< Jeremiah 42 >

1 Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
Barliq leshker bashliqliri, jümlidin Karéahning oghli Yohanan hem Hoshayaning oghli Yezaniya we eng kichikidin chongighiche barliq xelq
2 Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
Yeremiya peyghemberning yénigha kélip uningdin: «Telipimizni ijabet qilghaysen, Perwerdigar Xudayinggha xelqning qaldisi bolghan bizler üchün dua qilghaysenki (közüng körginidek burun köp bolghan bizler hazir intayin az qalduq),
3 Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
Perwerdigar Xudaying bizge mangidighan yol, qilidighan ishni körsetkey» — dep iltija qildi.
4 Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
Yeremiya peyghember ulargha: «Maqul! Mana, men Perwerdigar Xudayinglargha sözliringlar boyiche dua qilimen; shundaq boliduki, Perwerdigar silerge qandaq jawab berse, men uni silerge héchnémisini qaldurmay toluqi bilen bayan qilimen» — dédi.
5 Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
Ular Yeremiyagha: «Perwerdigar Xudaying séni ewetip bizge yetküzidighan sözning hemmisige emel qilmisaq, Perwerdigar bizge heqiqiy, gépide turudighan guwahchi bolup eyiblisun!» — dédi.
6 Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
«Biz séni Perwerdigar Xudayimizning yénigha ewetimiz; jawab yaxshi bolsun yaman bolsun, uning awazigha itaet qilimiz; biz Xudayimizning awazigha itaet qilghanda, bizge yaxshi bolidu».
7 Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
Shundaq boldiki, on kündin kéyin, Perwerdigarning sözi Yeremiyagha keldi.
8 O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
U Karéahning oghli Yohanan, leshker bashliqlirining hemmisi we eng kichikidin chongighiche barliq xelqni chaqirip
9 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
ulargha mundaq dédi: — «Siler méni telipinglarni Israilning Xudasi Perwerdigarning aldigha yetküzüshke ewetkensiler. U mundaq dédi: —
10 Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
«Siler yenila mushu zéminda turiwersenglarla, Men silerni qurup chiqimen; silerni ghulatmaymen; Men silerni tikip östürimen, silerni yulmaymen; chünki Men béshinglargha chüshürgen balayi’apetke ökünimen.
11 Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
Siler qorqidighan Babil padishahidin qorqmanglar; uningdin qorqmanglar, — deydu Perwerdigar, — chünki Men silerni qutquzush üchün, uning qolidin qutuldurush üchün siler bilen bille bolimen.
12 Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
Men silerge shundaq rehimdilliqni körsitimenki, u silerge rehim qilidu, shuning bilen silerni öz zémininglargha qaytishqa yol qoyidu.
13 “Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Biraq siler Perwerdigar Xudayinglarning awazigha qulaq salmay «Bu zéminda qet’iy turmaymiz» — désenglar
14 Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
we: «Yaq. biz Misir zéminigha barayli; shu yerde ne urushni körmeymiz, ne kanay-agah signalini anglimaymiz, ne nan’gha zar bolmaymiz; shu yerde yashaymiz» — désenglar,
15 nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
emdi Perwerdigarning sözini anglanglar, i Yehudaning bu qaldisi bolghan siler: Samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar — Israilning Xudasi mundaq deydu: — «Siler Misirgha kirip, shu yerde olturaqlishishqa qet’iy niyetke kelgen bolsanglar,
16 Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
emdi shundaq boliduki, siler qorqidighan qilich Misirda silerge yétishiwalidu, siler qorqidighan qehetchilik Misirda silerge egiship qoghlap baridu; shu yerde siler ölisiler.
17 Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
Shundaq boliduki, Misirgha kirip shu yerde turayli dep qet’iy niyet qilghan ademlerning hemmisi qilich, qehetchilik we waba bilen ölidu; ularning héchqaysisi tirik qalmaydu we yaki Men béshigha chüshüridighan balayi’apettin qutulalmaydu.
18 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
Chünki samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar — Israilning Xudasi mundaq deydu: — Ghezipim we qehrim Yérusalémdikilerning béshigha chüshürülgendek, siler Misirgha kirgininglarda, qehrim béshinglargha chüshürülidu; siler lenetke qalidighan we dehshet basidighan obyékt, lenet sözi hem reswachiliqning obyékti bolisiler we siler bu zéminni qaytidin héch körmeysiler.
19 “Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
Perwerdigar siler, yeni Yehudaning qaldisi toghruluq: «Misirgha barmanglar!» — dégen. — Emdi shuni bilip qoyunglarki, men bügünki künide silerni agahlandurdum!».
20 pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
— Silerning méni Perwerdigar Xudayinglarning yénigha ewetkininglar «Perwerdigar Xudayimizgha biz üchün dua qilghaysen; Perwerdigar Xudayimiz bizge néme dése, bizge yetküzüp berseng biz shuning hemmisige emel qilimiz» dégüzgininglar özünglarni aldap jéninglargha zamin bolushtin ibaret boldi, xalas.
21 Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
Men bügünki künde silerge Uning déginini éytip berdim; lékin siler Perwerdigar Xudayinglarning awazigha we yaki Uning méni silerning yéninglargha ewetken héchqaysi ishta Uninggha itaet qilmidinglar.
22 Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”
Emdi hazir shuni bilip qoyunglarki, siler olturaqlishayli dep baridighan jayda qilich, qehetchilik we waba bilen ölisiler».

< Jeremiah 42 >