< Jeremiah 44 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
Ko te kupu i puta mai ki a Heremaia mo nga Hurai katoa e noho ana i te whenua o Ihipa, e noho ana i Mikitoro, i Tahapanehe, i Nopo, i te whenua hoki o Patoro; i mea ia,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
Ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, a te Atua o Iharaira: Kua kite koutou i te kino katoa i takina mai nei e ahau ki runga ki Hiruharama, ki nga pa katoa hoki o Hura; na, i tenei ra he ururua ratou, kahore hoki he tangata e noho ana i reira;
3 Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
Mo ta ratou kino i mahia e ratou hei whakapataritari i ahau, i to ratou haerenga ki te tahu whakakakara, a ki te mahi ki nga atua ke, kihai nei ratou i mohio, ratou, koutou ranei, o koutou matua ranei.
4 Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
He ahakoa ra, i unga atu e ahau aku pononga katoa, nga poropiti, ki a koutou, maranga wawe ana ahau ki te unga i a ratou; i mea ahau, Kaua ra e mahia tenei mea whakarihariha e kino nei ahau.
5 Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
Otiia kihai ratou i rongo, kihai hoki i tahuri mai o ratou taringa, kihai i hoki mai i to ratou kino, ara i te tahu whakakakara ki nga atua ke.
6 Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
Koia i ringihia atu ai toku weriweri, toku riri, ngiha tonu ki nga pa o Hura, ki nga ara hoki o Hiruharama; na he ururua ratou, he tuhea, koia ano tenei inaianei.
7 “Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
Mo reira ko te kupu tenei inaianei a Ihowa, a te Atua o nga mano, a te Atua o Iharaira; He aha koutou i mahi ai i tenei kino nui mo o koutou wairua, ka hatepe atu i a koutou, i nga tane, i nga wahine, i te kohungahunga, i te mea ngote u, i roto i a Hura, a kore iho he toenga o koutou e mahue?
8 Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
I a koutou i whakapataritari na i ahau ki nga mahi a o koutou ringa, i a koutou ka tahu whakakakara nei ki nga atua ke i te whenua o Ihipa, kua haere atu na koutou ki reira noho ai, e hatepea atu ai koutou, e waiho ai koutou hei kanga, hei ingoa kino i roto i nga iwi katoa o te whenua.
9 Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Kua wareware ranei koutou ki te kino o o koutou matua, ki te kino o nga kingi o Hura, ki te kino hoki o a ratou wahine, ki o koutou na kino, ki te kino hoki o a koutou wahine i mahia nei e ratou ki te whenua o Hura, ki nga ara hoki o Hiruharama?
10 Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
Taea noatia tenei ra kahore ano ratou i whakaiti i a ratou, kahore ano i wehi, kahore i haere i runga i taku ture, i runga i aku tikanga i hoatu e ahau ki to koutou aroaro, ki te aroaro hoki o o koutou matua.
11 “Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
Mo reira ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, a te Atua o Iharaira: Nana, ka anga ke atu toku mata i a koutou mo te kino, he hatepe i a Hura katoa.
12 Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
Na ka mau ahau ki nga morehu o Hura, kua maro nei o ratou mata ki te haere ki te whenua o Ihipa, ki reira noho ai, a ka poto ratou katoa; ka hinga ratou ki te whenua o Ihipa; ka pau ratou i te hoari, i te hemokai; ka mate ratou, mai i te iti ki te rahi, i te hoari, i te hemokai: a ka waiho ratou hei kanga, hei miharotanga, hei kohukohutanga, hei ingoa kino.
13 Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
No te mea ka whiua e ahau te hunga e noho ana i te whenua o Ihipa, ka rite ki taku whiunga i Hiruharama ki te hoari, ki te hemokai, ki te mate uruta:
14 Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
Na ka kore tetahi o nga morehu o Hura i haere nei ki te whenua o Ihipa noho ai e mawhiti, e toe, hei hoki ki te whenua o Hura, ki te wahi e hiahia nei ratou kia hoki ki reira noho ai: na e kore tetahi e hoki ko te hunga anake e mawhiti atu.
15 Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
Na katahi nga tangata katoa i mohio kua tahu whakakakara a ratou wahine ki nga atua ke, nga wahine katoa hoki e tu mai ana, he nui te huihui, me te iwi katoa hoki e noho ana i te whenua o Ihipa, i Patoro, ka whakahoki ki a Heremaia, ka mea,
16 “Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
Na, mo te kupu kua korerotia nei e koe ki a matou i runga i te ingoa o Ihowa, e kore matou e rongo ki a koe.
