< Jeremiah 4 >

1 “Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,” ni Olúwa wí. “Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi, ìwọ kí ó sì rìn kiri.
If thou wilt return to me, O Israel, saith Jehovah, Thou shalt return [[to thy land]]; If thou wilt put away thy abominations from my sight, Thou shalt no more be a wanderer [[in a foreign land]].
2 Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ, àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
If thou wilt swear, As Jehovah liveth! In truth, in justice, and in righteousness, Then shall the nations bless themselves by thee, And in thee shall they glory.
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu: “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí, kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.
Thus saith Jehovah to the men of Judah and Jerusalem: Break up your fallow ground, And sow not among thorns!
4 Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa, kọ ọkàn rẹ ní ilà, ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná, nítorí ibi tí o ti ṣe kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
Circumcise yourselves to Jehovah; Yea, circumcise your hearts, Ye men of Judah, and inhabitants of Jerusalem! Lest, for the evil of your doings, My fury break forth like fire, And burn so that none can quench it.
5 “Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé: ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’ Kí o sì kígbe: ‘Kó ara jọ pọ̀! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
Declare ye in Judah, And proclaim in Jerusalem, and say, Blow ye the trumpet in the land; Cry ye aloud, and say, Gather yourselves together, And let us go into the fortified cities;
6 Fi àmì láti sálọ sí Sioni hàn, sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró. Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá, àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
Set up a standard toward Zion, Flee, make no stand! For I am about to bring evil from the north, Even great destruction.
7 Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀, apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde. Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀ láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́. Ìlú rẹ yóò di ahoro láìsí olùgbé.
The lion goeth up from his thicket, The destroyer of nations is on his way; He goeth forth from his place to make thy land desolate; Thy cities shall be laid waste so as to be without an inhabitant.
8 Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀ káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún, nítorí ìbínú ńlá Olúwa kò tí ì kúrò lórí wa.
For this cause gird on sackcloth, Lament and howl! For the fierce anger of Jehovah is not turned away from us.
9 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé, “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn, àwọn àlùfáà yóò wárìrì, àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
In that day, saith Jehovah, Shall the heart of the king perish, And the heart of the princes; The priests shall be amazed, And the prophets confounded.
10 Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
Then said I, Alas, O Lord Jehovah! Surely thou hast greatly deceived this people and Jerusalem; Thou hast said, “Ye shall have peace”; And the sword reacheth to the very life!
11 Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́.
At that time shall it be said to this people and to Jerusalem: A dry wind cometh from the hills of the desert, It cometh toward my people, Not to fan, nor to cleanse.
12 Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
Yea, a wind stronger than this shall come; Now will I myself give sentence against them.
13 Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ. Ègbé ni fún wa àwa parun.
Behold, he cometh up like clouds, And his chariots are like a whirlwind; His horses are swifter than eagles. Woe to us! for we are laid waste!
14 Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
Wash thy heart from wickedness, O Jerusalem, That thou mayst be saved! How long shall thy evil devices lodge within thee?
15 Ohùn kan sì ń kéde ní Dani o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
For a voice proclaimeth tidings from Dan, And announceth calamity from mount Ephraim.
16 “Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè, kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé: ‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
Proclaim ye to the nations, Behold, publish ye to Jerusalem, “Watchmen are coming from a far country, And lift their voice against the cities of Judah.”
17 Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá, nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’” ni Olúwa wí.
Like keepers of fields are they round about her Because she hath rebelled against me, saith Jehovah.
18 “Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ ló fa èyí bá ọ ìjìyà rẹ sì nìyìí. Báwo ló ti ṣe korò tó! Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
Thy way and thy doings have brought this upon thee; This is the fruit of thy wickedness; It is bitter; it reacheth to thy heart.
19 Háà! Ìrora mi, ìrora mi! Mo yí nínú ìrora. Háà, ìrora ọkàn mi! Ọkàn mi lù kìkì nínú mi, n kò le è dákẹ́. Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè, mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
O my breast, my breast! I am pained in the walls of my heart; My heart trembleth within me; I cannot be silent; For thou hearest, O my soul, the sound of the trumpet, The alarm of war!
20 Ìparun ń gorí ìparun; gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi, tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
There is a cry of destruction upon destruction; Yea, the whole land is laid waste; Suddenly are my tents destroyed, And my canopies in an instant.
21 Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
How long shall I see the standard, Hear the sound of the trumpet?
22 “Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi; wọn kò mọ̀ mí. Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ; wọ́n sì jẹ́ aláìlóye. Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe; wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
My people is foolish, They have no regard to me; Stupid children are they, And have no understanding; They are wise to do evil, But for doing good they have no knowledge.
23 Mo bojú wo ayé, ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo àti ní ọ̀run, ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
I look to the earth, and lo! emptiness and desolation; To the heavens, and there is no light.
24 Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n wárìrì; gbogbo òkè kéékèèké mì jẹ̀jẹ̀.
I look to the mountains, and lo! they tremble, And all the hills shake.
25 Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan; gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
I look, and lo! there is not a man, And all the birds of heaven are fled.
26 Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀ gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
I look, and lo! Carmel is a desert, And all its cities are thrown down, Before the presence of Jehovah, Before the heat of his anger.
27 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro, síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
For thus saith Jehovah: The whole land shall be desolate, Yet will I not make a full end.
28 Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀ mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
Therefore shall the earth mourn, And the heavens above be black, Because I have spoken, and I will not repent; I have purposed, and I will not recede from it.
29 Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà gbogbo ìlú yóò sálọ. Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó; ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ. Gbogbo ìlú náà sì di ahoro; kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
At the noise of the horsemen and bowmen every city fleeth; They go into thickets, And climb up upon the rocks; All the cities are forsaken, And not a man dwelleth in them.
30 Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán? Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́. Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ; wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
And thou, destined to perish, what wilt thou do? Though thou clothe thyself in scarlet, And deck thyself with ornaments of gold, And rend thine eyes with paint, In vain dost thou adorn thyself; Thy lovers despise thee; They seek thy life.
31 Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí, tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀. Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé, “Kíyèsi i mo gbé, nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”
I hear a cry, as of a woman in travail, Anguish, as of her that bringeth forth her first child. The voice of the daughter of Zion. She sobbeth, she spreadeth out her hands, “Ah! woe is me! I am dying by murderers!”

< Jeremiah 4 >