< Jeremiah 44 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
The word that came to Jeremiah for all the Jews who dwell in the land of Egypt, who dwell at Migdol, and at Thachpanches, and at Noph, and in the country of Pathros, saying,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
Thus hath said the Lord of hosts, the God of Israel, You yourselves have seen all the evil that I have brought over Jerusalem, and over all the cities of Judah; and, behold, they are ruins this day, and no man is dwelling in them;
3 Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
Because of their wickedness which they had committed to provoke me to anger, by going to burn incense, to serve other gods, whom they did not know, either they, you, or your fathers.
4 Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
And I sent unto you all my servants the prophets, making them rise early and sending them, saying, Oh, do not commit this abominable thing which I hate.
5 Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
But they hearkened not, and inclined not their ear to turn away from their wickedness, so as not to burn incense unto other gods.
6 Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
Whereupon my fury and my anger were poured forth, and were enkindled in the cities of Judah and in the streets of Jerusalem: and they are become ruins, a desert, as at this day.
7 “Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
And now thus hath said the Lord, the God of hosts, the God of Israel, Wherefore do ye commit so great an evil against your souls, so as to cut off unto you man and woman, child and suckling, out of the midst of Judah, so as not to leave you any remainder,
8 Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
By provoking me unto wrath with the works of your hands, in burning incense unto other gods in the land of Egypt, whither ye are come to sojourn there, in order to cut yourselves off, and in order that ye might become a curse and a disgrace among all the nations of the earth?
9 Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Have ye forgotten the wickedness of your fathers, and the wickedness of the kings of Judah, and the wickedness of their wives, and your own wickedness, and the wickedness of your wives, which they had committed in the land of Judah, and in the streets of Jerusalem?
10 Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
They are not humbled even up to this day, and they are not afraid, and they walk not in my law, nor in my statutes, that I have set before you and before your fathers.
11 “Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
Therefore thus hath said the Lord of hosts, the God of Israel, Behold, I will set my face against you for evil, and to cut off all Judah.
12 Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
And I will take the remnant of Judah, that have set their faces to go into the land of Egypt to sojourn there, and they shall all come to their end, and in the land of Egypt shall they fall: by the sword [and] by the famine shall they come to their end; from the least even unto the greatest, by the sword and by the famine shall they die; and they shall become an oath, an astonishment, and a curse, and a disgrace.
13 Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
And I will inflict punishment on those that dwell in the land of Egypt, as I have inflicted punishment on Jerusalem, through the sword, through the famine, and through the pestilence:
14 Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
So that there shall be no one that escapeth or remaineth of the remnant of Judah, who are gone into the land of Egypt to sojourn there, that they should return into the land of Judah, to which they direct [the desire of] their soul to return thither to dwell there; for they shall not return, but such as shall escape.
15 Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
Then did all the men who knew that their wives were burning incense unto other gods, and all the women that stood by, a great multitude, and all the people that dwelt in the land of Egypt, in Pathros, answer Jeremiah, saying,
16 “Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
Respecting the word that thou hast spoken unto us in the name of the Lord, we will not hearken unto thee.
17 Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
For to a surety we will do all the word that is gone forth out of our own mouth, to burn incense unto the queen of heaven, and to pour out drink-offerings unto her, as we have done, we, and our fathers, our kings, and our princes, in the cities of Judah, and in the streets of Jerusalem: when we had plenty of food, and fared well, and saw no evil.
18 Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
But since the time we have left off to burn incense to the queen of heaven, and to pour out drink-offerings unto her, have we had a lack of every thing; and we have come to our end through the sword and through the famine.
19 Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
And when we burnt incense to the queen of heaven, and poured out drink-offerings unto her, —was this without [the consent of] our husbands, that we did make cakes for her to make her image, and pour out drink-offerings unto her?
20 Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
Then said Jeremiah unto all the people, to the men, and to the women, and to all the people who had answered him [with that] word, saying,
21 “Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
Behold, it was the incense that ye burnt in the cities of Judah, and in the streets of Jerusalem, ye, and your fathers, your kings, and your princes, and the people of the land, which the Lord remembered, and which came into his mind;
22 Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
So that the Lord could no longer endure it, because of the evil of your doings, because of the abominations which ye had committed: therefore is your land become a ruin, and an [object of] astonishment, and a curse, without an inhabitant, as at this day.
23 Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
Because that ye had burnt incense, and because ye had sinned against the Lord, and had not hearkened to the voice of the Lord, and had not walked in his law, in his statutes, and in his testimonies: therefore did this evil befall you, as it is this day.
24 Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
And Jeremiah said [farther] to all the people, and to all the women, Hear the word of the Lord, all Judah that are in the land of Egypt,
25 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
Thus hath said the Lord of hosts, the God of Israel, saying, Ye and your wives have both spoken with your mouth, and fulfilled with your hands, saying, We will surely perform our vows that we have vowed, to burn incense to the queen of heaven, and to pour out drink-offerings unto her: ye will fully accomplish your vows, and fully perform your vows.
26 Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
Therefore hear ye the word of the Lord, all Judah that dwell in the land of Egypt, Behold, I have sworn by my great name, saith the Lord, that my name shall no more be called by the mouth of any man of Judah, saying, “As the Lord Eternal liveth,” in all the land of Egypt.
27 Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
Behold, I will watch over them for evil, and not for good: and all the men of Judah that are in the land of Egypt shall come to their end through the sword and through the famine, until they be destroyed.
28 Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
Yet some that escape the sword shall return out of the land of Egypt into the land of Judah, but few in number; and all the remnant of Judah, that are come into the land of Egypt to sojourn there, shall know whose words shall stand firm, mine, or theirs.
29 “‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
And this shall be unto you the sign, saith the Lord, that I will inflict punishment on you in this place, in order that ye may know that my words shall surely stand firm against you for evil:
30 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”
Thus hath said the Lord, Behold, I will give Pharaoh-chophra' the king of Egypt into the hand of his enemies, and into the hand of those that seek his life, as I gave Zedekiah the king of Judah into the hand of Nebuchadrezzar the king of Babylon, his enemy, and who had sought his life.

< Jeremiah 44 >