< Jeremiah 40 >

1 Ọ̀rọ̀ náà sì tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa lẹ́yìn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti tú u sílẹ̀ ní Rama. Ó rí Jeremiah tí a fi ẹ̀wọ̀n dè láàrín gbogbo àwọn tí wọ́n mú ní Jerusalẹmu àti Juda. Wọ́n kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli.
La parole qui vint à Jérémie de par l’Éternel, après que Nebuzaradan, chef des gardes, l’eut renvoyé de Rama, quand il l’eut pris, et qu’il était lié de chaînes au milieu de tous les captifs de Jérusalem et de Juda qu’on transportait à Babylone.
2 Nígbà tí balógun ẹ̀ṣọ́ rí Jeremiah, ó sọ fún un wí pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ni ó pàṣẹ ibí yìí fún mi.
Et le chef des gardes prit Jérémie, et lui dit: L’Éternel, ton Dieu, avait prononcé ce mal sur ce lieu-ci.
3 Nísinsin yìí, Olúwa ti mú un jáde; ó ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ pé òun yóò ṣe. Gbogbo èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wí pé ẹ̀yin ènìyàn ṣẹ̀ sí Olúwa, àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
Et l’Éternel l’a fait venir, et a fait comme il avait dit, car vous avez péché contre l’Éternel, et vous n’avez pas écouté sa voix; et cette chose vous est arrivée.
4 Ṣùgbọ́n, ní òní yìí mò ń tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọwọ́ rẹ. Bí o bá fẹ́, tẹ̀lé mi ká lọ sí Babeli, èmi yóò sì bojútó ọ; ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá fẹ́, dúró síbí. Wò ó, gbogbo orílẹ̀-èdè wà níwájú rẹ, lọ sí ibikíbi tí ó bá tẹ́ ọ lọ́rùn.”
Et maintenant, voici, aujourd’hui je te délivre des chaînes qui sont à tes mains. S’il est bon à tes yeux de venir avec moi à Babylone, viens, et j’aurai les yeux sur toi; mais, s’il est mauvais à tes yeux de venir avec moi à Babylone, ne viens pas. Regarde, toute la terre est devant toi: va où il est bon et droit à tes yeux d’aller.
5 Ẹ̀wẹ̀, kí ó tó di pé Jeremiah pẹ̀yìndà láti máa lọ, Nebusaradani fi kún un wí pé, “Padà tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu lọ, ọmọ Ṣafani, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ìlú Juda, kí o sì máa gbé ní àárín àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o máa lọ ibikíbi tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ.” Nígbà náà ni balógun náà fún un ní oúnjẹ àti ẹ̀bùn, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
Et comme encore il ne répondait pas, [Nebuzaradan lui dit]: Retourne-t’en vers Guedalia, fils d’Akhikam, fils de Shaphan, que le roi de Babylone a établi sur les villes de Juda, et demeure avec lui au milieu du peuple, ou va partout où il sera bon à tes yeux d’aller. Et le chef des gardes lui donna des provisions et un présent, et le renvoya.
6 Báyìí ni Jeremiah lọ sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ní Mispa, ó sì dúró tì í láàrín àwọn ènìyàn tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ náà.
Et Jérémie vint vers Guedalia, fils d’Akhikam, à Mitspa, et habita avec lui parmi le peuple qui était de reste dans le pays.
7 Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ènìyàn tí wọ́n kù lórí orílẹ̀-èdè náà gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀ ní ilẹ̀ náà; àti pé ó ti fi àwọn ọkùnrin, obìnrin àti ọmọdé tí wọ́n jẹ́ tálákà ní ilẹ̀ náà tí wọn kò kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì sí ìkáwọ́ rẹ̀,
Et tous les chefs des forces qui étaient dans la campagne, eux et leurs hommes, apprirent que le roi de Babylone avait établi Guedalia, fils d’Akhikam, sur le pays, et qu’il lui avait confié les hommes, et les femmes, et les enfants, et des pauvres du pays d’entre ceux qui n’avaient pas été transportés à Babylone;
8 wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ní Mispa; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, Johanani àti Jonatani ọmọkùnrin ti Karea, Seraiah ọmọkùnrin Tanhumeti tí í ṣe ọmọkùnrin Efai ará Netofa àti Jesaniah ọmọkùnrin Maakati àti àwọn ènìyàn wọn.
et ils vinrent vers Guedalia à Mitspa, savoir Ismaël, fils de Nethania, et Jokhanan et Jonathan, les fils de Karéakh, et Seraïa, fils de Thanhumeth, et les fils d’Éphaï, le Netophathite, et Jezania, fils d’un Maacathien, eux et leurs hommes.
