< Jeremiah 4 >

1 “Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,” ni Olúwa wí. “Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi, ìwọ kí ó sì rìn kiri.
Si Israël revient à moi, dit le Seigneur, s'il se convertit, s'il retire de sa bouche ses abominations et s'il craint devant ma face,
2 Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ, àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
Et s'il jure, Vive le Seigneur avec sincérité, équité et justice, les nations seront bénies en lui, et loueront Dieu dans Jérusalem.
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu: “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí, kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.
Car ainsi dit le Seigneur aux hommes de Juda et aux habitants de Jérusalem: Labourez une terre neuve, et ne semez point parmi les chardons.
4 Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa, kọ ọkàn rẹ ní ilà, ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná, nítorí ibi tí o ti ṣe kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
Circoncisez-vous pour votre Dieu, circoncisez la dureté de vos cœurs, hommes de Juda, et vous, habitants de Jérusalem, de peur que ma colère ne jaillisse comme une flamme et ne vous brûle, et que nul ne soit là pour l'éteindre à la vue de la malice de vos péchés.
5 “Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé: ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’ Kí o sì kígbe: ‘Kó ara jọ pọ̀! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
Annoncez à Juda, et qu'on vous entende en Jérusalem; dites: Donnez le signal de la trompette sur la terre; criez fort et dites: Rassemblez-vous tous, et entrez dans les villes fortifiées.
6 Fi àmì láti sálọ sí Sioni hàn, sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró. Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá, àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
Emportez tout ce que vous pourrez; réfugiez-vous dans Sion; hâtez-vous, ne faites point de halte; car moi, je vais vous amener de l'aquilon des maux et de grands brisements de cœur.
7 Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀, apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde. Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀ láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́. Ìlú rẹ yóò di ahoro láìsí olùgbé.
Le lion est sorti de son antre; il s'est élancé exterminant les nations, et il est parti de sa contrée pour faire de la terre une solitude; et les cités seront abattues, parce qu'il n'y aura plus d'habitants.
8 Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀ káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún, nítorí ìbínú ńlá Olúwa kò tí ì kúrò lórí wa.
C'est pourquoi ceignez-vous de cilices, frappez-vous la poitrine, jetez de grands cris; car la colère du Seigneur ne s'est point détournée de vous,
9 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé, “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn, àwọn àlùfáà yóò wárìrì, àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
Et en ce jour, dit le Seigneur, périra le cœur du roi et le cœur des princes; les prêtres seront saisis de stupeur, et les prophètes seront confondus.
10 Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
Et je dis: O Seigneur, maître, est-ce donc que vous avez trompé ce peuple et Jérusalem, disant: La paix règnera, et voilà que le glaive a pénétré jusqu'à leur âme!
11 Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́.
En ce temps-là, on viendra dire à ce peuple et à Jérusalem: Un esprit d'erreur souffle au désert; la voie de la fille de mon peuple ne conduit ni à la pureté ni à la sainteté.
12 Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
Mais un souffle de plénitude me viendra; et alors moi je dirai mes jugements contre eux.
13 Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ. Ègbé ni fún wa àwa parun.
Voilà qu'il va venir comme une nuée, et son char sera comme un vent impétueux, ses chevaux plus rapides que l'aigle: Malheur à nous! car nous serons accablés de souffrances.
14 Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
Jérusalem, lave ton cœur de tes méchancetés, afin que tu sois sauvée. Jusques à quand resteront-elles en ton cœur, les pensées qui causent tes maux.
15 Ohùn kan sì ń kéde ní Dani o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
Car la voix du messager de malheur viendra de Dan, et on entendra des cris de douleur des montagnes d'Éphraïm.
16 “Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè, kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé: ‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
Vous étés averties, nations; voilà qu'ils sont arrivés, proclamez-le dans Jérusalem; leurs bandes viennent d'une terre lointaine, et elles ont poussé des cris contre la ville de Juda.
