< Jeremiah 40 >

1 Ọ̀rọ̀ náà sì tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa lẹ́yìn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti tú u sílẹ̀ ní Rama. Ó rí Jeremiah tí a fi ẹ̀wọ̀n dè láàrín gbogbo àwọn tí wọ́n mú ní Jerusalẹmu àti Juda. Wọ́n kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli.
Cuvântul care a venit la Ieremia de la DOMNUL, după ce Nebuzaradan, căpetenia gărzii, îl lăsase să plece din Rama, când îl luase, el fiind legat în lanțuri printre toți cei care erau duși captivi din Ierusalim și din Iuda, care erau duși captivi în Babilon.
2 Nígbà tí balógun ẹ̀ṣọ́ rí Jeremiah, ó sọ fún un wí pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ni ó pàṣẹ ibí yìí fún mi.
Și căpetenia gărzii l-a luat pe Ieremia și i-a spus: DOMNUL Dumnezeul tău a pronunțat acest rău asupra acestui loc.
3 Nísinsin yìí, Olúwa ti mú un jáde; ó ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ pé òun yóò ṣe. Gbogbo èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wí pé ẹ̀yin ènìyàn ṣẹ̀ sí Olúwa, àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
Și, DOMNUL a adus aceasta și a făcut conform cu ce a spus, pentru că voi ați păcătuit împotriva DOMNULUI și nu ați ascultat de vocea lui, de aceea acest lucru a venit asupra voastră.
4 Ṣùgbọ́n, ní òní yìí mò ń tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọwọ́ rẹ. Bí o bá fẹ́, tẹ̀lé mi ká lọ sí Babeli, èmi yóò sì bojútó ọ; ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá fẹ́, dúró síbí. Wò ó, gbogbo orílẹ̀-èdè wà níwájú rẹ, lọ sí ibikíbi tí ó bá tẹ́ ọ lọ́rùn.”
Și acum, iată, te dezleg în această zi de lanțurile care erau pe mâna ta. Dacă ți se pare cuvenit să vii cu mine la Babilon, vino; și ochiul meu va fi asupra ta; dar dacă nu ți se pare cuvenit să vii cu mine la Babilon, atunci să nu vii; iată, toată țara este înaintea ta; unde îți pare bine și cuvenit să mergi, acolo să mergi.
5 Ẹ̀wẹ̀, kí ó tó di pé Jeremiah pẹ̀yìndà láti máa lọ, Nebusaradani fi kún un wí pé, “Padà tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu lọ, ọmọ Ṣafani, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ìlú Juda, kí o sì máa gbé ní àárín àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o máa lọ ibikíbi tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ.” Nígbà náà ni balógun náà fún un ní oúnjẹ àti ẹ̀bùn, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
Și până el nu se întorsese înapoi, a spus: Du-te înapoi la Ghedalia, fiul lui Ahicam, fiul lui Șafan, pe care împăratul Babilonului l-a făcut guvernator peste cetățile lui Iuda și locuiește cu el în mijlocul poporului; sau mergi oriunde ți se pare cuvenit să mergi. Astfel căpetenia gărzii i-a dat merinde și o răsplată și l-a lăsat să plece.
6 Báyìí ni Jeremiah lọ sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ní Mispa, ó sì dúró tì í láàrín àwọn ènìyàn tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ náà.
Atunci Ieremia s-a dus la Ghedalia, fiul lui Ahicam, la Mițpa, și a locuit cu el în mijlocul poporului care era rămas în țară.
7 Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ènìyàn tí wọ́n kù lórí orílẹ̀-èdè náà gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀ ní ilẹ̀ náà; àti pé ó ti fi àwọn ọkùnrin, obìnrin àti ọmọdé tí wọ́n jẹ́ tálákà ní ilẹ̀ náà tí wọn kò kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì sí ìkáwọ́ rẹ̀,
Și când toate căpeteniile armatelor, care erau în câmpii, ei și oamenii lor, au auzit că împăratul Babilonului îl făcuse pe Ghedalia, fiul lui Ahicam, guvernator în țară și că îi încredințase bărbați și femei și copii și dintre săracii țării, dintre cei care nu fuseseră duși captivi la Babilon;
8 wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ní Mispa; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, Johanani àti Jonatani ọmọkùnrin ti Karea, Seraiah ọmọkùnrin Tanhumeti tí í ṣe ọmọkùnrin Efai ará Netofa àti Jesaniah ọmọkùnrin Maakati àti àwọn ènìyàn wọn.
