< Jeremiah 38 >

1 Ṣefatia ọmọ Mattani, Gedaliah ọmọ Paṣuri, Jehukali ọmọ Ṣelemiah, àti Paṣuri ọmọ Malkiah, gbọ́ ohun tí Jeremiah ń sọ fún àwọn ènìyàn nígbà tí ó sọ wí pé,
Shephatia, fils de Mattan, Guedalia, fils de Pashhur, Jucal, fils de Shelemia, et Pashhur, fils de Malkija, entendirent les paroles que Jérémie adressa à tout le peuple, en disant:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ẹnikẹ́ni tó bá dúró nínú ìlú yìí yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tó bá lọ sí Babeli yóò yè; yóò sá àsálà, yóò sì yè.’
« Yahvé dit: Celui qui restera dans cette ville mourra par l'épée, par la famine et par la peste, mais celui qui partira pour les Chaldéens vivra. Il échappera à la mort et il vivra.
3 Àti pé èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ìdánilójú wà wí pé a ó fi ìlú náà lé ọwọ́ àwọn ọmọ-ogun ọba Babeli; tí yóò sì kó wa nígbèkùn.’”
Yahvé dit: « Cette ville sera livrée entre les mains de l'armée du roi de Babylone, qui s'en emparera ».
4 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè wí fún ọba pé, “Ó yẹ kí a pa ọkùnrin yìí; ó ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ-ogun tókù nínú ìlú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn nípa ohun tí ó ń sọ fún wọn. Ọkùnrin yìí kò fẹ́ ìre fún àwọn ènìyàn bí kò ṣe ìparun.”
Et les princes dirent au roi: « Je t'en prie, que cet homme soit mis à mort, car il affaiblit les mains des hommes de guerre qui restent dans cette ville, et les mains de tout le peuple, en leur tenant de tels propos; car cet homme ne cherche pas le bien-être de ce peuple, mais le mal. »
5 Sedekiah ọba sì wí pé, “Ó wà lọ́wọ́ yín. Ọba kò lè ṣe ohunkóhun láti takò yín.”
Le roi Sédécias dit: « Voici qu'il est entre tes mains, car le roi ne peut rien faire pour s'opposer à toi. »
6 Wọ́n gbé Jeremiah sọ sínú ihò Malkiah, ọmọ ọba, tí ó wà ní àgbàlá ilé túbú; wọ́n fi okùn sọ Jeremiah kalẹ̀ sí ìsàlẹ̀ ihò; kò sì ṣí omi nínú ihò náà bí kò ṣe ẹrọ̀fọ̀, Jeremiah sì rì sínú ẹrọ̀fọ̀ náà.
Ils prirent Jérémie et le jetèrent dans le cachot de Malkija, fils du roi, qui se trouvait dans la cour des gardes. Ils firent descendre Jérémie avec des cordes. Dans le cachot, il n'y avait pas d'eau, mais de la boue, et Jérémie s'enfonça dans la boue.
7 Ṣùgbọ́n, Ebedimeleki, ará Kuṣi ìjòyè nínú ààfin ọba gbọ́ pé wọ́n ti ju Jeremiah sínú kànga. Nígbà tí ọba jókòó ní ẹnu-bodè Benjamini.
Lorsque Ebedmélec, l'Éthiopien, un eunuque, qui se trouvait dans la maison du roi, apprit qu'on avait mis Jérémie dans le cachot (le roi était alors assis à la porte de Benjamin),
8 Ebedimeleki jáde kúrò láàfin ọba, ó sì sọ fún un pé,
Ebedmélec sortit de la maison du roi et parla au roi, en disant:
9 “Olúwa mi ọba, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti ṣe ohun búburú sí Jeremiah wòlíì Ọlọ́run. Wọ́n ti gbé e sọ sínú kànga níbi tí kò sí oúnjẹ kankan nínú ìlú mọ́.”
« Mon seigneur le roi, ces hommes ont mal agi dans tout ce qu'ils ont fait au prophète Jérémie, qu'ils ont jeté dans le cachot. Il risque de mourir dans le lieu où il se trouve, à cause de la famine, car il n'y a plus de pain dans la ville. »
10 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Ebedimeleki ará Kuṣi pé, “Mú ọgbọ̀n ọkùnrin láti ibí pẹ̀lú rẹ, kí ẹ sì fa wòlíì Jeremiah sókè láti inú ihò, kí ó tó kú.”
