< Jeremiah 41 >

1 Ní oṣù keje Iṣmaeli, ọmọ Netaniah ọmọ Eliṣama, nínú irú-ọmọ ọba, àti àwọn ìjòyè ọba, àti àwọn ọkùnrin mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu wá ní Mispa; níbẹ̀ ni wọ́n jùmọ̀ jẹun ní Mispa.
And it came to pass in the seventh month, that Ishmael son of Nethaniah son of Elishama of the seed royal and chiefs of the king, and ten men with him, came in, unto Gedaliah son of Ahikam, at Mizpah, —and they did there eat bread together in Mizpah.
2 Iṣmaeli ọmọ Netaniah àti àwọn ọkùnrin mẹ́wàá tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀, sì dìde wọ́n kọlu Gedaliah ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani pẹ̀lú idà. Wọ́n sì pa á, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ilẹ̀ náà.
Then arose Ishmael son of Nethaniah—and the ten men who were with him and they smote Gedaliah son of Ahikam son of Shaphan—with the sword and slew him whom the king of Babylon had set in charge, over the land.
3 Iṣmaeli sì tún pa gbogbo àwọn Júù tí wọ́n wà pẹ̀lú Gedaliah ní Mispa, àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun Babeli tí wọ́n wà níbẹ̀ bákan náà.
And Ishmael smote, all the Jews who were with him even with Gedaliah in Mizpah, and the Chaldeans who were found there the men of war.
4 Ní ọjọ́ kejì tí wọ́n pa Gedaliah kí ó tó di wí pé ẹnikẹ́ni mọ̀,
And it came to pass, on the second day, after he had slain Gedaliah, not, a man, knowing it,
5 àwọn ọgọ́rin ọkùnrin wá láti Ṣekemu, Ṣilo àti Samaria, wọ́n fa irùngbọ̀n wọn, wọ́n ya aṣọ wọn, wọ́n ṣá ara wọn lọ́gbẹ́, wọ́n mú ẹbọ ọpẹ́ àti tùràrí wá sí ilé Olúwa.
that men came in from Shechem, from Shiloh, and from Samaria, —eighty men, with beards shaven and clothes rent who also had cut themselves, with a meal-offering and frankincense in their hand, to bring them into the house of Yahweh.
6 Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah jáde kúrò láti Mispa láti lọ pàdé wọn. Ó sì ń sọkún bí ó ti ṣe ń lọ, nígbà tí ó pàdé wọn, ó wí pé, “Ẹ wá sọ́dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu.”
Then went forth Ishmael son of Nethaniah to meet them out of Mizpah, weeping all along as he went, —and it came to pass when he fell in with them, that he said unto them, Come ye in unto Gedaliah son of Ahikam.
7 Nígbà tí wọ́n dé ìlú náà; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa wọ́n, wọ́n sì sọ òkú wọn sínú ihò kan.
And so it was when they had come into the midst of the city, that Ishmael son of Nethaniah slew them and cast them into the midst of a pit, he and the men who were with him.
8 Ṣùgbọ́n mẹ́wàá nínú wọn sọ fún Iṣmaeli pé, “Má ṣe pa wá! Àwa ní ọkà àti barle, òróró àti oyin ní ìpamọ́ nínú oko.” Nítorí náà, ó fi wọ́n sílẹ̀: kò sì pa wọ́n pẹ̀lú àwọn yòókù.
But, ten men, were found among them, who said unto Ishmael—Do not put us to death, for we have secret treasures in the field, wheat and barley and oil and honey, So he forbare and put them not to death in the midst of their brethren.
9 Nísinsin yìí, ihò náà tí ó kó gbogbo ara àwọn ọkùnrin tí ó ti pa pẹ̀lú Gedaliah sí ni ọba Asa ń lò gẹ́gẹ́ bí i ààbò nítorí ọba Baaṣa ti Israẹli. Iṣmaeli ọmọ Netaniah sì ti kó òkú kún inú rẹ̀.
