< Jeremiah 4 >

1 “Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,” ni Olúwa wí. “Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi, ìwọ kí ó sì rìn kiri.
Jeźlibyś się chciał nawrócić, Izraelu! mówi Pan, do mnie się nawróć. Bo jeźli odejmiesz obrzydłości twoje od oblicza mego, a nie będziesz się tułał,
2 Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ, àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
I przysiężeszli w prawdzie, w sądzie i w sprawiedliwości, mówiąc: Jako żyje Pan; tedy błogosławić sobie w nim będą narody, i w nim się przechwalać.
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu: “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí, kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.
Albowiem tak mówi Pan mężom Judzkim i Jeruzalemskim: Poorzcie sobie nowinę, a nie siejcie na cierniu;
4 Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa, kọ ọkàn rẹ ní ilà, ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná, nítorí ibi tí o ti ṣe kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
Obrzeżcie się Panu, a odejmijcie nieobrzezki serca waszego, mężowie Judzcy, a obywatele Jeruzalemscy! by snać nie wyszła jako ogień popędliwość moja, a nie zapaliła się, a nie byłby, ktoby ugasił dla złości przedsięwzięcia waszego.
5 “Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé: ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’ Kí o sì kígbe: ‘Kó ara jọ pọ̀! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
Opowiadajcie w Judzie, a w Jeruzalemie ogłaszajcie, i mówcie: Zatrąbcie w trąbę w ziemi, zwołajcie, zgromadźcie lud, a mówcie: Zbierzcie się, a wejdźmy do miast obronnych.
6 Fi àmì láti sálọ sí Sioni hàn, sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró. Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá, àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
Podnieście chorągiew na Syonie, bądźcie serca dobrego, nie zastanawiajcie się; bo Ja złe przywiodę od północy, i porażkę wielką.
7 Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀, apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde. Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀ láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́. Ìlú rẹ yóò di ahoro láìsí olùgbé.
Wychodzi lew z jaskini swojej, a ten, który niszczy narody, wyszedłszy z miejsca swego, ciągnie, aby obrócił ziemię twoję w pustynię, a miasta twoje aby zburzone były, aby nie było żadnego obywatela.
8 Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀ káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún, nítorí ìbínú ńlá Olúwa kò tí ì kúrò lórí wa.
Przetoż przepaście się worami, narzekajcie a kwilcie, bo nie jest odwrócony gniew zapalczywości Pańskiej od nas.
9 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé, “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn, àwọn àlùfáà yóò wárìrì, àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
I stanie się dnia onego, mówi Pan, że zginie serce królewskie, i serce książąt, a zdumieją się kapłani, i prorocy dziwować się będą.
10 Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
I rzekłem: Ach panujący Panie! zaprawdęś bardzo ten lud i Jeruzalem omylił, mówiąc: Pokój mieć będziecie! a wżdy miecz przeniknął aż do duszy.
11 Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́.
Czasu onego rzeką temu ludowi i Jeruzalemowi: Wiatr gwałtowny z miejsc wysokich na puszczy idzie prosto na lud mój, nie żeby przewiewał, ani wyczyszczał.
12 Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
Wiatr gwałtowniejszy niż oni przyjdzie mi; teraz Ja też opowiem im sądy.
13 Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ. Ègbé ni fún wa àwa parun.
Oto występuje jako obłoki, a wozy jego jako wicher, prędsze są niż orły konie jego. Biada nam! bośmy spustoszeni.
14 Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
Omyj od złości serce twoje, Jeruzalem! abyś wybawione było. Dokądże trwać będą w pośrodku ciebie myśli nieprawości twojej.
15 Ohùn kan sì ń kéde ní Dani o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
Bo głos opowiadającego idzie od Danu, a tego, który ogłasza nieprawość, z góry Efraim.
16 “Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè, kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé: ‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
Przypominajcież tym narodom: Oto ogłaszajcie Jeruzalemczykom, że stróżowie przychodzą z ziemi dalekiej, a wydawają przeciwko miastom Judzkim głos swój.
17 Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá, nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’” ni Olúwa wí.
Jako stróżowie pól położą się przeciwko niemu w około; bo mię do gniewu wzruszyło, mówi Pan.
18 “Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ ló fa èyí bá ọ ìjìyà rẹ sì nìyìí. Báwo ló ti ṣe korò tó! Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
Droga twoja i postępki twoje to uczyniły tobie; toć złość twoja przyniosła, że to jest gorzkie, a że przenika aż do serca twego.
19 Háà! Ìrora mi, ìrora mi! Mo yí nínú ìrora. Háà, ìrora ọkàn mi! Ọkàn mi lù kìkì nínú mi, n kò le è dákẹ́. Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè, mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
O wnętrzności moje, wnętrzności moje! boleść cierpię. O osierdzia moje! trwoży się we mnie serce moje, nie zamilczę; bo głos trąby słyszysz, duszo moja! i okrzyk wojenny.
20 Ìparun ń gorí ìparun; gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi, tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
Porażka za porażką ogłasza się, spustoszona będzie zaiste wszystka ziemia; nagle spustoszone będą namioty moje, i opony moje w okamgnieniu.
21 Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
Dokądże widzieć będę chorągiew, i słyszeć głos trąby?
22 “Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi; wọn kò mọ̀ mí. Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ; wọ́n sì jẹ́ aláìlóye. Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe; wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
Bo głupi lud mój nie zna mię, synowie niemądrzy i nierozumni są; mądrzy są do czynienia złego, ale dobrze czynić nie umieją.
23 Mo bojú wo ayé, ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo àti ní ọ̀run, ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
Spojrzęli na ziemię, a oto jest niepozorna i próżna; jeżeli na niebo, nie masz na niem światłości.
24 Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n wárìrì; gbogbo òkè kéékèèké mì jẹ̀jẹ̀.
Spojrzęli na góry, a oto się trzęsą, i wszystkie pagórki chwieją się.
25 Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan; gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
Spojrzęli, a oto niemasz człowieka, i wszelkie ptastwo niebieskie odleciało.
26 Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀ gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
Spojrzęli, a oto pole urodzajne jest pustynią, a wszystkie miasta jego zburzone są od oblicza Pańskiego, i od oblicza gniewu zapalczywości jego.
27 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro, síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
Bo tak mówi Pan: Spustoszona będzie wszystka ziemia, wszakże końca jeszcze nie uczynię.
28 Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀ mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
Nad tem ziemia kwilić będzie, a niebiosa w górze zaćmią się, przeto, żem mówił, com umyślił, a nie żałuję, ani się odwrócę od tego.
29 Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà gbogbo ìlú yóò sálọ. Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó; ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ. Gbogbo ìlú náà sì di ahoro; kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
Przed grzmotem jeźdźców i strzelających z łuku uciecze wszystko miasto; wejdą do gęstych obłoków, i na skały wstąpią. Wszystkie miasta opuszczone będą, a nie będzie, ktoby w nich mieszkał.
30 Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán? Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́. Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ; wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
A ty zburzona będąc cóż uczynisz? Choćbyś się ubrała w szarłat, choćbyś się ozdobiła ozdobą złotą, choćbyś też oblicze twe przyprawiła barwiczką, próżno się stroisz; wzgardzą tobą zalotnicy twoi, a duszy twojej szukać będą.
31 Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí, tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀. Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé, “Kíyèsi i mo gbé, nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”
Bom słyszał głos jako rodzącej, uciski jako pierworodzącej, głos córki Syońskiej narzekającej, a załamującej ręce swe, mówiąc: Biada mnie teraz! bo ustała dusza moja dla morderców.

< Jeremiah 4 >