< Jeremiah 39 >
1 Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
In the ninth year of Zedekiah king of Judah, in the tenth month, Nebuchadnezzar king of Babylon and all his force have come to Jerusalem, and they lay siege against it;
2 Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
in the eleventh year of Zedekiah, in the fourth month, on the ninth of the month, the city has been broken up;
3 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
and all the heads of the king of Babylon come in, and they sit at the middle gate, Nergal-Sharezer, Samgar-Nebo, Sarsechim, Rab-Saris, Nergal-Sharezer, chief magus, and all the rest of the heads of the king of Babylon.
4 Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
And it comes to pass, when Zedekiah king of Judah and all the men of war have seen them, that they flee and go forth by night from the city, the way of the king’s garden, through the gate between the two walls, and he goes forth the way of the plain.
5 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
And the forces of the Chaldeans pursue after them, and overtake Zedekiah in the plains of Jericho, and they take him, and bring him up to Nebuchadnezzar king of Babylon, to Riblah, in the land of Hamath, and he speaks with him—judgments.
6 Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
And the king of Babylon slaughters the sons of Zedekiah, in Riblah, before his eyes, indeed, the king of Babylon has slaughtered all the nobles of Judah.
7 Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
And he has blinded the eyes of Zedekiah, and he binds him with bronze chains to bring him to Babylon.
8 Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
And the house of the king, and the house of the people, the Chaldeans have burned with fire, and they have broken down the walls of Jerusalem.
9 Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
And the remnant of the people who are left in the city, and those defecting who have defected to him, and the remnant of the people who are left, Nebuzar-Adan, chief of the executioners, has removed [to] Babylon.
10 Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
And Nebuzar-Adan, chief of the executioners, has left in the land of Judah the poor people who have nothing, and he gives vineyards and fields to them in that day.
11 Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
And Nebuchadnezzar king of Babylon gives a charge concerning Jeremiah, by the hand of Nebuzar-Adan, chief of the executioners, saying,
12 “Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
“Take him, and place your eyes on him, and do no evil thing to him, but as he speaks to you, so do with him.”
13 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
And Nebuzar-Adan, chief of the executioners, sends, and Nebushazban, chief of the eunuchs, and Nergal-Sharezer, chief magus, and all the chiefs of the king of Babylon,
14 ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
indeed, they send and take Jeremiah out of the court of the prison, and give him to Gedaliah son of Ahikam, son of Shaphan, to carry him home, and he dwells in the midst of the people.
15 Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
And a word of YHWH has been to Jeremiah—in his being detained in the court of the prison—saying:
16 “Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
“Go, and you have spoken to Ebed-Melech the Cushite, saying, Thus said YHWH of Hosts, God of Israel: Behold, I am bringing in My words to this city for calamity, and not for good, and they have been before you in that day.
17 Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
And I have delivered you in that day—a declaration of YHWH—and you are not given into the hand of the men of whose face you are afraid,
18 Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”
for I certainly deliver you, and you do not fall by sword, and your life has been to you for a spoil, for you have trusted in Me—a declaration of YHWH.”