< Jeremiah 4 >

1 “Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,” ni Olúwa wí. “Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi, ìwọ kí ó sì rìn kiri.
Jeśli chcesz powrócić, Izraelu, mówi PAN, to wróć do mnie. A jeśli usuniesz swoje obrzydliwości sprzed mego oblicza, to już nie będziesz się tułał.
2 Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ, àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
I przysięgniesz: Jak żyje PAN w prawdzie, w sądzie i w sprawiedliwości. Wtedy narody będą sobie błogosławić w nim i w nim będą się chlubić.
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu: “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí, kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.
Tak bowiem mówi PAN do mężczyzn z Judy i Jerozolimy: Przeorzcie swoje ugory, a nie siejcie między ciernie;
4 Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa, kọ ọkàn rẹ ní ilà, ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná, nítorí ibi tí o ti ṣe kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
Obrzeżcie się dla PANA i usuńcie napletki waszych serc, Judejczycy i mieszkańcy Jerozolimy, aby moja zapalczywość nie wybuchła jak ogień i nie paliła się tak, że nikt nie zdoła jej zgasić z powodu zła waszych uczynków.
5 “Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé: ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’ Kí o sì kígbe: ‘Kó ara jọ pọ̀! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
Opowiadajcie w Judzie, ogłaszajcie w Jerozolimie i mówcie: Dmijcie w trąbę w [całej] ziemi; wołajcie, zgromadźcie się i mówcie: Zbierzcie się i wejdźmy do miast warownych.
6 Fi àmì láti sálọ sí Sioni hàn, sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró. Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá, àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
Podnieście sztandar w kierunku Syjonu, uciekajcie, nie zastanawiajcie się. Sprowadzam bowiem nieszczęście od północy i wielkie zniszczenie.
7 Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀, apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde. Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀ láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́. Ìlú rẹ yóò di ahoro láìsí olùgbé.
Lew wyszedł ze swojej jaskini, niszczyciel narodów wyruszył, wyszedł ze swego miejsca, aby zamienić twoją ziemię w pustkowie, a twoje miasta zostaną zburzone i pozbawione mieszkańców.
8 Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀ káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún, nítorí ìbínú ńlá Olúwa kò tí ì kúrò lórí wa.
Dlatego przepaszcie się worami, lamentujcie i zawódźcie, bo nie odwróciła się od nas zapalczywość gniewu PANA.
9 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé, “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn, àwọn àlùfáà yóò wárìrì, àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
I stanie się w owym dniu, mówi PAN, że zginie serce króla i serce książąt, a zdumieją się kapłani i prorocy dziwić się będą.
10 Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
I powiedziałem: Ach, Panie BOŻE! Naprawdę bardzo zawiodłeś ten lud i Jerozolimę, mówiąc: Będziecie mieć pokój! A tymczasem miecz przeniknął nas aż do duszy.
11 Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́.
W owym czasie będzie się mówić do tego ludu i do Jerozolimy: Gorący wiatr wyżynny z pustyni [idzie] prosto na mój lud, [lecz] nie po to, by go przewiać czy oczyścić.
12 Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
Wiatr silniejszy niż oni przyjdzie do mnie; teraz ja też wydam na nich wyrok.
13 Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ. Ègbé ni fún wa àwa parun.
Oto nadciągnie jak obłoki, a jego rydwany jak wicher, jego konie są szybsze niż orły. Biada nam, bo jesteśmy spustoszeni.
14 Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
Obmyj z nieprawości swoje serce, Jerozolimo, abyś została wybawiona. Jak długo będą trwać w tobie twoje niegodziwe myśli?
15 Ohùn kan sì ń kéde ní Dani o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
Głos bowiem opowiada od strony Dan i z góry Efraim ogłasza klęskę.
16 “Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè, kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé: ‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
Przypominajcie narodom: Oto ogłaszajcie Jerozolimie, że stróże nadciągają z dalekiej ziemi i wznoszą swój głos przeciwko miastom Judy.
17 Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá, nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’” ni Olúwa wí.
Jak stróże pól otoczą ją dokoła, bo zbuntowała się przeciwko mnie, mówi PAN.
18 “Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ ló fa èyí bá ọ ìjìyà rẹ sì nìyìí. Báwo ló ti ṣe korò tó! Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
Twoja droga i twoje uczynki sprowadziły to na ciebie; twoja niegodziwość [sprawia], że jest to gorzkie [i] że przenika aż do twego serca.
19 Háà! Ìrora mi, ìrora mi! Mo yí nínú ìrora. Háà, ìrora ọkàn mi! Ọkàn mi lù kìkì nínú mi, n kò le è dákẹ́. Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè, mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
O moje wnętrze, moje wnętrze! Cierpię z boleści do samego serca! Trwoży się we mnie moje serce, nie mogę milczeć, bo usłyszałaś, moja duszo, głos trąby [i] okrzyk wojenny.
20 Ìparun ń gorí ìparun; gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi, tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
Klęska za klęską ogłasza się, bo cała ziemia jest spustoszona. Nagle zniszczone zostały moje namioty, w okamgnieniu – moje zasłony.
21 Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
Jak długo mam patrzeć na sztandar i słyszeć dźwięk trąby?
22 “Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi; wọn kò mọ̀ mí. Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ; wọ́n sì jẹ́ aláìlóye. Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe; wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
Bo mój lud jest głupi, nie zna mnie; to są dzieci niemądre i nierozumne. Są mądre w czynieniu zła, lecz dobrze czynić nie umieją.
23 Mo bojú wo ayé, ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo àti ní ọ̀run, ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
Spojrzałem na ziemię, a oto bezkształtna i pusta; na niebo, a nie było na nim światła.
24 Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n wárìrì; gbogbo òkè kéékèèké mì jẹ̀jẹ̀.
Spojrzałem na góry, a oto się trzęsły i wszystkie pagórki się chwiały.
25 Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan; gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
Spojrzałem, a oto nie było człowieka i wszelkie ptactwo niebieskie odleciało.
26 Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀ gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
Spojrzałem, a oto pole urodzajne stało się pustynią, a wszystkie jego miasta zostały zburzone przed PANEM [i] przez zapalczywość jego gniewu.
27 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro, síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
Bo tak mówi PAN: Cała ziemia zostanie spustoszona, lecz całkowicie jej nie zniszczę.
28 Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀ mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
Nad tym ziemia będzie lamentować, a niebiosa w górze zaćmią się, gdyż powiedziałem i postanowiłem, a nie będę żałował ani nie odwrócę się od tego.
29 Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà gbogbo ìlú yóò sálọ. Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó; ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ. Gbogbo ìlú náà sì di ahoro; kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
Przed wrzawą jeźdźców i łuczników ucieknie całe miasto; wejdą w gęstwiny i wstąpią na skały. Wszystkie miasta będą opuszczone i nie będzie w nich żadnego mieszkańca.
30 Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán? Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́. Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ; wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
A ty, spustoszona, cóż uczynisz? Choćbyś się ubrała w szkarłat, choćbyś się przystroiła w złote ozdoby, choćbyś też przyozdobiła swoją twarz kolorem, na próżno się stroisz; [twoi] kochankowie pogardzą tobą, będą czyhać na twoje życie.
31 Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí, tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀. Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé, “Kíyèsi i mo gbé, nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”
Słyszałem bowiem głos jakby rodzącej kobiety, udrękę jakby rodzącej po raz pierwszy, głos córki Syjonu, która lamentuje i wyciąga swe ręce, [mówiąc]: Biada mi teraz, bo moja dusza omdlewa z powodu morderców.

< Jeremiah 4 >