< Jeremiah 43 >

1 Nígbà tí Jeremiah parí sísọ ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rán an sí wọn tan.
And it came to pass, when Jeremiah had made an end of speaking unto the whole people all the words of the Lord their God, with which the Lord their God had sent him to them, [namely, ] all these words,
2 Asariah ọmọ Hoṣaiah àti Johanani ọmọ Karea, àti gbogbo àwọn agbéraga ọkùnrin sọ fún Jeremiah pé, “Ìwọ ń pa irọ́! Olúwa Ọlọ́run wa kò rán ọ láti sọ pé, ‘Ẹ má lọ sí Ejibiti láti ṣàtìpó níbẹ̀.’
That then spoke 'Azaryah the son of Hosha'yah, and Jochanan the son of Kareach, and all the presumptuous men, saying unto Jeremiah, Thou speakest falsely: the Lord our God hath not sent thee to say, Ye shall not go into Egypt to sojourn there;
3 Ṣùgbọ́n Baruku, ọmọ Neriah, ni ó fi ọ̀rọ̀ sí ọ lẹ́nu sí wa, láti fà wá lé àwọn ará Babeli lọ́wọ́, láti pa wá àti láti kó wa ní ìgbèkùn lọ sí Babeli.”
But Baruch the son of Neriyah setteth thee on against us, in order to deliver us into the hand of the Chaldeans, that they may put us to death, or carry us away as exiles to Babylon.
4 Nítorí náà, Johanani ti Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun, àti gbogbo àwọn ènìyàn tàpá sí àṣẹ Olúwa nípa dídúró sí Juda.
So Jochanan the son of Kareach, and all the captains of the armies, and all the people, hearkened not to the voice of the Lord, to remain in the land of Judah.
5 Dípò bẹ́ẹ̀, Johanani ọmọ Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun sì ko àwọn àjẹkù Juda tí wọ́n wá láti gbé ilẹ̀ Juda láti orílẹ̀-èdè gbogbo tí wọ́n ti tú wọn ká.
But Jochanan the son of Kareach, and all the captains of the armies, took all the remnant of Judah, that were returned from all the nations, whither they had been driven, to sojourn in the land of Judah;
6 Wọ́n tún kó àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé, àti àwọn ọmọ ọba tí ó jẹ́ obìnrin èyí tí Nebusaradani balógun ẹ̀ṣọ́ ti fi sílẹ̀ pẹ̀lú Gedaliah ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani, àti Jeremiah wòlíì náà àti Baruku ọmọ Neriah.
The men, and the women, and the children, and the king's daughters, and every person that Nebuzaradan the captain of the guard had left with Gedalyahu the son of Achikam the son of Shaphan; and Jeremiah the prophet, and Baruch the son of Neriyah;
7 Nítorí náà, wọn wọ Ejibiti pẹ̀lú àìgbọ́ràn sí àṣẹ Olúwa, wọ́n sì lọ títí dé Tafanesi.
And they entered into the land of Egypt; for they hearkened not to the voice of the Lord; and they came as far as Thachpanches.
8 Ní Tafanesi ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá:
Then came the word of the Lord unto Jeremiah in Thachpanches, saying,
9 “Nígbà tí àwọn Júù ń wòye mú àwọn òkúta pẹ̀lú rẹ, kí o sì rì wọ́n mọ́ inú amọ̀ tí ó wà nínú bíríkì tí ó wà níbi pèpéle ẹnu-ọ̀nà ààfin Farao ní Tafanesi.
Take great stones in thy hand, and hide them in the mortar in the brick-kiln which is at the entrance of Pharaoh's house in Thachpanches, before the eyes of the Jewish men;
10 Báyìí kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí. Èmi yóò ránṣẹ́ sí ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli, Èmi yóò gbé ìjọba rẹ̀ ka orí àwọn òkúta; èyí tí mo ti rì sí ibí yìí, yóò tan ìjọba rẹ̀ jù wọ́n lọ.
And thou shalt say unto them, Thus hath said the Lord of hosts, the God of Israel, Behold, I will send for and take Nebuchadrezzar the king of Babylon, my servant, and I will set his throne above these stones that I have hidden; and he shall spread his royal pavilion over them.
11 Yóò gbé ogun sí Ejibiti; yóò mú ikú bá àwọn tí ó yan ikú; ìgbèkùn fún àwọn tí ó ti yan ìgbèkùn, àti idà fún àwọn tí ó yan idà.
And he shall come and smite the land of Egypt: such as are destined for death shall be given to death; and such as are destined for captivity, to captivity; and such as are destined for the sword, to the sword.
12 Yóò dá, iná sun tẹmpili àwọn òrìṣà Ejibiti, yóò sun tẹmpili àwọn òrìṣà Ejibiti, yóò sì mú wọn lọ ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn, yóò ró aṣọ rẹ̀ mọ́ra, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni yóò ró Ejibiti òun yóò sì lọ kúrò níbẹ̀ ní àlàáfíà.
And I will kindle a fire in the houses of the gods of Egypt, and he shall burn them, and carry them away captive: and he shall wrap around him the land of Egypt, as a shepherd wrappeth his garment around him; and he shall go forth from there in peace.
13 Ní tẹmpili ni yóò ti fọ́ ère ilé oòrùn tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti túútúú, yóò sì sun àwọn tẹmpili àwọn òrìṣà Ejibiti.’”
And he shall break the statues of Bethshemesh, which is in the land of Egypt; and the houses of the gods of the Egyptians shall he burn with fire.

< Jeremiah 43 >