< Jeremiah 44 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
The worde that came to Ieremiah concerning all the Iewes, which dwell in the lande of Egypt, and remained at Migdol and at Tahpanhes, and at Noph, and in the coutry of Pathros, saying,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
Thus sayeth the Lord of hostes the God of Israel, Yee haue seene all the euill that I haue brought vpon Ierusalem, and vpon all the cities of Iudah: and beholde, this day they are desolate, and no man dwelleth therein,
3 Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
Because of their wickednes which they haue comitted, to prouoke me to anger in that they went to burne incense, and to serue other gods, who they knew not, neither they nor you nor your fathers.
4 Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
Howbeit I sent vnto you all my seruats the Prophets rising earely, and sending them, saying, Oh doe not this abominable thing that I hate.
5 Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
But they would not heare nor incline their eare to turne from their wickednes, and to burne no more incense vnto other gods.
6 Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
Wherefore my wrath, and mine anger was powred foorth and was kindled in the cities of Iudah, and in the streetes of Ierusalem, and they are desolate, and wasted, as appeareth this day.
7 “Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
Therefore now thus saith the Lord of hosts the God of Israel, Wherfore commit ye this great euill against your soules, to cut off from you man and woman, childe and suckling out of Iudah, and leaue you none to remaine?
8 Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
In that yee prouoke mee vnto wrath with the woorkes of your hands, burning incense vnto other Gods in the lande of Egypt whither yee be gone to dwell: that yee might bring destruction vnto your selues, and that ye might be a curse and a reproch among all nations of the earth.
9 Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Haue yee forgotten the wickednes of your fathers, and the wickednesse of the Kings of Iudah and the wickednesse of their wiues and your owne wickednes and the wickednes of your wiues, which they haue committed in the land of Iudah and in the streetes of Ierusalem?
10 Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
They are not humbled vnto this day, neither haue they feared nor walked in my lawe nor in my statutes, that I set before you and before your fathers.
11 “Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
Therefore thus sayeth the Lord of hostes the God of Israel, Beholde, I will set my face against you to euill and to destroy all Iudah,
12 Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
And I will take the remnant of Iudah, that haue set their faces to goe into the lande of Egypt there to dwell, and they shall all bee consumed and fall in the lande of Egypt: they shall euen bee consumed by the sworde and by the famine: they shall die from the least vnto the most, by the sworde, and by the famine, and they shall be a detestation and an astonishment and a curse and a reproche.
13 Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
For I will visite them that dwel in the land of Egypt, as I haue visited Ierusalem, by ye sworde, by the famine, and by the pestilence,
14 Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
So that none of the remnant of Iudah, which are gone into the lande of Egypt to dwell there, shall escape or remaine, that they shoulde returne into the land of Iudah to the which they haue a desire to returne to dwell there: for none shall returne, but such as shall escape.
15 Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
Then all the men which knewe that their wiues had burnt incense vnto other gods and all the women that stoode by, a great multitude, euen all the people that dwelt in the lande of Egypt in Pathros, answered Ieremiah, saying,
16 “Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
The worde that thou hast spoken vnto vs in the Name of the Lord, wee will not heare it of thee,
17 Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
But wee will doe whatsoeuer thing goeth out of our owne mouth, as to burne incense vnto the Queene of heauen, and to powre out drinke offerings vnto her, as we haue done, both we and our fathers, our Kings and our princes in the cities of Iudah, and in the streetes of Ierusalem: for then had wee plentie of vitailes and were well and felt none euill.
18 Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
But since wee left off to burne incense to the Queene of heauen, and to powre out drinke offerings vnto her, we haue had scarcenesse of all things, and haue beene consumed by the sworde and by the famine.
19 Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
And when we burnt incense to ye Queene of heauen, and powred out drinke offerings vnto her, did wee make her cakes to make her glad, and powre out drinke offerings vnto her without our husbands?
20 Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
Then said Ieremiah vnto all the people, to the men, and to the women, and to all the people which had giuen him that answere, saying,
21 “Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
Did not the Lord remember the incense, that yee burnt in the cities of Iudah, and in the streetes of Ierusalem, both you, and your fathers, your Kinges, and your princes, and the people of the land, and hath he not considered it?
22 Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
So that the Lord could no longer forbeare, because of the wickednes of your inuentions, and because of the abominations, which ye haue committed: therefore is your lande desolate and an astonishment, and a curse and without inhabitant, as appeareth this day.
23 Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
Because ye haue burnt incense and because ye haue sinned against the Lord, and haue not obeyed the voyce of the Lord, nor walked in his Lawe, nor in his statutes, nor in his testimonies, therefore this plague is come vpon you, as appeareth this day.
24 Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
Moreouer Ieremiah saide vnto all the people and to all the women, Heare the word of the Lord, all Iudah that are in the land of Egypt.
25 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
Thus speaketh the Lord of hosts, the God of Israel, saying, Ye and your wiues haue both spoken with your mouthes, and fulfilled with your hande, saying, We will performe our vowes that we haue vowed to burne incense to the Queene of heauen, and to powre out drinke offerings to her: yee will perfourme your vowes and doe the things that yee haue vowed.
26 Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
Therefore heare the word of the Lord, all Iudah that dwel in the land of Egypt. Beholde, I haue sworne by my great Name, sayeth the Lord, that my Name shall no more be called vpon by the mouth of any man of Iudah, in all the lande of Egypt, saying, The Lord God liueth.
27 Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
Behold, I wil watch ouer them for euil and not for good, and all men of Iudah that are in the land of Egypt, shalbe consumed by the sword, and by the famine, vntill they be vtterly destroied.
28 Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
Yet a small nomber that escape the sworde, shall returne out of the lande of Egypt into the lande of Iudah: and all the remnant of Iudah that are gone into the lande of Egypt to dwell there, shall know whose words shall stad, mine or theirs.
29 “‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
And this shall be a signe vnto you, saith the Lord, whe I visit you in this place, that ye may know that my words shall surely stand against you for euill.
30 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”
Thus sayth the Lord, Beholde, I will giue Pharaoh Hophra King of Egypt into the hand of his enemies, and into the hand of them that seeke his life: as I gaue Zedekiah King of Iudah into the hand of Nebuchad-nezzar King of Babel his enemie, who also sought his life.