< Jeremiah 38 >
1 Ṣefatia ọmọ Mattani, Gedaliah ọmọ Paṣuri, Jehukali ọmọ Ṣelemiah, àti Paṣuri ọmọ Malkiah, gbọ́ ohun tí Jeremiah ń sọ fún àwọn ènìyàn nígbà tí ó sọ wí pé,
Forsothe Safacie, sone of Nathan, and Jedelie, sone of Fassur, and Jothal, sone of Selemye, and Fassour, sone of Melchie, herden the wordis whiche Jeremye spak to al the puple,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ẹnikẹ́ni tó bá dúró nínú ìlú yìí yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tó bá lọ sí Babeli yóò yè; yóò sá àsálà, yóò sì yè.’
`and seide, The Lord seith these thingis, Who euer dwellith in this citee, schal die bi swerd, and hungur, and pestilence; but he that flieth to Caldeis, shal lyue, and his soule schal be hool and lyuynge.
3 Àti pé èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ìdánilójú wà wí pé a ó fi ìlú náà lé ọwọ́ àwọn ọmọ-ogun ọba Babeli; tí yóò sì kó wa nígbèkùn.’”
The Lord seith these thingis, This citee to be bitakun schal be bitakun in to the hond of the oost of the kyng of Babiloyne, and he schal take it.
4 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè wí fún ọba pé, “Ó yẹ kí a pa ọkùnrin yìí; ó ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ-ogun tókù nínú ìlú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn nípa ohun tí ó ń sọ fún wọn. Ọkùnrin yìí kò fẹ́ ìre fún àwọn ènìyàn bí kò ṣe ìparun.”
And the princes seiden to the kyng, We preien, that this man be slayn; for of bifore castyng he discoumfortith the hondis of men werriours, that dwelliden in this citee, and the hondis of al the puple, and spekith to hem bi alle these wordis. For whi this man sekith not pees to this puple, but yuel.
5 Sedekiah ọba sì wí pé, “Ó wà lọ́wọ́ yín. Ọba kò lè ṣe ohunkóhun láti takò yín.”
And kyng Sedechie seide, Lo! he is in youre hondis, for it is not leueful that the kyng denye ony thing to you.
6 Wọ́n gbé Jeremiah sọ sínú ihò Malkiah, ọmọ ọba, tí ó wà ní àgbàlá ilé túbú; wọ́n fi okùn sọ Jeremiah kalẹ̀ sí ìsàlẹ̀ ihò; kò sì ṣí omi nínú ihò náà bí kò ṣe ẹrọ̀fọ̀, Jeremiah sì rì sínú ẹrọ̀fọ̀ náà.
Therfor thei token Jeremye, and castiden hym doun in to the lake of Elchie, sone of Amalech, which was in the porche of the prisoun; and thei senten doun Jeremye bi cordis in to the lake, wherynne was no watir, but fen; therfor Jeremye yede doun in to the filthe.
7 Ṣùgbọ́n, Ebedimeleki, ará Kuṣi ìjòyè nínú ààfin ọba gbọ́ pé wọ́n ti ju Jeremiah sínú kànga. Nígbà tí ọba jókòó ní ẹnu-bodè Benjamini.
Forsothe Abdemalech Ethiopien, a chast man and oneste, herde, that was in the kyngis hous, that thei hadden sent Jeremye in to the lake; sotheli the king sat in the yate of Beniamyn.
8 Ebedimeleki jáde kúrò láàfin ọba, ó sì sọ fún un pé,
And Abdemalech yede out of the kyngis hous, and spak to the kyng,
9 “Olúwa mi ọba, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti ṣe ohun búburú sí Jeremiah wòlíì Ọlọ́run. Wọ́n ti gbé e sọ sínú kànga níbi tí kò sí oúnjẹ kankan nínú ìlú mọ́.”
and seide, My lord the kyng, these men diden yuele alle thingis, what euer thingis thei diden ayens Jeremye, the profete, sendynge hym in to the lake, that he die there for hungur; for whi looues ben no more in the citee.
10 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Ebedimeleki ará Kuṣi pé, “Mú ọgbọ̀n ọkùnrin láti ibí pẹ̀lú rẹ, kí ẹ sì fa wòlíì Jeremiah sókè láti inú ihò, kí ó tó kú.”
