< Jeremiah 4 >

1 “Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,” ni Olúwa wí. “Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi, ìwọ kí ó sì rìn kiri.
Israël, si tu te retournes, dit l'Eternel, retourne-toi à moi; si tu ôtes tes abominations de devant moi, tu ne seras plus errant ça et là.
2 Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ, àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
Alors tu jureras en vérité, et en jugement, et en justice, l'Eternel est vivant; et les nations se béniront en lui, et se glorifieront en lui.
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu: “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí, kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.
Car ainsi a dit l'Eternel à ceux de Juda et de Jérusalem: défrichez-vous les terres, et ne semez point sur les épines.
4 Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa, kọ ọkàn rẹ ní ilà, ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná, nítorí ibi tí o ti ṣe kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
Hommes de Juda, et vous habitants de Jérusalem, soyez circoncis à l'Eternel, et ôtez les prépuces de vos cœurs; de peur que ma fureur ne sorte comme un feu, et qu'elle ne s'embrase, sans qu'il y ait personne qui l'éteigne, à cause de la méchanceté de vos actions.
5 “Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé: ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’ Kí o sì kígbe: ‘Kó ara jọ pọ̀! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
Faites savoir en Juda, et publiez dans Jérusalem, et dites: sonnez du cor par le pays, criez, [et] vous amassez; et dites: assemblez-vous, et nous entrerons dans les villes fortes.
6 Fi àmì láti sálọ sí Sioni hàn, sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró. Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá, àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
Dressez l'enseigne vers Sion, retirez-vous en troupe, et ne vous arrêtez point; car je m'en vais faire venir de l'Aquilon le mal et une grande calamité.
7 Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀, apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde. Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀ láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́. Ìlú rẹ yóò di ahoro láìsí olùgbé.
Le lion est sorti de la caverne, et le destructeur des nations est parti; il est sorti de son lieu pour réduire ton pays en désolation, tes villes seront ruinées, tellement qu'il n'y aura personne qui y habite.
8 Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀ káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún, nítorí ìbínú ńlá Olúwa kò tí ì kúrò lórí wa.
C'est pourquoi ceignez-vous de sacs, lamentez, et hurlez; car l'ardeur de la colère de l'Eternel n'est point détournée de nous.
9 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé, “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn, àwọn àlùfáà yóò wárìrì, àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
Et il arrivera en ce jour-là, dit l'Eternel, que le cœur du Roi, et le cœur des principaux sera épouvanté, et que les Sacrificateurs seront étonnés, et que les Prophètes seront tout confus.
10 Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
C'est pourquoi j'ai dit: ha! ha! Seigneur Eternel! oui certainement tu as abusé ce peuple et Jérusalem, en disant: vous aurez la paix; et l'épée est venue jusqu’à l'âme.
11 Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́.
En ce temps-là on dira à ce peuple, et à Jérusalem: un vent éclaircissant les lieux élevés [souffle] au désert, dans le chemin de la fille de mon peuple, non pas pour vanner ni pour nettoyer:
12 Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
Un vent plus véhément que ceux-là viendra à moi, et je leur ferai maintenant leur procès.
13 Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ. Ègbé ni fún wa àwa parun.
Voici, il montera comme des nuées, et ses chariots seront semblables à un tourbillon, ses chevaux seront plus légers que des aigles; malheur à nous! car nous sommes détruits.
14 Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
Jérusalem, nettoie ton cœur de ta malice, afin que tu sois délivrée; jusques à quand séjourneront au dedans de toi les pensées de ton injustice?
15 Ohùn kan sì ń kéde ní Dani o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
Car le cri apporte des nouvelles de Dan, et publie du mont d'Ephraïm le tourment.
16 “Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè, kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé: ‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
Faites l'entendre aux nations, voici, publiez contre Jérusalem, [et dites]: les assiégeants viennent d'un pays éloigné, et ils ont jeté leur cri contre les villes de Juda.
17 Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá, nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’” ni Olúwa wí.
Ils se sont mis tout autour d'elle comme les gardes des champs, parce qu'elle m'a été rebelle, dit l'Eternel.
18 “Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ ló fa èyí bá ọ ìjìyà rẹ sì nìyìí. Báwo ló ti ṣe korò tó! Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
Ta conduite et tes actions t'ont produit ces choses; telle a été ta malice; parce que ç'a été une chose amère; certainement elle te touchera jusques au cœur.
19 Háà! Ìrora mi, ìrora mi! Mo yí nínú ìrora. Háà, ìrora ọkàn mi! Ọkàn mi lù kìkì nínú mi, n kò le è dákẹ́. Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè, mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
Mon ventre! mon ventre! je suis dans la douleur; le dedans de mon cœur, mon cœur me bat, je ne me puis taire; car ô mon âme! tu as ouï le son du cor, et le retentissement bruyant de l'alarme.
20 Ìparun ń gorí ìparun; gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi, tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
Une ruine est appelée par l'autre, car toute la terre est détruite; mes tentes ont été incontinent détruites, [et] mes pavillons en un moment.
21 Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
Jusques à quand verrai-je l'enseigne, et entendrai-je le son du cor?
22 “Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi; wọn kò mọ̀ mí. Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ; wọ́n sì jẹ́ aláìlóye. Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe; wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
Car mon peuple est insensé, ils ne m'ont point reconnu; ce sont des enfants insensés, et qui n'ont point d'entendement; ils sont habiles à faire le mal, mais ils ne savent pas faire le bien.
23 Mo bojú wo ayé, ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo àti ní ọ̀run, ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
J'ai regardé la terre, et voici, elle est sans forme et vide; et les cieux, et il n'y a point de clarté.
24 Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n wárìrì; gbogbo òkè kéékèèké mì jẹ̀jẹ̀.
J'ai regardé les montagnes, et voici, elles branlent; et toutes les collines sont renversées.
25 Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan; gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
J'ai regardé, et voici, il n'y a pas un seul homme, et tous les oiseaux des cieux s'en sont fuis.
26 Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀ gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
J'ai regardé, et voici, Carmel est un désert, et toutes ses villes ont été ruinées par l'Eternel, et par l'ardeur de sa colère.
27 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro, síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
Car ainsi a dit l'Eternel: toute la terre ne sera que désolation; néanmoins je ne l'achèverai pas entièrement.
28 Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀ mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
C'est pourquoi la terre mènera deuil, et les cieux seront obscurcis au-dessus, parce que je l'ai prononcé; je l'ai pensé, je ne m'en repentirai point, et je ne le révoquerai point.
29 Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà gbogbo ìlú yóò sálọ. Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó; ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ. Gbogbo ìlú náà sì di ahoro; kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
Toute ville s'enfuit à cause du bruit des gens de cheval, et de ceux qui tirent de l'arc; ils sont entrés dans les bois épais, et sont montés sur les rochers; toute ville est abandonnée et personne n'y habite.
30 Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán? Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́. Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ; wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
Et quand tu auras été détruite, que feras-tu? quoique tu te vêtes de cramoisi, et que tu te pares d'ornements d'or, et que tu couvres ton visage de fard, tu t'embellis en vain; tes amoureux t'ont rebutée, ils chercheront ta vie.
31 Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí, tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀. Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé, “Kíyèsi i mo gbé, nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”
Car j'ai ouï un cri comme celui d'une [femme] qui est en travail, et une angoisse comme celle d'une femme qui est en travail de son premier-né; c'est le cri de la fille de Sion; elle soupire, elle étend ses mains, [en disant]: Malheur maintenant à moi, car mon âme est défaillie à cause des meurtriers.

< Jeremiah 4 >