9 Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu, ọmọkùnrin ti Ṣafani ṣe ìbúra láti tún fi dá àwọn ènìyàn lójú pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù láti sin àwọn Babeli.” Ó sọ wí pé, “Gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì máa sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.
Et Guedalia, fils d’Akhikam, fils de Shaphan, leur jura, à eux et à leurs hommes, disant: Ne craignez pas de servir les Chaldéens; habitez dans le pays et servez le roi de Babylone, et vous vous en trouverez bien.
10 Èmi fúnra mi yóò dúró ní Mispa láti ṣojú yín níwájú Babeli tí wọ́n tọ̀ wá wá. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni yóò máa kórè ọtí wáìnì, èso igi àti òróró; kí ẹ sì kó wọn sí inú àpò àpamọ́wọ́ yín; kí ẹ̀yin sì máa gbé ní ìlú tí ẹ ti gbà.”
Et pour moi, voici, j’habite à Mitspa, pour me tenir là devant les Chaldéens qui viendront vers nous; et vous, récoltez du vin, et des fruits d’été, et de l’huile, et mettez-les dans vos vases, et habitez dans vos villes dont vous avez pris possession.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn Juda ní Moabu, Ammoni, Edomu àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ pé ọba Babeli ti fi ohun tókù sílẹ̀ ní Juda, àti pé ó ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ọmọkùnrin Ṣafani gẹ́gẹ́ bí gómìnà lórí wọn.
Et aussi tous les Juifs qui étaient en Moab, et parmi les fils d’Ammon, et en Édom, ou qui étaient dans tous les pays, entendirent que le roi de Babylone avait accordé un reste à Juda, et qu’il avait établi sur eux Guedalia, fils d’Akhikam, fils de Shaphan;
12 Gbogbo wọn padà wá sí ilẹ̀ Juda sọ́dọ̀ Gedaliah ní Mispa láti orílẹ̀-èdè gbogbo tí a ti lé wọn sí. Wọ́n sì kórè ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọtí wáìnì àti èso igi.
alors tous les Juifs retournèrent de tous les lieux où ils avaient été chassés, et vinrent dans le pays de Juda, vers Guedalia, à Mitspa, et récoltèrent du vin et des fruits d’été en grande abondance.
13 Johanani ọmọkùnrin ti Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí ó kù ní orílẹ̀-èdè sì tọ Gedaliah wá ní Mispa.
Mais Jokhanan, fils de Karéakh, et tous les chefs des forces qui étaient dans la campagne, vinrent vers Guedalia, à Mitspa,
14 Wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ha mọ̀ pé Baalisi ọba àwọn Ammoni ti rán Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah láti lọ mú ẹ̀mí rẹ?” Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọkùnrin ti Ahikamu kò gbà wọ́n gbọ́.
et lui dirent: Sais-tu bien que Baalis, roi des fils d’Ammon, a envoyé Ismaël, fils de Nethania, pour te frapper à mort? Mais Guedalia, fils d’Akhikam, ne les crut point.
15 Nígbà náà ni Johanani ọmọkùnrin Karea sọ ní ìkọ̀kọ̀ fún Gedaliah ní Mispa pé, “Jẹ́ kí èmi lọ pa Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, ẹnikẹ́ni kò sì ní mọ èyí. Kí ni ìdí rẹ̀ tí yóò ṣe mú ẹ̀mí rẹ, tí o sì ṣe fẹ́ mú àwọn Júù tí ó yí ọ ká túká, kí ìyókù Juda sì parun?”
Et Jokhanan, fils de Karéakh, parla en secret à Guedalia, à Mitspa, disant: Que j’aille, je te prie, et je frapperai Ismaël, fils de Nethania, et personne ne le saura; pourquoi te frapperait-il à mort, et tous ceux de Juda qui se sont rassemblés vers toi seraient-ils dispersés, et le reste de Juda périrait-il?
16 Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọ Ahikamu sọ fún Johanani ọmọ Karea pé, “Má ṣe ṣe nǹkan yìí! Nítorí nǹkan tí ò ń sọ nípa Iṣmaeli kì í ṣe òtítọ́.”
Et Guedalia, fils d’Akhikam, dit à Jokhanan, fils de Karéakh: Ne fais pas cette chose-là, car c’est un mensonge que tu dis à l’égard d’Ismaël.

< Jeremiah 40 >