< Jeremiah 38 >

1 Ṣefatia ọmọ Mattani, Gedaliah ọmọ Paṣuri, Jehukali ọmọ Ṣelemiah, àti Paṣuri ọmọ Malkiah, gbọ́ ohun tí Jeremiah ń sọ fún àwọn ènìyàn nígbà tí ó sọ wí pé,
Chefatia, fils de Matan, Ghedalia, fils de Pachhour, Youkhal, fils de Chélémia et Pachhour, fils de Malkia eurent connaissance des propos que tenait Jérémie au peuple réuni, à savoir:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ẹnikẹ́ni tó bá dúró nínú ìlú yìí yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tó bá lọ sí Babeli yóò yè; yóò sá àsálà, yóò sì yè.’
"Ainsi parle l’Eternel: Quiconque demeurera dans cette ville périra par le glaive, par la famine ou par la peste; mais celui qui en sortira pour se rendre aux Chaldéens aura la vie sauve, son existence sera sa part de butin: il vivra."
3 Àti pé èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ìdánilójú wà wí pé a ó fi ìlú náà lé ọwọ́ àwọn ọmọ-ogun ọba Babeli; tí yóò sì kó wa nígbèkùn.’”
Ainsi parle l’Eternel: "Cette ville tombera infailliblement au pouvoir de l’armée du roi de Babylone, qui la prendra de vive force."
4 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè wí fún ọba pé, “Ó yẹ kí a pa ọkùnrin yìí; ó ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ-ogun tókù nínú ìlú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn nípa ohun tí ó ń sọ fún wọn. Ọkùnrin yìí kò fẹ́ ìre fún àwọn ènìyàn bí kò ṣe ìparun.”
Les hauts fonctionnaires dirent alors au roi: "Que cet homme soit donc mis à mort! puisqu’aussi bien il jette le découragement parmi les gens de guerre, qui restent encore dans cette ville, et parmi toute la population, en leur adressant de pareils discours; assurément cet homme ne recherche point le salut de ce peuple, mais sa ruine."
5 Sedekiah ọba sì wí pé, “Ó wà lọ́wọ́ yín. Ọba kò lè ṣe ohunkóhun láti takò yín.”
Le roi Sédécias répondit: "Voici, il est entre vos mains, car le roi n’a aucun pouvoir sur vous."
6 Wọ́n gbé Jeremiah sọ sínú ihò Malkiah, ọmọ ọba, tí ó wà ní àgbàlá ilé túbú; wọ́n fi okùn sọ Jeremiah kalẹ̀ sí ìsàlẹ̀ ihò; kò sì ṣí omi nínú ihò náà bí kò ṣe ẹrọ̀fọ̀, Jeremiah sì rì sínú ẹrọ̀fọ̀ náà.
Ils se saisirent donc de Jérémie, et le jetèrent dans la citerne de Malkia, fils du roi, située dans la cour de la geôle. Ce fut au moyen de cordes qu’ils descendirent Jérémie. Dans la citerne, il n’y avait pas d’eau, mais de la vase, et Jérémie enfonça dans cette vase.
7 Ṣùgbọ́n, Ebedimeleki, ará Kuṣi ìjòyè nínú ààfin ọba gbọ́ pé wọ́n ti ju Jeremiah sínú kànga. Nígbà tí ọba jókòó ní ẹnu-bodè Benjamini.
Ebed-Mélec, l’Ethiopien, eunuque attaché à la maison du roi, ayant appris qu’on avait jeté Jérémie dans la citernele roi se tenait alors à la porte de Benjamin,
8 Ebedimeleki jáde kúrò láàfin ọba, ó sì sọ fún un pé,
Ebed-Mélec sortit donc du palais royal et s’adressa au roi en ces termes:
9 “Olúwa mi ọba, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti ṣe ohun búburú sí Jeremiah wòlíì Ọlọ́run. Wọ́n ti gbé e sọ sínú kànga níbi tí kò sí oúnjẹ kankan nínú ìlú mọ́.”
"Seigneur roi, ces hommes-là ont mis le comble aux mauvais traitements infligés à Jérémie, en le jetant dans la citerne, où il mourra de faim sur place, le pain faisant défaut dans la ville."