Therfor the kyng comaundide to Abdemelech Ethiopien, and seide, Take with thee thretti men fro hennus, and reise thou Jeremye, the profete, fro the lake, bifor that he die.
11 Ebedimeleki kó àwọn ọkùnrin náà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n lọ sínú yàrá kan nínú ààfin ọba. Ó mú àwọn aṣọ àkísà àti okùn tọ Jeremiah lọ nínú kànga.
Therfor whanne Abdemelech hadde take men with hym, he entride in to the hous of the kyng, that was vndur the celer; and he took fro thennus elde clothis, and elde ragges, that weren rotun; and he sente tho doun to Jeremye, in to the lake, bi cordis.
12 Ebedimeleki ará Kuṣi sọ fún Jeremiah pé, “Fi àkísà àti okùn bọ abẹ́ abíyá rẹ, Jeremiah sì ṣe bẹ́ẹ̀.”
And Abdemelech Ethiopien seide to Jeremye, Putte thou elde clothis, and these to-rent and rotun thingis vndur the cubit of thin hondis, and on the cordis. Therfor Jeremye dide so.
13 Báyìí ni wọ́n ṣe fi okùn yọ Jeremiah jáde, wọ́n sì mu un gòkè láti inú ihò wá, Jeremiah sì wà ní àgbàlá ilé túbú.
And thei drowen out Jeremye with cordis, and ledden hym out of the lake. Forsothe Jeremye dwellide in the porche of the prisoun.
14 Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ pe, Jeremiah òjíṣẹ́ Ọlọ́run àti láti mú un wá sí ẹnu ibodè kẹta nílé Olúwa. Ọba sì sọ fún Jeremiah pé, “Èmi yóò bi ọ́ ní ohun kan; má sì ṣe fi ohun kan pamọ́ fún mi.”
And kyng Sedechie sente, and took hym Jeremye, the profete, at the thridde dore that was in the hous of the Lord. And the kyng seide to Jeremye, Y axe of thee a word; hide thou not ony thing fro me.
15 Jeremiah sì sọ fún Sedekiah pé, “Tí mo bá fún ọ ní èsì, ṣé o kò nípa mí? Tí mo bá gbà ọ́ nímọ̀ràn, o kò ní gbọ́ tèmi.”
Forsothe Jeremye seide to Sedechie, If Y telle to thee, whether thou schalt not sle me? And if Y yyue councel to thee, thou schalt not here me.
16 Ṣùgbọ́n ọba Sedekiah búra ní ìkọ̀kọ̀ fún Jeremiah wí pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó fún wa ní ẹ̀mí, èmi kò nípa ọ́ tàbí fà ọ́ fún àwọn tó ń lépa ẹ̀mí rẹ.”
Therfor Sedechie the king swoor to Jeremye priueli, and seide, The Lord lyueth, that maad to vs this soule, Y schal not sle thee, and Y schal not bitake thee in to the hondis of these men, that seken thi lijf.
17 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún Sedekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Àyàfi bí o bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn olóyè ọba Babeli, a ó dá ẹ̀mí rẹ sí àti pé ìlú yìí kò ní di jíjó ní iná; ìwọ àti ilé rẹ yóò sì wà láààyè.
And Jeremye seide to Sedechie, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, If thou goest forth, and goest out to the princes of the kyng of Babiloyne, thi soule schal lyue, and this citee schal not be brent with fier, and thou schalt be saaf, thou and thin hous.
18 Ṣùgbọ́n tí o kò bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn ìjòyè ọba Babeli, a ó fa ìlú yìí lé ọwọ́ àwọn Babeli. Wọn yóò sì fi iná sun ún, ìwọ gan an kò ní le sá mọ́ wọn lọ́wọ́.’”
Forsothe if thou goest not out to the princes of the kyng of Babiloyne, this citee schal be bitakun in to the hondis of Caldeis; and thei schulen brenne it with fier, and thou schalt not ascape fro the hond of hem.
19 Ọba Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Mò ń bẹ̀rù àwọn Júù tó ti sálọ sí ilẹ̀ Babeli, nítorí pé àwọn ará Babeli lè fà mí lé wọn lọ́wọ́ láti fìyà jẹ mí.”