17 Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
Engari ka tino mahi matou i nga mea katoa i puaki i o matou mangai, ka tahu whakakakara ki te kuini o te rangi, ka riringi ano i nga ringihanga ki a ia, ka pera me ta matou, me ta o matou matua, me ta o matou kingi, me ta o matou rangatira i nga pa o Hura, i nga ara o Hiruharama: i makona hoki matou i reira i te kai, i pai hoki matou, a kihai i kite i te he.
18 Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
Otiia no te mutunga o ta matou tahu whakakakara ki te kuini o te rangi, o ta matou ringihanga i nga ringihanga ki a ia, kua kore nga mea katoa, i a matou, a poto iho matou i te hoari, i te hemokai.
19 Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
A, i a matou i tahu whakakakara ai ki te kuini o te rangi, i riringi ai hoki i nga ringihanga ki a ia, e ngaro ana ranei a matou tane i a matou e hanga ana i nga keke nana, hei karakia ki a ia; i a matou hoki i riringi ai i nga ringihanga mana?
20 Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
Katahi a Heremaia ka korero ki te iwi katoa, ki nga tane, ki nga wahine, ki te iwi katoa ano nana taua kupu whakautu ki a ia, ka mea,
21 “Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
Ko te whakakakara i tahuna ra e koutou ki nga pa o Hura, ki nga ara hoki o Hiruharama, e koutou, e o koutou matua, e o koutou kingi, e o koutou rangatira, e te iwi hoki o te whenua, kihai ianei ena mea i maharatia e Ihowa, kihai ianei i puta ake ki tona ngakau?
22 Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
A te ahei a Ihowa te whakamanawanui tonu i te kino o a koutou hanga, i nga mea whakarihariha i mahia e koutou; heoi kua ururua to koutou whenua, kua waiho hei miharotanga, hei kohukohutanga, te ai te tangata hei noho, koia ano tenei inaianei.
23 Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
No te mea kua tahu koutou i te whakakakara, kua hara hoki ki a Ihowa, a kihai i rongo ki te reo o Ihowa, kihai hoki i haere i runga i tana ture, i runga i ana tikanga, i runga i ana whakaatu; mo reira i tutaki ai tenei he ki a koutou, koia ano t enei inaianei.
24 Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
I mea atu ano a Heremaia ki te iwi katoa, ki nga wahine katoa hoki, Whakarongo ki te kupu a Ihowa, e Hura katoa i te whenua o Ihipa nei:
25 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
Ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, a te Atua o Iharaira; e ki ana ia: Ko koutou, me a koutou wahine, kua korero o koutou mangai, kua rite ano i o koutou ringa te kupu, Ka mahia marietia e matou a matou kupu taurangi i korerotia e matou, kia ta hu whakakakara ki te kuini o te rangi, kia riringi i nga ringihanga ki a ia: tena whakaungia a koutou kupu taurangi, mahia hoki a koutou kupu taurangi.
26 Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
Mo reira whakarongo ki te kupu a Ihowa, e Hura katoa e noho nei i te whenua o Ihipa: Nana, kua oatitia e ahau toku ingoa nui, e ai ta Ihowa, e kore toku ingoa e whakahuatia a muri ake nei e te mangai o tetahi tangata o Hura i te whenua katoa o I hipa, e kore e kiia, E ora ana te Ariki, a Ihowa.
27 Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
Nana, kei te tirotiro ahau i a ratou mo te kino, ehara i te mea hei pai: a, ko nga tangata katoa o Hura i te whenua o Ihipa, ka poto i te hoari, i te hemokai hoki, a moti noa ratou.
28 Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
A, ko nga morehu i te hoari, ka hoki atu i te whenua o Ihipa ki te whenua o Hura, he hunga torutoru; a ka mohio nga morehu katoa o Hura i haere nei ki te whenua o Ihipa noho ai, ko ta wai kupu e tu, ko taku ranei, ko ta ratou ranei.
29 “‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
A ko te tohu tenei ki a koutou, e ai ta Ihowa, ka whiua koutou e ahau ki tenei wahi, kia mohio ai koutou ka mau tonu aku kupu ki te kino mo koutou.
30 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”
Ko te kupu tenei a Ihowa, Nana, ka hoatu e ahau a Parao Hopara kingi o Ihipa ki te ringa o ona hoariri, ki te ringa hoki o te hunga e whai ana kia whakamatea ia; ka rite ano ki taku hoatutanga i a Terekia kingi o Hura ki te ringa o Nepukareha ki ngi o Papurona, o tona hoariri i whai nei kia whakamatea ia.

< Jeremiah 44 >