17 Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá, nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’” ni Olúwa wí.
Comme les gardiens d'un champ, ils font une enceinte autour d'elle; parce que tu m'as négligé, dit le Seigneur.
18 “Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ ló fa èyí bá ọ ìjìyà rẹ sì nìyìí. Báwo ló ti ṣe korò tó! Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
Tes voies et tes pensées ont attiré sur toi de tels maux, parce que ta méchanceté a été pleine d'amertume, et a pénétré jusqu'au fond de ton cœur.
19 Háà! Ìrora mi, ìrora mi! Mo yí nínú ìrora. Háà, ìrora ọkàn mi! Ọkàn mi lù kìkì nínú mi, n kò le è dákẹ́. Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè, mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
Mes entrailles, je souffre en mes entrailles et dans les sensations de mon cœur; mon âme est agitée de transports; mon cœur est déchiré. Je ne garderai point le silence; car mon âme a entendu le son de la trompette et les cris de la guerre.
20 Ìparun ń gorí ìparun; gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi, tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
Et de sa profonde misère elle appelle le secours de la contrition; car toute la terre a été dans la désolation, le tabernacle a été soudain désolé, et les tentures en ont été dispersées.
21 Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
Jusques à quand verrai-je mes guerriers en fuite, et entendrai-je le son de la trompette?
22 “Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi; wọn kò mọ̀ mí. Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ; wọ́n sì jẹ́ aláìlóye. Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe; wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
Les princes de mon peuple ne m'ont point reconnu; ce sont des fils insensés et privés d'intelligence; ils sont habiles pour mal faire, et ne savent pas faire le bien.
23 Mo bojú wo ayé, ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo àti ní ọ̀run, ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
J'ai regardé la terre, et voilà qu'il n'y avait plus rien; j'ai regardé le ciel, et ses astres n'étaient plus.
24 Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n wárìrì; gbogbo òkè kéékèèké mì jẹ̀jẹ̀.
J'ai vu les montagnes, et elles étaient tremblantes, toutes les collines pleines de troubles.
25 Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan; gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
J'ai regardé, et voilà qu'il n'y avait pas un homme, et tous les oiseaux du ciel étaient effarouchés.
26 Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀ gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
J'ai vu, et voilà que le Carmel était désert, et toutes les villes brûlées par le feu, devant la face du Seigneur; elles avaient toutes été effacées devant la face de sa colère.
27 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro, síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
Or voici ce que dit le Seigneur: Toute la terre sera déserte; mais je ne la ferai point périr tout entière.
28 Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀ mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
Que la terre pleure sur ces maux; que le ciel s'obscurcisse en ses hauteurs; j'ai parlé et je ne me repentirai pas; je me suis élancé en avant, et je ne me détournerai pas du but.
29 Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà gbogbo ìlú yóò sálọ. Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó; ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ. Gbogbo ìlú náà sì di ahoro; kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
Aux cris du cavalier, à l'aspect de l'arc tendu, toute la terre s'est enfuie; ils sont entrés dans les cavernes, ils se sont cachés dans les bois, ils sont montés sur les rochers, Toute ville a été abandonnée; il n'y reste pas un homme.
30 Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán? Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́. Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ; wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
Et toi, que feras-tu? Tu auras beau te revêtir d'écarlate, mettre tes joyaux d'or, teindre en noir tes sourcils; tu te seras parée en vain. Tes amants t'ont repoussée, c'est ta vie qu'ils demandent.
31 Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí, tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀. Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé, “Kíyèsi i mo gbé, nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”
J'ai entendu tes cris comme ceux d'une femme en mal d'enfant, tes gémissements comme ceux d'une mère qui enfante pour la première fois; la voix de la fille de Sion sera brisée, et elle laissera tomber ses mains. Malheur à moi! dira-t-elle, mon âme est défaillante au milieu des morts.

< Jeremiah 4 >