< Jeremiah 44 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
Parole qui fut adressée par Jérémie à tous les Juifs qui habitaient dans la terre d’Egypte, à Magdalum, et à Taphnis, et à Memphis, et dans la terre de Phaturès, disant:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
Voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Vous, vous avez vu tout le mal que j’ai amené sur Jérusalem, et sur toutes les villes de Juda; et voilà qu’elles sont désertes aujourd’hui, et qu’il n’y a pas en elles d’habitant,
3 Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
À cause de la malice dont ils se sont rendus coupables, afin de me provoquer au courroux, en allant sacrifier, et en adorant des dieux étrangers qu’ils ne connaissaient ni eux, ni vous, ni vos pères.
4 Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
Et j’ai envoyé vers vous tous mes serviteurs, les prophètes, me levant dès la nuit, et les envoyant et disant: Ne faites pas de ces choses abominables que je hais.
5 Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
Et ils n’ont pas écouté, et ils n’ont pas incliné leur oreille afin de se convertir de leur méchanceté, et de ne pas sacrifier à des dieux étrangers.
6 Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
Et mon indignation et ma fureur se sont allumées, et se sont embrasées dans les cités de Juda, et dans les places de Jérusalem; et elles ont été changées en solitude et en ruine, comme on les voit en ce jour.
7 “Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
Et maintenant, voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Pourquoi vous, commettez-vous ce grand mal contre vos âmes, que parmi vous et du milieu de Juda périt l’homme, et la femme, et le petit enfant, et celui qui est encore à la mamelle, en sorte qu’il ne vous est laissé aucun reste?
8 Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
Me provoquant par les œuvres de vos mains en sacrifiant à des dieux étrangers dans la terre d’Egypte, où vous êtes entrés afin d’y habiter, et d’y périr entièrement, et d’y être en malédiction et en opprobre à toutes les nations de la terre.
9 Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Est-ce que vous avez oublié les crimes de vos pères, et les crimes des rois de Juda, et les crimes de leurs femmes, et vos crimes, les crimes de vos femmes, crimes qu’elles ont commis dans la terre de Juda et dans les quartiers de Jérusalem.
10 Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
Ils ne se sont pas purifiés jusqu’à ce jour; et ils n’ont pas craint, et ils n’ont pas marché dans la loi du Seigneur, et dans mes préceptes que j’ai donnés devant vous et devant vos pères.
11 “Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
C’est pourquoi voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Voilà que moi je tournerai ma face vers vous pour votre malheur; et je perdrai entièrement tout Juda.
12 Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
Et je prendrai les restes de Juda qui ont tourné leurs faces afin d’entrer en Egypte, et d’y habiter; et ils seront tous détruits dans la terre d’Egypte; ils tomberont par le glaive et par la famine, et ils seront détruits depuis le plus petit jusqu’au plus grand; c’est par le glaive et par la famine qu’ils mourront; et ils seront en exécration, et en étonnement, et en malédiction et en opprobre.
13 Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
Et je visiterai les habitants de la terre d’Egypte, comme j’ai visité Jérusalem, par le glaive, par la famine et par la peste.
14 Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
Et il n’y aura personne qui échappe et qui survive d’entre les restes des Juifs qui vont pour séjourner dans la terre d’Egypte, et pour retourner dans la terre de Juda vers laquelle ils élèvent leurs âmes pour y retourner et y habiter; il ne retournera que ceux qui auront fui de l’Egypte.
15 Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
Et tous les hommes qui écoutaient Jérémie, sachant que leurs femmes sacrifiaient à des dieux étrangers, et toutes les femmes dont une grande multitude était là, et tout le peuple qui habitait dans la terre d’Egypte, à Phaturès, répondirent à Jérémie, disant:
16 “Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
La parole que tu nous as dite au nom du Seigneur, nous ne l’écouterons pas venant de toi;
17 Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
Mais nous exécuterons entièrement toute parole qui sortira de notre bouche, en sacrifiant à la reine du ciel, et en lui faisant de nombreuses libations, comme nous avons fait, nous et nos pères, nos rois et nos princes, dans les villes de Juda et les places de Jérusalem; car alors nous avons été rassasiés de pain, et bien nous a été, et nous n’avons pas vu le mal.