Alors le roi donna cet ordre à Ebedmelech, l'Éthiopien: « Prends avec toi trente hommes d'ici, et fais sortir Jérémie le prophète du cachot, avant qu'il ne meure. »
11 Ebedimeleki kó àwọn ọkùnrin náà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n lọ sínú yàrá kan nínú ààfin ọba. Ó mú àwọn aṣọ àkísà àti okùn tọ Jeremiah lọ nínú kànga.
Ebedmélec prit donc les hommes avec lui, et entra dans la maison du roi, sous le trésor; il prit là des chiffons et des vêtements usés, et les fit descendre par des cordes dans le cachot de Jérémie.
12 Ebedimeleki ará Kuṣi sọ fún Jeremiah pé, “Fi àkísà àti okùn bọ abẹ́ abíyá rẹ, Jeremiah sì ṣe bẹ́ẹ̀.”
Ebedmelech, l'Éthiopien, dit à Jérémie: « Mets maintenant ces chiffons et ces vêtements usés sous tes aisselles, sous les cordes. » Jérémie fit ainsi.
13 Báyìí ni wọ́n ṣe fi okùn yọ Jeremiah jáde, wọ́n sì mu un gòkè láti inú ihò wá, Jeremiah sì wà ní àgbàlá ilé túbú.
Et ils soulevèrent Jérémie avec les cordes, et le firent monter hors du cachot; et Jérémie resta dans la cour des gardes.
14 Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ pe, Jeremiah òjíṣẹ́ Ọlọ́run àti láti mú un wá sí ẹnu ibodè kẹta nílé Olúwa. Ọba sì sọ fún Jeremiah pé, “Èmi yóò bi ọ́ ní ohun kan; má sì ṣe fi ohun kan pamọ́ fún mi.”
Alors le roi Sédécias envoya chercher Jérémie, le prophète, et le fit entrer dans la troisième entrée, celle de la maison de l'Éternel. Le roi dit alors à Jérémie: « Je vais te demander quelque chose. Ne me cache rien. »
15 Jeremiah sì sọ fún Sedekiah pé, “Tí mo bá fún ọ ní èsì, ṣé o kò nípa mí? Tí mo bá gbà ọ́ nímọ̀ràn, o kò ní gbọ́ tèmi.”
Jérémie dit alors à Sédécias: « Si je te le déclare, ne me feras-tu pas mourir? Si je te donne un conseil, tu ne m'écouteras pas. »
16 Ṣùgbọ́n ọba Sedekiah búra ní ìkọ̀kọ̀ fún Jeremiah wí pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó fún wa ní ẹ̀mí, èmi kò nípa ọ́ tàbí fà ọ́ fún àwọn tó ń lépa ẹ̀mí rẹ.”
Et le roi Sédécias jura secrètement à Jérémie, en disant: « L'Éternel est vivant, lui qui a fait nos âmes, je ne te ferai pas mourir, et je ne te livrerai pas entre les mains de ces hommes qui en veulent à ta vie. »
17 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún Sedekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Àyàfi bí o bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn olóyè ọba Babeli, a ó dá ẹ̀mí rẹ sí àti pé ìlú yìí kò ní di jíjó ní iná; ìwọ àti ilé rẹ yóò sì wà láààyè.
Jérémie dit alors à Sédécias: « Yahvé, le Dieu des armées, le Dieu d'Israël, dit: « Si tu vas vers les princes du roi de Babylone, ton âme vivra, et cette ville ne sera pas brûlée par le feu. Tu vivras, ainsi que ta maison.
18 Ṣùgbọ́n tí o kò bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn ìjòyè ọba Babeli, a ó fa ìlú yìí lé ọwọ́ àwọn Babeli. Wọn yóò sì fi iná sun ún, ìwọ gan an kò ní le sá mọ́ wọn lọ́wọ́.’”
Mais si tu ne sors pas vers les chefs du roi de Babylone, cette ville sera livrée entre les mains des Chaldéens, qui la brûleront par le feu, et tu n'échapperas pas à leurs mains.'"
