹
30 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”
Tako govori Gospod: ›Glejte, izročil bom faraona Hofrája, egiptovskega kralja, v roko njegovih sovražnikov in v roko tistih, ki strežejo po njegovem življenju, kakor sem Judovega kralja Sedekíja izročil v roko babilonskega kralja Nebukadnezarja, njegovega sovražnika in ki je stregel po njegovem življenju.‹«

< Jeremiah 44 >