18 Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
Mais depuis le temps que nous avons cessé de sacrifier à la reine du ciel et de lui faire de nombreuses libations, nous manquons de tout, et nous avons été consumés par le glaive et par la famine.
19 Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
Que si nous sacrifions à la reine du ciel et si nous lui faisons de nombreuses libations, est-ce sans nos époux que nous lui avons fait des gâteaux pour l’honorer, et que nous lui faisons de nombreuses libations?
20 Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
Et Jérémie parla à tout le peuple, contre les hommes, contre les femmes et contre toute la foule qui lui avait fait cette réponse, disant:
21 “Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
N’est-ce pas le sacrifice que vous avez offert dans les cités de Juda et sur les places de Jérusalem, vous et vos pères, vos rois et vos princes et le peuple de la terre, n’est-ce pas de ces choses, que le Seigneur s’est souvenu, et ce qui est monté sur son cœur?
22 Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
Et le Seigneur ne pouvait plus vous supporter à cause de la malice de vos œuvres, et à cause des abominations que vous avez commises; et votre terre a été livrée à la désolation, à la stupeur et à la malédiction, pour qu’il n’y ait point d’habitant, comme c’est en ce jour.
23 Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
Parce que vous avez sacrifié aux idoles, et que vous avez péché contre le Seigneur, et que vous n’avez point écouté la voix du Seigneur, et que vous n’avez pas marché dans sa loi, dans ses préceptes et ses témoignages, c’est pour cela que vous sont venus ces maux, comme on le voit en ce jour.
24 Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
Jérémie dit aussi à tout le peuple et à toutes les femmes: Ecoutez la parole du Seigneur, vous tous, enfants de Juda, qui êtes dans la terre d’Egypte.
25 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
Voici ce que dit le Seigneur des armées. Dieu d’Israël: Vous et vos femmes, vous avez accompli par vos mains vos paroles, disant: Acquittons-nous des vœux que nous avons voués de sacrifier à la reine du ciel et de lui faire de nombreuses libations; vous avez accompli vos vœux et vous les avez exécutés.
26 Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
C’est pourquoi écoutez la parole du Seigneur, vous tous, enfants de Juda, qui habitez dans la terre d’Egypte: Voilà que moi j’ai juré par mon grand nom, dit le Seigneur, que mon nom ne sera jamais pins nommé dans toute la terre d’Egypte par la bouche d’aucun homme Juif, disant: Le Seigneur Dieu vit!
27 Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
Voilà que moi je veillerai sur eux pour leur malheur, et non pour leur bien; et tous les hommes de Juda qui sont dans la terre d’Egypte seront détruits par le glaive et par la famine, jusqu’à ce qu’ils soient entièrement détruits.
28 Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
Et ceux qui auront fui le glaive reviendront de la terre d’Egypte dans la terre de Juda, hommes en petit nombre; et tous les restes de ceux de Juda qui sont entrés en Egypte pour y habiter sauront de qui la parole sera accomplie, la mienne ou la leur.
29 “‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
Et voici pour vous, dit le Seigneur, le signe que moi je vous visiterai en ce lieu, afin que vous sachiez que véritablement s’accompliront mes paroles contre vous pour votre malheur.
30 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”
Voici ce que dit le Seigneur: Voilà que moi je livrerai Pharaon Ephrée, roi d’Egypte, à la main de ses ennemis, et à la main de ceux qui cherchent son âme, comme j’ai livré Sédécias, roi de Juda, à la main de Nabuchodonosor, roi de Babylone, son ennemi, et qui cherchait son âme.

< Jeremiah 44 >