< Jeremiah 42 >

1 Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
Potom přistoupili všecka knížata vojsk, i Jochanan syn Kareachův i Jazaniáš syn Hosaiášův, i všecken lid, od nejmenšího až do největšího,
2 Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
A řekli Jeremiášovi proroku: Uslyš medle nás v ponížené prosbě naší, a modl se za nás Hospodinu Bohu svému, za všecken ostatek tento, nebo nás maličko zůstalo z mnohých, jakž oči tvé nás vidí,
3 Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
Ať nám oznámí Hospodin Bůh tvůj cestu, po níž bychom jíti, a co činiti měli.
4 Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
Jimž řekl Jeremiáš prorok: Uslyšel jsem. Aj, já modliti se budu Hospodinu Bohu vašemu podlé slov vašich, a cožkoli vám odpoví Hospodin, oznámím vám; nezatajím před vámi slova.
5 Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
Oni zase řekli Jeremiášovi: Nechť jest Hospodin mezi námi svědkem pravým a věrným, jestliže podlé každého slova, pro něž poslal tě Hospodin Bůh tvůj k nám, tak se chovati nebudeme.
6 Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
Buď dobré aneb zlé, hlasu Hospodina Boha našeho, pro nejž tě vysíláme k němu, uposlechneme, aby nám dobře bylo, když uposlechneme hlasu Hospodina Boha našeho.
7 Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
Stalo se pak po přeběhnutí desíti dnů, když se stalo slovo Hospodinovo k Jeremiášovi,
8 O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
Že povolal Jochanana syna Kareachova, a všech knížat vojsk, kteříž s ním byli, i všeho lidu, od nejmenšího až do největšího,
9 Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
A řekl jim: Takto praví Hospodin Bůh Izraelský, k němuž jste mne poslali, abych rozprostíral poníženou prosbu vaši před oblíčejem jeho:
10 Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
Jestliže navrátíce se, zůstanete v zemi této, zajisté že vzdělám vás, a nezkazím, anobrž vštípím vás, a nevypléním; neboť lituji toho zlého, kteréž jsem učinil vám.
11 Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
Nebojtež se krále Babylonského, jehož se bojíte, nebojte se ho, dí Hospodin; neboť s vámi jsem, abych vás vysvobozoval, a vytrhoval vás z ruky jeho.
12 Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
Nadto způsobím vám milost, aby se slitoval nad vámi, a dal se vám navrátiti do země vaší.
13 “Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Ale řeknete-li: Nezůstaneme v zemi této, neposlouchajíce hlasu Hospodina Boha svého,
14 Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
A říkajíce: Nikoli, ale do země Egyptské vejdeme, kdež neuzříme boje, ani zvuku trouby neuslyšíme, a chleba lačněti nebudeme, pročež tam se osadíme:
15 nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
Protož nyní slyštež slovo Hospodinovo, ostatkové Judští: Takto praví Hospodin zástupů, Bůh Izraelský: Jestliže vy zarputile na tom zůstanete, abyste vešli do Egypta, a vejdete-li, abyste tam pobyli,
16 Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
Jistě stane se to, že meč, kteréhož se bojíte, tam v zemi Egyptské vás postihne, a hlad, jehož se obáváte, přijde na vás v Egyptě, a tam pomřete.
17 Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
Tak se stane všechněm těm mužům, kteříž uložili předce jíti do Egypta, aby tam byli pohostinu, že zhynou mečem, hladem a morem, a nezůstane z nich žádného, aniž kdo znikne toho zlého, kteréž já uvedu na ně.
18 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
Nebo takto praví Hospodin zástupů, Bůh Izraelský: Jakož vylit jest hněv můj a prchlivost má na obyvatele Jeruzalémské, tak vylita bude prchlivost má na vás, když vejdete do Egypta, a budete k proklínání, a k užasnutí, a k zlořečení, a za útržku; nadto neuzříte více místa tohoto.
19 “Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
K vámť mluví Hospodin, ó ostatkové Judští: Nevcházejte do Egypta. Jistotně vězte, (neboť se vám dnes osvědčuji),
20 pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
Poněvadž jste se neupřímě ke mně měli v myšleních svých, poslavše mne k Hospodinu Bohu vašemu, řkouce: Modl se za nás Hospodinu Bohu našemu, a všecko, jakžť koli dí Hospodin Bůh náš, tak nám oznam, a učiníme,
21 Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
Když pak oznamuji vám dnes, však neposloucháte hlasu Hospodina Boha vašeho hned v ničemž, pročež mne k vám poslal:
22 Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”
Protož pravím, vězte jistotně, že mečem, hladem a morem pomřete v tom místě, kamž se vám zachtělo jíti, abyste tam byli pohostinu.

< Jeremiah 42 >