< Jeremiah 42 >
1 Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
Da kom alle Høvedsmændene for Hærene frem og Johanan, Kareaks Søn, og Jesanja, Hosajas Søn, og alt Folket, baade smaa og store.
2 Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
Og de sagde til Profeten Jeremias: Kære, lad vor ydmyge Begæring komme ind for dit Ansigt, og bed for os til Herren din Gud, for alle dem, som ere blevne tilbage — thi vi ere blevne tilbage som faa af mange; saaledes som dine Øjne se os —,
3 Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
at Herren din Gud vil tilkendegive os den Vej, som vi skulle vandre paa, og den Ting, som vi skulle gøre.
4 Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
Og Profeten Jeremias sagde til dem: Jeg har hørt det; se, jeg vil bede til Herren, eders Gud, efter eders Ord, og det skal ske, at Jeg vil kundgøre eder hvert Ord, Herren svarer eder, og ikke holde et Ord tilbage for eder.
5 Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
Da sagde de til Jeremias: Herren være et sandt og trofast Vidne imellem os, at vi tilforladeligt ville gøre efter ethvert Ord, med hvilket Herren din Gud sender dig til os;
6 Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
hvad enten det er godt eller ondt, da ville vi høre Herren, vor Guds Røst, til hvem vi sende dig, paa det, at det maa gaa os vel, fordi vi høre Herren vor Guds Røst.
7 Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
Og det skete, der ti Dage vare tilende, da kom Herrens Ord til Jeremias.
8 O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
Og han kaldte ad Johanan, Kareaks Søn, og ad alle de Høvedsmænd for Hæren, som vare med ham, og ad alt Folket, baade smaa og store.
9 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
Og han sagde til dem: Saa siger Herren, Israels Gud, til hvem I sendte mig, for at lade eders ydmyge Begæring komme ind for hans Ansigt:
10 Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
Dersom I fremdeles blive boende i dette Land, da vil jeg bygge og ikke nedbryde eder og plante og ikke oprykke eder, thi jeg har angret det onde, som jeg har gjort eder;
11 Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
frygter ikke for Kongen af Babel, for hvem I frygte, frygter ikke for ham, siger Herren; thi jeg er med eder til at frelse eder og til at redde eder fra hans Haand.
12 Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
Og jeg vil lade eder finde Barmhjertighed, og han skal forbarme sig over eder og lade eder komme tilbage til eders Land.
13 “Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Men dersom I sige: Vi ville ikke blive i dette Land, saa at I ikke lyde Herren eders Guds Røst,
14 Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
men sige: Nej! thi vi ville drage ind i Ægyptens Land, at vi ej skulle se Krig og ej høre Trompetens Lyd og ej lide Hunger for Brøds Skyld, og der ville vi blive:
15 nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
Saa hører da nu Herrens Ord, I, som ere overblevne af Juda! saa siger den Herre Zebaoth, Israels Gud: Dersom I vende eders Ansigt imod Ægypten for at komme did, og I komme for at være der som fremmede,
16 Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
da skai det Sværd, for hvilket Ifrygte, naa eder der i Ægyptens Land; og den Hunger, for hvilken I ængstes, skal følge eder i Hælene der i Ægypten, og der skulle I dø.
17 Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
Saa skal det gaa alle de Mænd, som have vendt deres Ansigt imod Ægypten, for at komme did og være der som fremmede, de skulle dø ved Sværdet, ved Hungeren og ved Pesten; og der skal ingen af dem blive tilovers eller undkomme fra den Ulykke, som jeg lader komme over dem.
18 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
Thi saa siger den Herre Zebaoth, Israels Gud: Ligesom min Vrede og min Harme har været udøst over Jerusalems Indbyggere, saa skal min Vrede udøses over eder, naar I komme til Ægypten; og I skulle blive til en Ed og til en Forfærdelse og til en Forbandelse og til en Forhaanelse og ikke ydermere se dette Sted.
19 “Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
Herren har talt imod eder, I, som ere overblevne af Juda: Drager ikke ind i Ægypten; I skulle visselig vide, at jeg har vidnet for eder i Dag.
20 pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
Thi I have bedraget eder selv; thi I sendte mig til Herren eders Gud og sagde: Bed for os til Herren vor Gud, og giv os det saa til Kende efter alt det, som Herren vor Gud siger, og vi ville gøre det.
21 Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
Og jeg tilkendegav eder det i Dag, men I hørte ikke paa Herren eders Guds Røst, eller noget af det, om hvilket han sendte mig til eder.
22 Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”
Derfor skulle I nu visselig vide, at I skulle dø ved Sværdet, ved Hungeren og ved Pesten, paa det Sted, hvorhen I have Lyst til at komme for der at være som fremmede.