Now the pit whereinto Ishmael cast all the dead bodies of the men whom he had smitten, was a large pit which King Asa had made for fear of Baasha king of Israel, —the same, did Ishmael son of Nethaniah fill with the slain,
10 Iṣmaeli sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní Mispa nígbèkùn, ọmọbìnrin ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn tókù síbẹ̀ lórí àwọn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti fi yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ṣe olórí. Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah kó wọn ní ìgbèkùn, ó sì jáde rékọjá sí ọ̀dọ̀ àwọn Ammoni.
Then did Ishmael take captive all the remnant of the people that was in Mizpah, —the daughters of the king, and all the people that were left remaining in Mizpah, whom Nebuzaradan chief of the royal executioners had committed unto Gedaliah son of Ahikam, —yea Ishmael son of Nethaniah took them captive, and departed to pass over unto the sons of Ammon.
11 Nígbà tí Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ gbọ́ nípa gbogbo ìpànìyàn náà tí Iṣmaeli ọmọ Netaniah ti ṣe.
But when Johanan son of Kareah and all the captains of the forces who were with him heard of all the wickedness which Ishmael son of Nethaniah had done,
12 Wọ́n kó gbogbo àwọn ọkùnrin wọn, wọ́n sì, lọ bá Iṣmaeli ọmọ Netaniah jà. Wọ́n pàdé rẹ̀ ní odò kan lẹ́bàá Gibeoni.
then took they all the men, and went their way to fight with Ishmael son of Nethaniah, —and found him near the many waters which were in Gibeon.
13 Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn Iṣmaeli tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ rí Johanani ọmọkùnrin Karea àti àwọn olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì yọ̀.
And it came to pass, when all the people who were with Ishmael saw Johanan son of Kareah, and all the captains of the forces who were with him, then were they glad.
14 Gbogbo àwọn ènìyàn tí Iṣmaeli ti kó ní ìgbèkùn ní Mispa yípadà, wọ́n sì lọ sọ́dọ̀ Johanani ọmọ Karea.
So all the people whom Ishmael had carried away captive out of Mizpah, compassed about, and returned and went their way unto Johanan son of Kareah.
15 Ṣùgbọ́n Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah àti àwọn mẹ́jọ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀ bọ́ lọ́wọ́ Johanani, wọ́n sì sálọ sí Ammoni.
But, Ishmael son of Nethaniah, escaped with eight men, from the face of Johanan, —and departed unto the sons of Ammon.
16 Lẹ́yìn náà Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí wọn wà pẹ̀lú rẹ̀ sì kó gbogbo àwọn tí ó kù ní Mispa; àwọn tí ó ti rí gbà lọ́wọ́ Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah; lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa Gedaliah ọmọ Ahikamu. Àwọn ọmọ-ogun, àwọn obìnrin, àwọn ọmọdé àti àwọn olórí ilé ẹjọ́ tí ó ti kó wa láti Gibeoni.
Then did Johanan son of Kareah and all the captains of the forces who were with him take all the remnant of the people whom he had recovered from Ishmael son of Nethaniah out of Mizpah, after he had smitten Gedaliah son of Ahikam, —mighty men, men of war, and women and children and eunuchs, whom he had recovered out of Gibeon;
17 Wọ́n sì kúrò níbẹ̀, wọ́n dúró ní Geruti Kimhamu ní ẹ̀bá Bẹtilẹhẹmu ní ọ́nà ìrìnàjò wọn sí Ejibiti.
and they departed, and dwelt in the khan of Chimham, which is near Bethlehem, —that they might go to enter Egypt;
18 Láti gba àwọn Babeli sílẹ̀. Wọ́n bẹ̀rù wọn nítorí wí pé, “Iṣmaeli ọmọ Netaniah ti pa Gedaliah ọmọ Ahikamu èyí tí ọba Babeli ti yàn gẹ́gẹ́ bí i gómìnà lórí ilẹ̀ náà.”
because of the Chaldeans, for they were afraid of them, —because Ishmael son of Nethaniah had smitten Gedaliah son of Ahikam, whom the king of Babylon had set in charge over the land.

< Jeremiah 41 >