< Jeremiah 39 >

1 Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
In the nynethe yeer of Sedechie, kyng of Juda, in the tenthe monethe, Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, and al his oost cam to Jerusalem, and thei bisegiden it.
2 Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
Forsothe in the enleuenthe yeer of Sedechie, in the fourthe monethe, in the fyuethe day of the monethe, the citee was opened;
3 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
and alle the princes of the kyng of Babiloyne entriden, and saten in the myddil yate, Veregel, Fererer, Semegar, Nabusarrachym, Rapsaces, Neregel, Sereser, Rebynag, and alle othere princes of the kyng of Babiloyne.
4 Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
And whanne Sedechie, the kyng of Juda, and alle the men werriouris hadden seien hem, thei fledden, and yeden out bi niyt fro the citee, bi the weie of the gardyn of the kyng, and bi the yate that was bitwixe twei wallis; and thei yeden out to the weie of desert.
5 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
Forsothe the oost of Caldeis pursueden hem, and thei token Sedechie in the feeld of wildirnesse of Jericho; and thei token hym, and brouyten to Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, in Reblatha, which is in the lond of Emath; and Nabugodonosor spak domes to hym.
6 Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
And the kyng of Babiloyne killide the sones of Sedechye in Reblatha, bifor hise iyen; and the kyng of Babyloyne killide alle the noble men of Juda.
7 Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
Also he puttide out the iyen of Sedechie, and boond hym in feteris, that he schulde be led in to Babiloyne.
8 Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
And Caldeis brenten with fier the hous of the kyng, and the hous of the comun puple, and distrieden the wal of Jerusalem.
9 Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
And Nabusardan, the maister of knyytis, translatide in to Babiloyne the residues of the puple, that dwelliden in the citee, and the fleeris awei, that hadden fled ouer to hym, and the superflue men of the comyn puple, that weren left.
10 Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
And Nabusardan, the maistir of knyytis, lefte in the lond of Juda, of the puple of pore men, and yaf to hem vyneris and cisternes in that dai.
11 Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
Forsothe Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, hadde comaundid of Jeremye to Nabusardan, maister of chyualrie, and seide,
12 “Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
Take thou him, and sette thin iyen on hym, and do thou no thing of yuel to him; but as he wole, so do thou to hym.
13 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
Therfor Nabusardan, the prynce of chyualrie, sente Nabu, and Lesban, and Rapsases, and Veregel, and Sereser, and Rebynag, and alle the principal men of the kyng of Babiloyne,
14 ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
senten, and token Jeremye fro the porche of the prisoun, and bitokun hym to Godolie, the sone of Aicham, sone of Saphan, that he schulde entre in to the hous, and dwelle among the puple.
15 Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
Forsothe the word of the Lord was maad to Jeremye, whanne he was closid in the porche of the prisoun, and seide,
16 “Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
Go thou, and seie to Abdemelech Ethiopien, and speke thou, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Lo! Y schal brynge my wordis on this citee in to yuel, and not in to good; and tho schulen be in thi siyt in that dai.
17 Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
And Y schal delyuere thee in that day, seith the Lord, and thou schalt not be bitakun in to the hondis of men, whiche thou dreddist;
18 Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”
but Y delyuerynge schal delyuere thee, and thou schalt not falle doun bi swerd; but thi soule schal be in to helthe to thee, for thou haddist trist in me, seith the Lord.

< Jeremiah 39 >