10 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Ebedimeleki ará Kuṣi pé, “Mú ọgbọ̀n ọkùnrin láti ibí pẹ̀lú rẹ, kí ẹ sì fa wòlíì Jeremiah sókè láti inú ihò, kí ó tó kú.”
Le roi donna alors l’ordre suivant à Ebed-Mélec, l’Ethiopien: "Emmène avec toi d’ici une trentaine d’hommes et retire le prophète Jérémie de la citerne avant qu’il succombe."
11 Ebedimeleki kó àwọn ọkùnrin náà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n lọ sínú yàrá kan nínú ààfin ọba. Ó mú àwọn aṣọ àkísà àti okùn tọ Jeremiah lọ nínú kànga.
Ebed-Mélec prit ces hommes sous sa direction; il se rendit au palais du roi, pénétra dans une salle sise sous le Trésor, et en emporta de vieux haillons et des lambeaux de vêtements usés. Puis il les lança, avec des cordes, à Jérémie, dans la citerne.
12 Ebedimeleki ará Kuṣi sọ fún Jeremiah pé, “Fi àkísà àti okùn bọ abẹ́ abíyá rẹ, Jeremiah sì ṣe bẹ́ẹ̀.”
Ebed-Mélec, l’Ethiopien, dit à Jérémie: "Attache-toi ces vieux haillons et ces vêtements usés sous les aisselles en dessous des cordes", ce que fit Jérémie.
13 Báyìí ni wọ́n ṣe fi okùn yọ Jeremiah jáde, wọ́n sì mu un gòkè láti inú ihò wá, Jeremiah sì wà ní àgbàlá ilé túbú.
De la sorte on hissa Jérémie au moyen des cordes et on le fit remonter de la citerne. Et Jérémie demeura dès lors dans la cour de la geôle.
14 Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ pe, Jeremiah òjíṣẹ́ Ọlọ́run àti láti mú un wá sí ẹnu ibodè kẹta nílé Olúwa. Ọba sì sọ fún Jeremiah pé, “Èmi yóò bi ọ́ ní ohun kan; má sì ṣe fi ohun kan pamọ́ fún mi.”
Le roi Sédécias envoya chercher le prophète Jérémie, qu’il se fit amener dans la troisième avenue de la maison de l’Eternel, et là le roi dit à Jérémie: "J’Ai à te demander quelque chose; ne me dissimule rien."
15 Jeremiah sì sọ fún Sedekiah pé, “Tí mo bá fún ọ ní èsì, ṣé o kò nípa mí? Tí mo bá gbà ọ́ nímọ̀ràn, o kò ní gbọ́ tèmi.”
Jérémie répondit à Sédécias: "Si je te parle franchement, tu me feras mourir, et si je te donne un conseil, tu ne m’écouteras pas!"
16 Ṣùgbọ́n ọba Sedekiah búra ní ìkọ̀kọ̀ fún Jeremiah wí pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó fún wa ní ẹ̀mí, èmi kò nípa ọ́ tàbí fà ọ́ fún àwọn tó ń lépa ẹ̀mí rẹ.”
Le roi Sédécias jura alors à Jérémie dans leur entretien secret, en disant: "Par le Dieu vivant qui nous a donné ce souffle de vie, je ne te ferai pas mourir ni ne te livrerai aux mains de ces gens qui en veulent à tes jours!".
17 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún Sedekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Àyàfi bí o bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn olóyè ọba Babeli, a ó dá ẹ̀mí rẹ sí àti pé ìlú yìí kò ní di jíjó ní iná; ìwọ àti ilé rẹ yóò sì wà láààyè.
Aussitôt Jérémie dit à Sédécias: "Ainsi parle l’Eternel, Dieu-Cebaot, Dieu d’Israël: Si tu te décides à te rendre aux officiers du roi de Babylone, ta vie sera sauve, cette ville ne deviendra pas la proie des flammes, tu vivras, toi et ta famille.
18 Ṣùgbọ́n tí o kò bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn ìjòyè ọba Babeli, a ó fa ìlú yìí lé ọwọ́ àwọn Babeli. Wọn yóò sì fi iná sun ún, ìwọ gan an kò ní le sá mọ́ wọn lọ́wọ́.’”
Mais si tu ne te rends pas aux officiers du roi de Babylone, cette ville sera livrée aux mains des Chaldéens, qui la détruiront par le feu. Quant à toi, tu ne leur échapperas point."