Atunci ei au venit la Ghedalia la Mițpa, chiar Ismael, fiul lui Netania, și Iohanan și Ionatan, fiii lui Careah, și Seraia, fiul lui Tanhumet, și fiii lui Efai, netofatitul; și Iezania, fiul unui maacatit, ei și oamenii lor.
9 Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu, ọmọkùnrin ti Ṣafani ṣe ìbúra láti tún fi dá àwọn ènìyàn lójú pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù láti sin àwọn Babeli.” Ó sọ wí pé, “Gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì máa sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.
Și Ghedalia, fiul lui Ahicam, fiul lui Șafan, le-a jurat lor și oamenilor lor, spunând: Nu vă temeți să serviți caldeenilor; locuiți în țară și serviți împăratului Babilonului și vă va fi bine.
10 Èmi fúnra mi yóò dúró ní Mispa láti ṣojú yín níwájú Babeli tí wọ́n tọ̀ wá wá. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni yóò máa kórè ọtí wáìnì, èso igi àti òróró; kí ẹ sì kó wọn sí inú àpò àpamọ́wọ́ yín; kí ẹ̀yin sì máa gbé ní ìlú tí ẹ ti gbà.”
Cât despre mine, iată, eu voi locui la Mițpa, pentru a servi caldeenilor, care vor veni la noi; dar voi adunați vin și fructe de vară și untdelemn și puneți-le în vasele voastre și locuiți în cetățile voastre pe care le-ați luat.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn Juda ní Moabu, Ammoni, Edomu àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ pé ọba Babeli ti fi ohun tókù sílẹ̀ ní Juda, àti pé ó ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ọmọkùnrin Ṣafani gẹ́gẹ́ bí gómìnà lórí wọn.
De asemenea când toți iudeii care erau în Moab și printre amoniți și în Edom și care erau în toate țările au auzit că împăratul Babilonului lăsase o rămășiță din Iuda și că îl pusese peste ei pe Ghedalia, fiul lui Ahicam, fiul lui Șafan;
12 Gbogbo wọn padà wá sí ilẹ̀ Juda sọ́dọ̀ Gedaliah ní Mispa láti orílẹ̀-èdè gbogbo tí a ti lé wọn sí. Wọ́n sì kórè ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọtí wáìnì àti èso igi.
Toți iudeii s-au întors din toate locurile unde fuseseră alungați și au venit în țara lui Iuda, la Ghedalia, la Mițpa și au adunat vin și foarte multe fructe de vară.
13 Johanani ọmọkùnrin ti Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí ó kù ní orílẹ̀-èdè sì tọ Gedaliah wá ní Mispa.
Mai mult, Iohanan, fiul lui Careah, și toate căpeteniile armatelor, care erau în câmpii, au venit la Ghedalia la Mițpa,
14 Wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ha mọ̀ pé Baalisi ọba àwọn Ammoni ti rán Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah láti lọ mú ẹ̀mí rẹ?” Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọkùnrin ti Ahikamu kò gbà wọ́n gbọ́.
Și i-au spus: Știi tu într-adevăr că Baalis, împăratul amoniților, l-a trimis pe Ismael, fiul lui Netania, să te ucidă? Dar Ghedalia, fiul lui Ahicam, nu i-a crezut.
15 Nígbà náà ni Johanani ọmọkùnrin Karea sọ ní ìkọ̀kọ̀ fún Gedaliah ní Mispa pé, “Jẹ́ kí èmi lọ pa Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, ẹnikẹ́ni kò sì ní mọ èyí. Kí ni ìdí rẹ̀ tí yóò ṣe mú ẹ̀mí rẹ, tí o sì ṣe fẹ́ mú àwọn Júù tí ó yí ọ ká túká, kí ìyókù Juda sì parun?”
Atunci Iohanan, fiul lui Careah, i-a vorbit în ascuns lui Ghedalia la Mițpa, spunând: Lasă-mă să plec, te rog, și îl voi ucide pe Ismael, fiul lui Netania, și nimeni nu va ști aceasta; pentru ce să te ucidă el, ca toți iudeii care s-au adunat la tine să fie împrăștiați și rămășița lui Iuda să piară?
16 Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọ Ahikamu sọ fún Johanani ọmọ Karea pé, “Má ṣe ṣe nǹkan yìí! Nítorí nǹkan tí ò ń sọ nípa Iṣmaeli kì í ṣe òtítọ́.”
Dar Ghedalia, fiul lui Ahicam, i-a spus lui Iohanan, fiul lui Careah: Să nu faci acest lucru, pentru că tu vorbești neadevăr despre Ismael.

< Jeremiah 40 >