19 Ọba Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Mò ń bẹ̀rù àwọn Júù tó ti sálọ sí ilẹ̀ Babeli, nítorí pé àwọn ará Babeli lè fà mí lé wọn lọ́wọ́ láti fìyà jẹ mí.”
Le roi Sédécias dit à Jérémie: « J'ai peur des Juifs qui sont passés aux Chaldéens, de peur qu'ils ne me livrent entre leurs mains et qu'ils ne se moquent de moi. »
20 Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Wọn kò ní fi ọ́ lé e lọ́wọ́. Pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ nípa ṣíṣe ohun tí mo sọ fún ọ; yóò sì dára fún ọ, ẹ̀mí rẹ yóò sì wà.
Mais Jérémie dit: « Ils ne te délivreront pas. Obéis, je t'en prie, à la voix de Yahvé, dans ce que je te dis; ainsi tu seras heureux, et ton âme vivra.
21 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kọ̀ láti jọ̀wọ́ ara rẹ, èyí ni ohun tí Olúwa ti fihàn mí.
Mais si tu refuses de sortir, voici la parole que Yahvé m'a montrée:
22 Gbogbo àwọn obìnrin tókù ní ààfin ọba Juda ni wọn yóò kó jáde fún àwọn ìjòyè ọba Babeli. Àwọn obìnrin náà yóò sì sọ fún ọ pé: “‘Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì borí rẹ. Ẹsẹ̀ rẹ rì sínú ẹrọ̀fọ̀; àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti fi ọ́ sílẹ̀.’
Voici que toutes les femmes qui resteront dans la maison du roi de Juda seront amenées devant les princes du roi de Babylone, et ces femmes diront, « Vos amis familiers se sont retournés contre vous, et l'ont emporté sur vous. Vos pieds sont enfoncés dans la boue, ils se sont détournés de toi. »
23 “Wọn yóò kó àwọn ìyàwó àti ọmọ rẹ wá sí Babeli. Ìwọ gan an kò ní bọ́ níbẹ̀, ọba Babeli yóò mú ọ, wọn yóò sì jó ìlú yìí kanlẹ̀.”
Ils emmèneront toutes vos femmes et vos enfants chez les Chaldéens. Tu n'échapperas pas à leur main, mais tu seras pris par la main du roi de Babylone. Tu feras en sorte que cette ville soit brûlée par le feu.'"
24 Nígbà náà ni Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ yìí, tàbí kí o kú.
Sédécias dit alors à Jérémie: « Que personne ne sache rien de ces paroles, et tu ne mourras pas.
25 Tí àwọn ìjòyè bá mọ̀ pé mo bá ọ sọ̀rọ̀, tí wọ́n bá wá bá ọ wí pé, ‘Sọ fún wa ohun tí o bá ọba sọ tàbí ohun tí ọba sọ fún ọ; má ṣe fi pamọ́ fún wa tàbí kí a pa ọ́,’
Mais si les chefs apprennent que je t'ai parlé, qu'ils viennent te voir et te disent: « Déclare-nous maintenant ce que tu as dit au roi; ne nous le cache pas, et nous ne te ferons pas mourir; dis-nous aussi ce que le roi t'a dit »,
26 nígbà náà kí o sọ fún wọn, ‘Mò ń bẹ ọba láti má jẹ́ kí n padà lọ sí ilé Jonatani láti lọ kú síbẹ̀.’”
tu leur diras: « J'ai présenté ma supplique au roi, pour qu'il ne me fasse pas retourner dans la maison de Jonathan, afin d'y mourir ».
27 Gbogbo àwọn olóyè sì wá sí ọ̀dọ̀ Jeremiah láti bi í léèrè, ó sì sọ gbogbo ohun tí ọba ní kí ó sọ. Wọn kò sì sọ ohunkóhun mọ́, nítorí kò sí ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ tí òun àti ọba jọ sọ.
Alors tous les princes vinrent auprès de Jérémie et l'interrogèrent; et il leur répondit selon toutes ces paroles que le roi avait ordonnées. Ils cessèrent donc de parler avec lui, car l'affaire n'était pas perçue.
28 Jeremiah wà nínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́ títí di ọjọ́ tí wọ́n fi kó Jerusalẹmu:
Jérémie resta donc dans la cour des gardes jusqu'au jour de la prise de Jérusalem.

< Jeremiah 38 >