And kyng Sedechie seide to Jeremye, Y am angwischid for the Jewis that fledden ouer to Caldeis, lest perauenture Y be bitakun in to the hondis of hem, and thei scorne me.
20 Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Wọn kò ní fi ọ́ lé e lọ́wọ́. Pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ nípa ṣíṣe ohun tí mo sọ fún ọ; yóò sì dára fún ọ, ẹ̀mí rẹ yóò sì wà.
Forsothe Jeremye answeride, and seide to hym, Thei schulen not bitake thee; Y biseche, here thou the vois of the Lord, which Y schal speke to thee, and it schal be wel to thee, and thi soule schal lyue.
21 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kọ̀ láti jọ̀wọ́ ara rẹ, èyí ni ohun tí Olúwa ti fihàn mí.
That if thou wolt not go out, this is the word which the Lord schewide to me, Lo!
22 Gbogbo àwọn obìnrin tókù ní ààfin ọba Juda ni wọn yóò kó jáde fún àwọn ìjòyè ọba Babeli. Àwọn obìnrin náà yóò sì sọ fún ọ pé: “‘Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì borí rẹ. Ẹsẹ̀ rẹ rì sínú ẹrọ̀fọ̀; àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti fi ọ́ sílẹ̀.’
alle the wymmen, that weren left in the hous of the kyng of Juda, schulen be led out to the princes of the kyng of Babiloyne; and tho wymmen schulen seie, Thi pesible men disseyueden thee, and hadden the maistrye ayens thee; thei drenchiden thee in filthe, and thi feet in slidirnesse, and yeden awei fro thee.
23 “Wọn yóò kó àwọn ìyàwó àti ọmọ rẹ wá sí Babeli. Ìwọ gan an kò ní bọ́ níbẹ̀, ọba Babeli yóò mú ọ, wọn yóò sì jó ìlú yìí kanlẹ̀.”
And alle thi wyues and thi sones schulen be led out to Caldeis, and thou schalt not ascape the hondis of hem; but thou schalt be bitakun in to the hondis of the kyng of Babiloyne, and he schal brenne this citee bi fier.
24 Nígbà náà ni Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ yìí, tàbí kí o kú.
Therfore Sedechie seide to Jeremye, No man wite these wordis, and thou schalt not die.
25 Tí àwọn ìjòyè bá mọ̀ pé mo bá ọ sọ̀rọ̀, tí wọ́n bá wá bá ọ wí pé, ‘Sọ fún wa ohun tí o bá ọba sọ tàbí ohun tí ọba sọ fún ọ; má ṣe fi pamọ́ fún wa tàbí kí a pa ọ́,’
Sotheli if the princes heren, that Y spak with thee, and comen to thee, and seien to thee, Schewe thou to vs what thou spakest with the kyng, hide thou not fro vs, and we schulen not sle thee; and what the kyng spak with thee,
26 nígbà náà kí o sọ fún wọn, ‘Mò ń bẹ ọba láti má jẹ́ kí n padà lọ sí ilé Jonatani láti lọ kú síbẹ̀.’”
thou schalt seie to hem, Knelyngli Y puttide forth my preiris bifore the kyng, that he schulde not comaunde me to be led ayen in to the hous of Jonathan, and Y schulde die there.
27 Gbogbo àwọn olóyè sì wá sí ọ̀dọ̀ Jeremiah láti bi í léèrè, ó sì sọ gbogbo ohun tí ọba ní kí ó sọ. Wọn kò sì sọ ohunkóhun mọ́, nítorí kò sí ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ tí òun àti ọba jọ sọ.
Therfor alle the princes camen to Jeremye, and axiden hym; and he spak to hem bi alle the wordis whiche the kyng hadde comaundid to hym, and thei ceessiden fro hym; for whi no thing was herd.
28 Jeremiah wà nínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́ títí di ọjọ́ tí wọ́n fi kó Jerusalẹmu:
Therfor Jeremye dwellide in the porche of the prisoun, til to the dai wherynne Jerusalem was takun; and it was don, that Jerusalem schulde be takun.