< Jeremiah 39 >

1 Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
Ngomnyaka wesificamunwemunye kaZedekhiya inkosi yakoJuda, ngenyanga yetshumi, kwafika uNebhukadirezari inkosi yeBhabhiloni lebutho lakhe lonke, bamelana leJerusalema, bayivimbezela.
2 Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
Ngomnyaka wetshumi lanye kaZedekhiya, ngenyanga yesine, ngolwesificamunwemunye lwenyanga, umuzi wafohlelwa.
3 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
Zonke iziphathamandla zenkosi yeBhabhiloni zasezingena, zahlala esangweni eliphakathi, oNerigali-Sharezi, uSamiganebo, uSarisekimi, uRabisarisi, uNerigali-Sharezi, uRabimagi, lazo zonke ezinye iziphathamandla zenkosi yeBhabhiloni.
4 Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
Kwasekusithi lapho uZedekhiya inkosi yakoJuda lawo wonke amadoda empi bezibona, babaleka, baphuma emzini ebusuku ngendlela yesivande senkosi, ngesango eliphakathi kwemiduli emibili; waphuma ngendlela yamagceke.
5 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
Kodwa ibutho lamaKhaladiya laxotshana labo, lamfica uZedekhiya emagcekeni eJeriko; selimbambile lamenyusela kuNebhukadinezari inkosi yeBhabhiloni eRibila, elizweni leHamathi, owakhuluma izigwebo ezimelene laye.
6 Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
Inkosi yeBhabhiloni yasibulala amadodana kaZedekhiya eRibila emehlweni akhe; inkosi yeBhabhiloni yabuya yabulala zonke izikhulu zakoJuda.
7 Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
Yasiphumputhekisa amehlo kaZedekhiya, yambopha ngamaketane ethusi amabili ukuze imuse eBhabhiloni.
8 Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
AmaKhaladiya asetshisa indlu yenkosi lezindlu zabantu ngomlilo, adilizela phansi imiduli yeJerusalema.
9 Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
Lensali yabantu eyayisele emzini, lalabo ababehlubukile, ababehlubukile kuyo, lensali yabantu eyayisele, uNebuzaradani induna yabalindi yabathumba yabasa eBhabhiloni.
10 Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
Kodwa uNebuzaradani induna yabalindi watshiya elizweni lakoJuda ebantwini ababengabayanga ababengelalutho, wabanika izivini lamasimu ngalolosuku.
11 Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
UNebhukadirezari inkosi yeBhabhiloni waselaya ngesandla sikaNebuzaradani induna yabalindi ngoJeremiya esithi:
12 “Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
Mthathe, umise amehlo akho kuye, ungamenzeli ulutho olubi, kodwa njengokukhuluma kwakhe kuwe wenze njalo ngaye.
13 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
Ngakho bathuma oNebuzaradani induna yabalindi, loNebushazibani, uRabisarisi, loNerigali-Sharezi, uRabimagi, lazo zonke induna zenkosi yeBhabhiloni,
14 ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
bathuma, bamthatha uJeremiya egumeni lentolongo, bamnikela kuGedaliya, indodana kaAhikhamu, indodana kaShafani, ukuze amkhuphe amuse endlini yakhe. Wasehlala phakathi kwabantu.
15 Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
Ilizwi leNkosi laselifika kuJeremiya esavalelwe egumeni lentolongo, lisithi:
16 “Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
Hamba ukhulume kuEbedimeleki umEthiyophiya uthi: Itsho njalo iNkosi yamabandla, uNkulunkulu kaIsrayeli: Khangela, ngizakwehlisela amazwi ami kulumuzi ngokubi kungeyisikho ngokuhle, njalo azakuba phambi kwakho ngalolosuku.
17 Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
Kodwa ngizakophula ngalolosuku, itsho iNkosi, njalo kawuyikunikelwa esandleni sabantu obesabayo.
18 Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”
Ngoba ngizakukhulula isibili, kawuyikuwa-ke ngenkemba, kodwa impilo yakho izakuba yimpango kuwe, ngoba uthembele kimi, itsho iNkosi.

< Jeremiah 39 >