19 Ọba Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Mò ń bẹ̀rù àwọn Júù tó ti sálọ sí ilẹ̀ Babeli, nítorí pé àwọn ará Babeli lè fà mí lé wọn lọ́wọ́ láti fìyà jẹ mí.”
Le roi Sédécias dit à Jérémie: "Je crains les Judéens qui ont passé aux Chaldéens. Peut-être me livrera-t-on entre leurs mains et subirai-je leurs outrages."
20 Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Wọn kò ní fi ọ́ lé e lọ́wọ́. Pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ nípa ṣíṣe ohun tí mo sọ fún ọ; yóò sì dára fún ọ, ẹ̀mí rẹ yóò sì wà.
Jérémie répliqua: "On ne te livrera pas! Ecoute donc la voix de l’Eternel concernant ce que je te dis: tu t’en trouveras bien et ta vie sera sauve.
21 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kọ̀ láti jọ̀wọ́ ara rẹ, èyí ni ohun tí Olúwa ti fihàn mí.
Mais si tu refuses de te rendre, voici la conséquence que m’a fait voir l’Eternel:
22 Gbogbo àwọn obìnrin tókù ní ààfin ọba Juda ni wọn yóò kó jáde fún àwọn ìjòyè ọba Babeli. Àwọn obìnrin náà yóò sì sọ fún ọ pé: “‘Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì borí rẹ. Ẹsẹ̀ rẹ rì sínú ẹrọ̀fọ̀; àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti fi ọ́ sílẹ̀.’
Toutes les femmes qui sont restées dans le palais du roi de Juda seront amenées aux officiers du roi de Babylone, tandis qu’elles s’écrieront: "Ils t’ont leurré et triomphé de toi, les hommes qui possédaient ton amitié. Maintenant que tes pieds sont enfoncés dans la fange, ils se sont éloignés de toi."
23 “Wọn yóò kó àwọn ìyàwó àti ọmọ rẹ wá sí Babeli. Ìwọ gan an kò ní bọ́ níbẹ̀, ọba Babeli yóò mú ọ, wọn yóò sì jó ìlú yìí kanlẹ̀.”
Oui, tes femmes et tes fils, tous, on les conduira auprès des Chaldéens, et toi-même ne leur échapperas point. Tu seras livré au pouvoir du roi de Babylone, et cette ville deviendra la proie des flammes."
24 Nígbà náà ni Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ yìí, tàbí kí o kú.
Sédécias dit à Jérémie: "Que personne ne sache rien de ces propos, sans cela tu es un homme mort!
25 Tí àwọn ìjòyè bá mọ̀ pé mo bá ọ sọ̀rọ̀, tí wọ́n bá wá bá ọ wí pé, ‘Sọ fún wa ohun tí o bá ọba sọ tàbí ohun tí ọba sọ fún ọ; má ṣe fi pamọ́ fún wa tàbí kí a pa ọ́,’
Et si les officiers apprennent que j’ai eu un entretien avec toi et qu’ils viennent te trouver et te dire: Répète-nous donc ce que tu as dit au roi; ne nous dissimule rien, si tu ne veux que nous te fassions périr. Et qu’est-ce que le roi t’a dit de son côté?
26 nígbà náà kí o sọ fún wọn, ‘Mò ń bẹ ọba láti má jẹ́ kí n padà lọ sí ilé Jonatani láti lọ kú síbẹ̀.’”
Tu leur répondras: J’Ai supplié instamment le roi de ne pas. me faire réintégrer la maison de Jonathan, où je succomberais."
27 Gbogbo àwọn olóyè sì wá sí ọ̀dọ̀ Jeremiah láti bi í léèrè, ó sì sọ gbogbo ohun tí ọba ní kí ó sọ. Wọn kò sì sọ ohunkóhun mọ́, nítorí kò sí ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ tí òun àti ọba jọ sọ.
Tous les officiers abordèrent en effet Jérémie pour l’interroger; mais il leur répondit dans les termes mêmes que le roi avait prescrits. Ils le laissèrent en repos, car rien n’avait transpiré.
28 Jeremiah wà nínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́ títí di ọjọ́ tí wọ́n fi kó Jerusalẹmu:
Et Jérémie demeura dans la cour de la geôle jusqu’au jour où Jérusalem fut prise. Et voici ce qui arriva après la prise de Jérusalem.

< Jeremiah 38 >