< Jeremiah 42 >

1 Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
Da kom alle hærførerne, både Johanan, Kareahs sønn, og Jesanja, Hosajas sønn, og alt folket, både små og store,
2 Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
og de sa til profeten Jeremias: La oss bære frem vår ydmyke bønn for dig og bed for oss til Herren din Gud for hele denne rest av folket - for bare nogen få er vi igjen av de mange, således som du selv ser oss her -
3 Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
at Herren din Gud vil la oss få vite hvilken vei vi skal gå, og hvad vi skal gjøre.
4 Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
Profeten Jeremias sa til dem: Jeg skal gjøre det; jeg vil bede til Herren eders Gud efter eders ord, og hvert et ord Herren svarer eder, skal jeg forkynne eder; jeg skal ikke holde et eneste ord skjult for eder.
5 Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
Da sa de til Jeremias: Herren være et sant og trofast vidne imot oss, dersom vi ikke gjør efter hvert ord som Herren din Gud sender dig til oss med!
6 Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
Enten det er godt eller ondt, vil vi lyde Herrens, vår Guds røst, som vi sender dig til, forat det må gå oss vel, når vi lyder Herrens, vår Guds røst.
7 Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
Ti dager efter kom Herrens ord til Jeremias.
8 O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
Og han kalte til sig Johanan, Kareahs sønn, og alle hærførerne som var med ham, og alt folket, både små og store,
9 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
og han sa til dem: Så sier Herren, Israels Gud, som I sendte mig til for å bære frem eders ydmyke bønn for hans åsyn:
10 Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
Dersom I blir i dette land, så vil jeg bygge eder op og ikke bryte eder ned, plante eder og ikke rykke eder op; for jeg angrer det onde jeg har gjort eder.
11 Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
Frykt ikke for Babels konge, som I nu frykter for, frykt ikke for ham, sier Herren; for jeg er med eder og vil frelse eder og fri eder av hans hånd.
12 Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
Og jeg vil la eder finne barmhjertighet, og han skal forbarme sig over eder og la eder vende tilbake til eders land.
13 “Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Men dersom I sier: Vi vil ikke bli i dette land, og I ikke lyder Herrens, eders Guds røst,
14 Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
men sier: Nei, vi vil gå til Egyptens land, så vi kan slippe å se krig og høre basunens lyd og hungre efter brød, og der vil vi bli,
15 nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
så hør nu derfor Herrens ord, I som er blitt igjen av Juda: Så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud: Dersom I setter eder fore å dra til Egypten, og I drar dit for å bo der,
16 Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
da skal sverdet I frykter for, nå eder der i Egyptens land, og hungeren som I er redde for, skal følge eder i hælene der i Egypten, og der skal I dø.
17 Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
Og alle de menn som har satt sig fore å dra til Egypten for å bo der, de skal dø ved sverd, hunger og pest, og ingen av dem skal bli igjen og slippe fra den ulykke som jeg lar komme over dem.
18 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
For så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud: Likesom min vrede og harme blev utøst over Jerusalems innbyggere, således skal min harme bli utøst over eder når I kommer til Egypten, og I skal bli til en ed og til en forferdelse og en forbannelse og til spott, og I skal ikke mere se dette sted.
19 “Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
Herren har talt til eder, I som er blitt igjen av Juda: Dra ikke til Egypten! I skal vite at jeg har advart eder idag.
20 pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
For I farer vill og forspiller eders liv; I har jo selv sendt mig til Herren eders Gud og sagt: Bed for oss til Herren vår Gud og forkynn oss alt det Herren vår Gud sier, og vi vil gjøre det.
21 Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
Og jeg har forkynt eder det idag; men I har ikke hørt på Herrens, eders Guds røst, og på alt det som han sendte mig til eder med.
22 Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”
Så skal I nu vite at I skal dø ved sverd, hunger og pest på det sted som I stunder efter å komme til for å bo der.

< Jeremiah 42 >