< Jeremiah 39 >

1 Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
La neuvième année de Sédécias Roi de Juda, au dixième mois, Nébucadnetsar Roi de Babylone vint avec toute son armée contre Jérusalem, et ils l'assiégèrent.
2 Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
Et la onzième année de Sédécias, au quatrième mois, le neuvième jour du mois, il y eut une brèche faite à la ville.
3 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
Et tous les principaux [Capitaines] du Roi de Babylone [y entrèrent], et s'assirent à la porte du milieu, [savoir] Nergal-saréetser, Samgar-nebu, Sar-sekim, Rabsaris, Nergal, Saréetser, Rabmag, et tout le reste des principaux [Capitaines] du Roi de Babylone.
4 Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
Or il arriva qu'aussitôt que Sédécias Roi de Juda, et tous les hommes de guerre les eurent vus, ils s'enfuirent, et sortirent de nuit hors de la ville, par le chemin du jardin du Roi, par la porte [qui était] entre les deux murailles, et ils s'en allaient par le chemin de la campagne.
5 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
Mais l'armée des Caldéens les poursuivit, et ils atteignirent Sédécias dans les campagnes de Jérico; et l'ayant pris, ils l'amenèrent vers Nébucadnetsar Roi de Babylone à Ribla, qui est au pays de Hamath, où on lui fit son procès.
6 Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
Et le Roi de Babylone fit égorger à Ribla les fils de Sédécias en sa présence; le Roi de Babylone fit aussi égorger tous les magistrats de Juda.
7 Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
Puis il fit crever les yeux à Sédécias, et le fit lier de doubles chaînes d'airain, pour l'emmener à Babylone.
8 Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
Les Caldéens brûlèrent aussi les maisons royales, et les maisons du peuple, et démolirent les murailles de Jérusalem.
9 Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
Et Nébuzar-adan, prévôt de l'hôtel, transporta à Babylone le reste du peuple qui était demeuré dans la ville, et ceux qui s'étaient allés rendre à lui, le résidu, dis-je, du peuple qui était demeuré de reste.
10 Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
Mais Nébuzar-adan, prévôt de l'hôtel, laissa d'entre le peuple les plus pauvres qui n'avaient rien dans le pays de Juda, et en ce jour-là il leur donna des vignes et des champs.
11 Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
Or Nébucadnetsar Roi de Babylone avait donné ordre et commission à Nébuzar-adan prévôt de l'hôtel, touchant Jérémie, en disant:
12 “Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
Retire cet homme-là, et aie les yeux sur lui, et ne lui fais aucun mal; mais fais pour lui tout ce qu'il te dira.
13 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
Nébuzar-adan donc, prévôt de l'hôtel, envoya, et aussi Nébusazban, Rabsaris, Nergal, Saréetser, Rabmag, et tous les principaux [Capitaines] du Roi de Babylone;
14 ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ils envoyèrent, [dis-je], retirer Jérémie de la cour de la prison, et le donnèrent à Guédalia fils d'Ahikam, fils de Saphan, pour le conduire à la maison; ainsi il demeura parmi le peuple.
15 Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
Or la parole de l'Eternel avait été [adressée] à Jérémie, du temps qu'il était enfermé dans la cour de la prison, en disant:
16 “Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
Va, et parle à Hebed-mélec Cusien, et lui dis: ainsi a dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël: voici, je m'en vais faire venir mes paroles sur cette ville pour son malheur, et non point pour son bien, et elles seront accomplies ce jour-là, en ta présence.
17 Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
Mais je te délivrerai en ce jour-là, dit l'Eternel, et tu ne seras point livré entre les mains des hommes dont tu as peur.
18 Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”
Car certainement je te délivrerai, tellement que tu ne tomberas point par l'épée; mais ta vie te sera pour butin, parce que tu as eu confiance en moi, dit l'Eternel.

< Jeremiah 39 >