< Jeremiah 44 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
The word which came to Jeremiah, against all the Jews who were dwelling in the land of Egypt, —who were dwelling in Migdol and in Tahpanhes, and in Noph, and in the land of Pathros saying:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
Thus, saith Yahweh of hosts, God of Israel, Ye yourselves, saw all the calamity which I brought in upon Jerusalem, and upon all the cities of Judah, —and there they are, a desolation this day, and there is not in them an inhabitant:
3 Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
because of their wickedness which they committed, provoking me to anger, by going to burn incense, to serve other gods, whom they had not known, they, ye nor your fathers;
4 Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
yet I sent unto you all my servants the prophets, betimes sending them, saying, Do not, I pray you, commit this abominable thing, which I hate!
5 Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
but they hearkened not neither inclined their ear, by turning from their wickedness, —so as not to burn incense to other gods.
6 Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
Therefore were mine indignation and mine anger poured out, and a fire was kindled in the cities of Judah and in the streets of Jerusalem, —and they became waste and desolate, as at this day.
7 “Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
Now, therefore, Thus, saith Yahweh God of hosts God of Israel—Wherefore, are ye committing a great wickedness against your own lives, that ye should cut off from you man and woman child and suckling, out of the midst of Judah, —so that there should not be left you a remnant:
8 Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
in that ye provoke me to anger by the works of your own hands, burning incense to other gods, in the land of Egypt, which ye have been entering to sojourn, —that ye should cut them off from you, and that ye should become a contempt and a reproach among all the nations of the earth?
9 Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Have ye forgotten the wicked ways of your fathers and the wicked ways of the kings of Judah, and the wicked ways of his wives, and your own wicked ways, and the wicked ways of your own wives, —which they committed in the land of Judah, and in the streets of Jerusalem?
10 Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
They have not been crushed, unto this day; neither have they been afraid, neither have they walked in my law, and in my statutes, which I set before you and before your fathers,
11 “Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
Therefore, Thus, saith Yahweh of hosts God of Israel, Behold me! setting my face against you for calamity, —even to cut off all Judah;
12 Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
and I will take the remnant of Judah who did set their faces to enter the land of Egypt to sojourn there, and they shall all be consumed, in the land of Egypt, shall they fall by the sword, by famine, shall they be consumed, from the least even unto the greatest, by sword and by famine, shall they die, —so shall they become a curse, and an astonishment, and a contempt and a reproach;
13 Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
and I will bring punishment upon them who are dwelling in the land of Egypt, just as I brought punishment upon Jerusalem, —by sword, by famine and by pestilence;
14 Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
and there shall be neither escape nor survival, unto the remnant of Judah who have been entering, to sojourn there into the land of Egypt, —that they should return to the land of Judah even when they are lifting up their soul to return to dwell there, for none shall return, saving fugitives.
15 Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
Then all the men who knew that their wives were burning incense to other gods, and all the women standing by, a great convocation, —with all the people who were dwelling in the land of Egypt in Pathros, made answer unto Jeremiah, saying:
16 “Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
As touching the word which thou hast spoken unto us, in the name of Yahweh we are not going to hearken unto thee;
17 Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
but, we will certainly do, the whole thing that hath gone forth out of our own mouth, by burning incense to the queen of the heavens, and pouring out to her drink-offerings, just as we and our fathers, and our kings and our princes, did, in the cities of Judah and in the streets of Jerusalem, then were we filled with bread and became prosperous, and calamity, saw we none;
18 Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
whereas, from the very time we ceased burning incense to the queen of the heavens and pouring out to her drink-offerings, we have lacked everything, —and by sword and by famine, have we been consumed.
19 Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
And, though we are burning incense to the queen of the heavens and pouring out to her drink-offerings, is it, without our men that we have made to her sacrificial cakes as images of her and poured out to her, drink-offerings?
20 Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
Then spake Jeremiah unto all the people, —against the men and against the women, and against all the people who had been making any answer unto him, saying:
21 “Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
Was it not, the very incense which ye burned in the cities of Judah, and in the streets of Jerusalem, ye and your fathers your kings and your princes and the people of the land, was it not those very things, that Yahweh did remember, and that came up on his heart;
22 Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
so that Yahweh could no longer forbear because of the wickedness of your doings, because of the abominations which ye committed, —and your land became a desolation, and an astonishment, and a contempt without inhabitant—as at this day?
23 Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
Because that ye burned incense, and that ye sinned against Yahweh and hearkened not unto the voice of Yahweh, and, in his law and in his statutes and in his testimonies, did not walk, for this cause, did this calamity befall you—as at this day.
24 Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
And Jeremiah said unto all the people, and unto all the women, —Hear ye the word of Yahweh, all Judah, who are in the land of Egypt, —
25 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
Thus, saith Yahweh of hosts, God of Israel, saying, Ye and your wives, have both spoken with your mouth and with your hands, have ye fulfilled saying, We will, certainly perform, our vows which we have vowed, to burn incense to the queen of the heavens, and to pour out to her drink-offerings: the women will certainly confirm, your vows, and, certainly perform, your vows.
26 Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
Therefore, hear ye the word of Yahweh, all Judah, who are dwelling in the land of Egypt, —Behold me! I have sworn by my great Name, Saith Yahweh, That my Name shall no more be invoked by the mouth of any man of Judah saying—By the life of My Lord, Yahweh in all the land of Egypt.
27 Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
Behold me! watching over them for calamity, and not for blessing, —so shall all the men of Judah who are in the land of Egypt, be consumed, by sword and by famine until there be an end of them.
28 Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
Yet, the fugitives of the sword, shall certainly return out of the land of Egypt into the land of Judah men easily counted, —that all the remnant of Judah who are entering Egypt to sojourn there, may know, whose word, shall stand, mine or theirs!
29 “‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
And, this, to you, shall be the sign, Declareth Yahweh, that I am about to bring punishment upon you in this place, —that ye may know that my words shall, certainly stand against you, for calamity:
30 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”
Thus, saith Yahweh, Behold me! delivering up Pharaoh-hophra king of Egypt into the hand of his enemies, yea into the hand of them who are seeking his life, —just as I delivered Zedekiah king of Judah into the hand of Nebuchadrezzar king of Babylon his enemy, and one seeking his life.

< Jeremiah 44 >